< Powtórzonego 28 >
1 Jeśli będziesz pilnie słuchał głosu PANA, swego Boga, by przestrzegać i wypełniać wszystkie jego przykazania, które ci dziś nakazuję, to PAN, twój Bóg, wywyższy cię ponad wszystkie narody ziemi.
Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
2 I spłyną na ciebie te wszystkie błogosławieństwa, i dosięgną cię, jeśli będziesz słuchał głosu PANA, swego Boga:
Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
3 Błogosławiony będziesz w mieście i błogosławiony będziesz na polu.
Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
4 Błogosławiony będzie owoc twego łona, owoc twojej ziemi, owoc twego bydła, przyrost twego stada oraz trzody twoich owiec.
Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
5 Błogosławiony będzie twój kosz i twoja dzieża.
Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
6 Błogosławiony będziesz, gdy będziesz wchodził, i błogosławiony, gdy będziesz wychodził.
Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
7 PAN sprawi, że twoi wrogowie, którzy powstaną przeciwko tobie, zostaną pobici przed tobą. Jedną drogą wyruszą przeciwko tobie, a siedmioma drogami będą przed tobą uciekać.
Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
8 PAN przykaże, aby było z tobą błogosławieństwo w twoich spichlerzach i we wszystkim, do czego wyciągniesz swoją rękę; i będzie ci błogosławił w ziemi, którą daje ci PAN, twój Bóg.
Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
9 PAN ustanowi cię dla siebie świętym ludem, tak jak ci poprzysiągł, jeśli będziesz przestrzegać przykazań PANA, swego Boga, i chodził jego drogami.
Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
10 I wszystkie narody ziemi zobaczą, że jesteś nazywany imieniem PANA, i będą się ciebie lękać.
Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
11 PAN obdarzy cię obfitością dobra, owocu twego łona, owocu twego bydła, owocu twego pola, w ziemi, którą PAN poprzysiągł twoim ojcom, że ją tobie da.
Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
12 PAN otworzy dla ciebie swój bogaty skarbiec, niebo, aby dawać deszcz twojej ziemi w odpowiednim czasie i błogosławić wszelką pracę twoich rąk. Będziesz pożyczał wielu narodom, a sam [od nikogo] nie będziesz pożyczał.
Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
13 I PAN umieści cię na czele, a nie na końcu; i będziesz tylko na górze, a nie będziesz na dole, jeśli będziesz słuchał przykazań PANA, swego Boga, które ci dziś nakazuję, abyś [ich] przestrzegał i [je] wypełniał.
Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
14 I nie odstąpisz od żadnego słowa, które ja wam dziś nakazuję, ani na prawo, ani na lewo, by iść za innymi bogami i im służyć.
Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
15 Lecz jeśli nie będziesz słuchał głosu PANA, swego Boga, by przestrzegać wszystkich jego przykazań i ustaw, które ci dziś nakazuję, i wypełniać je, to spadną na ciebie wszystkie te przekleństwa i cię dosięgną:
Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
16 Przeklęty będziesz w mieście, przeklęty będziesz na polu.
Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
17 Przeklęty będzie twój kosz i twoja dzieża.
Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
18 Przeklęty będzie owoc twego łona, owoc twojej ziemi, przyrost twego bydła oraz trzody twoich owiec.
Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
19 Przeklęty będziesz, kiedy będziesz wchodził, i przeklęty, kiedy będziesz wychodził.
Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
20 PAN ześle na ciebie przekleństwo, trwogę i karę we wszystkim, do czego wyciągniesz swoją rękę i co czynić będziesz, aż zostaniesz zniszczony i szybko zginiesz z powodu niegodziwości swoich czynów, przez które mnie opuściłeś.
Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
21 PAN sprawi, że przylgnie do ciebie zaraza, aż cię wyniszczy z ziemi, do której idziesz, by ją posiąść.
Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
22 PAN uderzy cię suchotami, febrą, zapaleniem, silną gorączką, mieczem, suszą i pleśnią, które będą cię prześladować, aż zginiesz.
Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
23 Niebo nad twoją głową stanie się miedzią, a ziemia pod tobą – żelazem.
Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
24 PAN ześle na twą ziemię jak deszcz proch i pył, [które] na ciebie spadną z nieba, aż cię zniszczy.
Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
25 PAN sprawi, że zostaniesz pobity przed swymi wrogami. Jedną drogą wyruszysz przeciwko nim, lecz siedmioma drogami będziesz uciekał przed nimi, i będziesz wysiedlony do wszystkich królestw ziemi.
Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
26 A twój trup będzie pokarmem dla wszelkiego ptactwa nieba i zwierząt ziemi i nikt [ich] nie odpędzi.
Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
27 PAN dotknie cię wrzodem egipskim, hemoroidami, świerzbem i liszajem, z których nie zdołasz się wyleczyć.
Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
28 PAN dotknie cię obłędem, ślepotą i przerażeniem serca.
Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
29 W południe będziesz chodził po omacku, jak ślepy w ciemności, i nie powiedzie ci się na twoich drogach. Będziesz uciskany i łupiony po wszystkie dni, a nikt cię nie wybawi.
Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
30 Poślubisz [sobie] żonę, lecz inny mężczyzna będzie z nią obcować. Zbudujesz dom, lecz w nim nie zamieszkasz. Zasadzisz winnicę, lecz z niej nie skorzystasz.
Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
31 Twój wół zostanie zabity na twoich oczach, ale nie będziesz go jadł. Twój osioł zostanie ci zabrany sprzed twego oblicza, ale nie zwrócą ci go. Twoje owce zostaną oddane twoim wrogom, ale nikt cię nie uratuje.
Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
32 Twoi synowie i twoje córki zostaną wydani innemu narodowi, a twoje oczy, wypatrując [ich], zasłabną z tęsknoty za nimi przez cały dzień, a twoja ręka będzie bezsilna.
Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
33 Owoc twojej ziemi i całą twoją pracę pożre naród, którego ty nie znasz, i będziesz tylko uciskany i dręczony po wszystkie dni.
Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
34 I oszalejesz na widok tego, co zobaczą twoje oczy.
Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
35 PAN dotknie cię złośliwym wrzodem na kolanach i na goleniach, którego nie będzie można wyleczyć, od stopy aż po czubek głowy.
Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
36 PAN zaprowadzi ciebie i twojego króla, którego ustanowisz nad sobą, do narodu, którego nie znałeś ani ty, ani twoi ojcowie. Tam będziesz służył innym bogom, drewnu i kamieniowi.
Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
37 I będziesz dziwowiskiem, tematem przysłowia i pośmiewiskiem wśród wszystkich narodów, do których PAN cię zaprowadzi.
Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
38 Dużo ziarna wyniesiesz na pole, lecz mało zbierzesz, gdyż pożre je szarańcza.
Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
39 Winnicę zasadzisz i uprawisz, ale nie będziesz pił wina ani zbierał [winogron], gdyż pożre je robactwo.
Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
40 Będziesz miał drzewa oliwne we wszystkich swoich granicach, lecz nie namaścisz się oliwą, bo twoje oliwki opadną.
Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
41 Spłodzisz synów i córki, ale nie będą twoje, bo pójdą w niewolę.
Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
42 Wszystkie twoje drzewa i owoc twojej ziemi pożre szarańcza.
Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
43 Cudzoziemiec, który jest pośród ciebie, wzniesie się wielce nad tobą, a ty schylisz się bardzo nisko.
Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
44 On będzie tobie pożyczał, a ty jemu nie będziesz pożyczał. On będzie na czele, a ty będziesz na końcu.
Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
45 I spadną na ciebie wszystkie te przekleństwa, i będą cię ścigały, i dosięgną cię, aż cię zniszczą, ponieważ nie słuchałeś głosu PANA, swego Boga, by przestrzegać jego przykazań i ustaw, które ci nakazał.
Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
46 A [te plagi] będą na tobie i na twym potomstwie jako znak i cud na wieki.
Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
47 Dlatego, że nie służyłeś PANU, swemu Bogu, w radości i z weselem serca, gdy miałeś obfitość wszystkiego.
Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
48 I będziesz służył swoim wrogom, których PAN ześle na ciebie, w głodzie, w pragnieniu, w nagości i w niedostatku wszystkiego. I włoży żelazne jarzmo na twoją szyję, aż cię wyniszczy.
Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
49 PAN sprowadzi na ciebie naród z daleka, z krańców ziemi, [który] przyleci jak orzeł; naród, którego języka nie zrozumiesz.
Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
50 Naród o srogim obliczu, który nie będzie miał względu na starego ani się nad dzieckiem nie zlituje;
Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
51 I pożre owoc twego bydła i owoc twojej ziemi, aż cię zniszczy. I nie zostawi ci ani zboża, ani moszczu, ani oliwy, [ani] przyrostu twych wołów, ani trzód twych owiec, aż cię wyniszczy.
Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
52 I oblegnie cię we wszystkich twoich bramach, aż w całej twojej ziemi upadną twoje wysokie i obronne mury, w których pokładałeś ufność. Oblegnie cię we wszystkich twoich bramach, na całej twojej ziemi, którą daje ci PAN, twój Bóg.
Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
53 Będziesz jadł płód swego łona, ciało swoich synów i córek, których dał ci PAN, twój Bóg, w czasie oblężenia i ucisku, jakimi twój wróg cię przytłoczy.
Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
54 Mężczyzna delikatny pośród was i w rozkoszy wychowany będzie spoglądał złym okiem na swego brata, na swą własną żonę i na resztę swych dzieci, które pozostały.
Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
55 I nie da żadnemu z nich z ciała swych dzieci, które będzie jadł, dlatego że nic innego mu nie zostało w oblężeniu i ucisku, jakimi twój wróg cię uciśnie we wszystkich twoich bramach.
Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
56 [Kobieta] delikatna pośród was i w rozkoszy wychowana, która nie chciała postawić swojej nogi na ziemi z powodu delikatności i rozkoszy, będzie spoglądała złym okiem na męża swego łona, na swego syna i na swoją córkę;
Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
57 I na swe łożysko, które wychodzi z niej przy porodzie, i na swoje dzieci, które urodzi. Potajemnie będzie je bowiem jeść z braku wszystkiego w czasie oblężenia i ucisku, jakimi twój wróg przytłoczy cię w twoich bramach.
àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
58 Jeśli nie będziesz pilnował wypełnienia wszystkich słów tego prawa, które są napisane w tej księdze, żebyś się bał tego chwalebnego i strasznego imienia: PAN, twój Bóg;
Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
59 PAN ześle na ciebie i na twoje potomstwo niezwykłe plagi, plagi wielkie i niekończące się, także ciężkie i długotrwałe choroby.
Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
60 I sprowadzi na ciebie wszystkie choroby egipskie, których się lękałeś, i przylgną [one] do ciebie.
Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
61 Także wszelką chorobę i wszelką plagę, która nie jest napisana w księdze tego prawa, PAN sprowadzi na ciebie, aż cię wytępi.
Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
62 I pozostanie was niewielu, którzy przedtem byliście tak liczni jak gwiazdy niebieskie, bo nie posłuchałeś głosu PANA, swego Boga.
Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
63 I będzie tak, że jak PAN radował się wami, czyniąc wam dobrze i rozmnażając was, tak PAN będzie się wami radował, niszcząc was i gładząc was; i będziecie wykorzenieni z ziemi, do której idziecie, aby ją posiąść.
Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
64 I PAN rozproszy cię wśród wszystkich narodów, od jednego krańca ziemi aż do drugiego; tam będziesz służył innym bogom, których nie znałeś ani ty, ani twoi ojcowie – [nawet] drewnu i kamieniowi.
Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
65 A wśród tych narodów nie zaznasz wytchnienia ani stopa twojej nogi nie odpocznie. A PAN da ci tam lękliwe serce, wyczerpane oczy i smutek duszy.
Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
66 I twoje życie będzie przed tobą [jakby] w zawieszeniu, będziesz się lękał w nocy i we dnie i nie będziesz pewien swego życia.
Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
67 Rano powiesz: Oby już był wieczór, a wieczorem powiesz: Oby już był ranek; z powodu strachu w twoim sercu, który będziesz odczuwać, i z powodu tego, co zobaczą twoje oczy.
Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
68 I PAN zawróci cię do Egiptu na okrętach drogą, o której ci powiedziałem, że już jej nie zobaczysz. Tam będziecie się sprzedawać swoim wrogom jako niewolnicy i niewolnice, ale [nikt] was nie kupi.
Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.