< Powtórzonego 22 >
1 Jeśli zobaczysz zabłąkanego wołu albo owcę swego brata, nie omijaj ich, [lecz] koniecznie odprowadź je do swego brata.
Bí o bá rí màlúù tàbí àgùntàn arákùnrin rẹ tí ó ń sọnù, má ṣe ṣé àìkíyèsí i rẹ̀ ṣùgbọ́n rí i dájú pé o mú padà wá fún un.
2 A jeśli twój brat nie jest blisko ciebie albo nie znasz go, to zaprowadź je do swego domu i będą u ciebie, aż twój brat będzie ich poszukiwał i [wtedy] mu je zwrócisz.
Bí ọkùnrin náà kì í bá gbé ní tòsí rẹ tàbí bí o kò bá mọ ẹni náà, mú un lọ ilé pẹ̀lú rẹ kí o sì fi pamọ́ títí yóò fi wá a wá. Nígbà náà ni kí o fi fún un.
3 Tak samo postąpisz z jego osłem, tak samo postąpisz z jego szatą i tak samo postąpisz z każdą zgubioną rzeczą swego brata, która mu zginęła, a ty [ją] znalazłeś. Nie omijaj jej.
Ṣe bákan náà tí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ arákùnrin rẹ tàbí aṣọ ìlekè tàbí ohunkóhun rẹ̀ tí ó sọnù. Má ṣe ṣe àìkíyèsí i rẹ̀.
4 Jeśli zobaczysz, że osioł albo wół twego brata upadł na drodze, nie omijaj ich, lecz niezwłocznie pomóż mu je podnieść.
Bí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù arákùnrin rẹ tí o dùbúlẹ̀ sójú ọ̀nà, má ṣe ṣàìfiyèsí i rẹ̀, ràn án lọ́wọ́ láti dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀.
5 Kobieta nie będzie nosiła ubrania mężczyzny ani mężczyzna nie włoży na siebie ubrania kobiety, gdyż ci, którzy tak czynią, budzą odrazę u PANA, twego Boga.
Obìnrin kò gbọdọ̀ wọ aṣọ ọkùnrin, tàbí kí ọkùnrin wọ aṣọ obìnrin, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó ṣe èyí.
6 Jeśli przed sobą na drodze napotkasz ptasie gniazdo na jakimkolwiek drzewie lub na ziemi, z pisklętami lub jajkami, a matka wysiaduje pisklęta lub jajka, nie zabierzesz matki z młodymi;
Bí ìwọ bá ṣe alábòápàdé ìtẹ́ ẹyẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, bóyá lára igi tàbí lórí ilẹ̀, tí ìyá wọn sì jókòó lórí àwọn ọmọ, tàbí lórí àwọn ẹyin, má ṣe gbé ìyá pẹ̀lú àwọn ọmọ.
7 Lecz wypuścisz matkę na wolność, a młode weźmiesz sobie, aby ci się dobrze powodziło i abyś przedłużył [swoje] dni.
Ìwọ lè gbé ọmọ, ṣùgbọ́n rí i dájú pé o jọ̀wọ́ ìyá lọ́wọ́ lọ, kí ó ba à lè dára fún ọ àti kí o lè ní ẹ̀mí gígùn.
8 Gdy zbudujesz nowy dom, wtedy uczynisz na swoim dachu ogrodzenie, byś nie sprowadził krwi na swój dom, gdyby ktoś z niego spadł.
Nígbà tí o bá kọ́ ilé tuntun, mọ odi yí òrùlé rẹ̀ ká nítorí kí o má ba à mú ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ wá sórí ilẹ̀ rẹ bí ẹnikẹ́ni bá ṣubú láti òrùlé.
9 Nie zasiewaj w swojej winnicy różnych rodzajów ziarna, abyś nie splugawił plonu posianego ziarna i zbioru winnicy.
Má ṣe gbin oríṣìí èso méjì sínú ọgbà àjàrà rẹ; bí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, kì í ṣe èso oko tí o gbìn nìkan ṣùgbọ́n èso ọgbà àjàrà pẹ̀lú yóò bàjẹ́.
10 Nie będziesz orał wołem razem z osłem.
Ìwọ kò gbọdọ̀ fi akọ màlúù àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tulẹ̀ pọ̀.
11 Nie będziesz nosił szaty utkanej z wełny razem z lnem.
Ìwọ kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun àgùntàn àti aṣọ funfun papọ̀.
12 Sporządzisz sobie frędzle na czterech rogach swego płaszcza, którym będziesz się okrywał.
Kí o ṣe wajawaja sí etí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin aṣọ ìlekè rẹ.
13 Jeśli mężczyzna pojmie żonę, będzie z nią obcował, a potem ją znienawidzi;
Bí ọkùnrin kan bá mú ìyàwó àti, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti dùbúlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, kórìíra rẹ̀,
14 I sprawi, że będą o niej mówić [źle], i zniesławi jej imię, mówiąc: Pojąłem tę żonę, lecz gdy obcowałem z nią, nie stwierdziłem u niej dziewictwa;
tí ó ṣì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sì i, tí o sì fún un ní orúkọ búburú, wí pé, “Mo fẹ́ obìnrin yìí, ṣùgbọ́n nígbà tí mo súnmọ́ ọn. Èmi kò rí àmì ìbálé rẹ̀.”
15 Wtedy ojciec i matka dziewczyny wezmą i zaniosą dowody dziewictwa tej dziewczyny do starszych miasta, do bramy;
Nígbà náà ni baba ọmọbìnrin náà àti ìyá rẹ̀ yóò mú ẹ̀rí pé, ó ti wà ní ìbálé tẹ́lẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ìlú ní ẹnu-bodè.
16 I ojciec tej dziewczyny powie do starszych: Dałem swoją córkę temu mężczyźnie za żonę, a on jej nienawidzi;
Baba obìnrin náà yóò wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Mo fi ọmọbìnrin mi fún ọkùnrin yìí láti fẹ́ níyàwó, ṣùgbọ́n ó kórìíra rẹ̀.
17 A oto sam daje powód, aby mówiono o niej [źle], mówiąc: Nie stwierdziłem u twej córki dziewictwa; lecz oto są dowody dziewictwa mojej córki. Wtedy rozłożą prześcieradło przed starszymi miasta.
Ní ìsinsin yìí ó ti sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí i ó sì wí pé, ‘Èmi kò rí ọmọbìnrin rẹ kí ó wà ní wúńdíá.’ Ṣùgbọ́n níhìn-ín yìí ni ẹ̀rí ìbálé ọmọbìnrin mi.” Nígbà náà ni àwọn òbí rẹ̀ yóò fi aṣọ hàn níwájú àwọn àgbàgbà ìlú,
18 Wtedy starsi miasta wezmą tego mężczyznę i ukarzą go.
àwọn àgbàgbà yóò sì mú ọkùnrin náà, wọn yóò sì jẹ ní yà.
19 I nałożą na niego grzywnę wynoszącą sto syklów srebra, które oddadzą ojcu tej dziewczyny, ponieważ zniesławił dziewicę Izraela. Pozostanie jego żoną i nie będzie mógł jej oddalić po wszystkie swoje dni.
Wọn yóò sì gba ìtánràn ọgọ́rùn-ún ṣékélì owó fàdákà fún baba ọmọbìnrin náà, nítorí ọkùnrin yìí ti fi orúkọ búburú fún wúńdíá Israẹli. Yóò sì máa ṣe ìyàwó rẹ̀; kò gbọdọ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ní gbogbo ayé e rẹ̀.
20 Lecz jeśli oskarżenie będzie słuszne, a nie znajdą się [dowody] dziewictwa tej dziewczyny;
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀sùn náà bá jẹ́ òtítọ́ tí a kò sí rí ẹ̀rí ìbálé obìnrin náà,
21 Wtedy wyprowadzą tę dziewczynę do drzwi domu jej ojca i mężczyźni tego miasta ukamienują ją na śmierć, gdyż popełniła haniebny czyn w Izraelu, uprawiając nierząd w domu swego ojca. Tak usuniesz zło spośród siebie.
wọn yóò mú wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé baba rẹ̀ níbẹ̀ sì ni àwọn ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò ti sọ ọ́ ní òkúta pa. Ó ti ṣe ohun ìtìjú ní Israẹli nípa ṣíṣe àgbèrè nígbà tí ó wà nílé baba rẹ̀. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín yín.
22 Jeśli znajdzie się mężczyznę leżącego z zamężną kobietą, wtedy oboje umrą, mężczyzna, który leżał z kobietą, i ta kobieta. Tak usuniesz zło z Izraela.
Bí o bá rí ọkùnrin kan tí ó bá ìyàwó ọkùnrin mìíràn lòpọ̀, àwọn méjèèjì ní láti kú. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín Israẹli.
23 Jeśli dziewczynę, która jest dziewicą zaślubioną mężowi, napotka jakiś mężczyzna w mieście i będzie z nią obcował;
Bí ó bá ṣẹlẹ̀ wí pé ọkùnrin kan pàdé wúńdíá tí a ti fi fún ni láti fẹ́ láàrín ìlú tí ó sì lòpọ̀ pẹ̀lú u rẹ̀,
24 Wtedy wyprowadzisz oboje do bramy miasta i ukamienujecie ich na śmierć; dziewczynę za to, że [będąc] w mieście, nie krzyczała, a mężczyznę za to, że zhańbił żonę swego bliźniego. Tak usuniesz zło spośród siebie.
ìwọ yóò mú àwọn méjèèjì lọ sí ẹnu ibodè ìlú náà kí o sì sọ wọ́n ní òkúta pa nítorí ọmọbìnrin náà wà ní ìlú kò sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́, àti ọkùnrin náà nítorí ó ba ìyàwó ọkùnrin mìíràn jẹ́. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ.
25 Lecz jeśli mężczyzna napotka zaślubioną dziewczynę w polu, porwie ją i zgwałci, wtedy poniesie śmierć tylko mężczyzna, który z nią obcował.
Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe ìgbẹ́ ní ó ti ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin kan ti pàdé ọmọbìnrin tí a ti fẹ́ ṣọ́nà tí o sì fi tagbára tagbára bá a ṣe, ọkùnrin náà nìkan tí ó ṣe èyí ni yóò kú.
26 Ale dziewczynie nic nie uczynisz; dziewczyna nie zasługuje na śmierć, gdyż jest podobnie jak w przypadku, gdy ktoś powstaje przeciwko swemu bliźniemu i morduje go.
Má ṣe fi ohunkóhun ṣe ọmọbìnrin náà; kò ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó tọ́ sí ikú. Ẹjọ́ yìí rí bí i ti ẹnìkan tí a gbámú tí ó pa aládùúgbò rẹ̀.
27 Napotkał ją bowiem w polu, [a gdy] zaślubiona dziewczyna krzyczała, nie było nikogo, kto by ją uratował.
Nítorí ọkùnrin náà rí ọmọbìnrin náà ní ìta ibodè, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọmọbìnrin àfẹ́sọ́nà kígbe, kò sí ẹnìkankan níbẹ̀ láti gbà á kalẹ̀.
28 Jeśli mężczyzna napotka dziewczynę, która jest dziewicą i niezaślubiona, pochwyci ją i będzie z nią obcował, i zostaną przyłapani;
Bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin pàdé wúńdíá tí kò ì tí ì ní àfẹ́sọ́nà tí ó sì fi tipátipá bá a ṣe tí a gbá wọn mú.
29 Wtedy mężczyzna, który z nią obcował, da ojcu dziewczyny pięćdziesiąt syklów srebra i będzie ona jego żoną; a ponieważ ją zhańbił, nie będzie mógł jej oddalić po wszystkie swoje dni.
Ó ní láti san àádọ́ta fàdákà fún baba obìnrin náà, nítorí tí ó ti bà á jẹ́. Kò lè kọ̀ ọ́ sílẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí ó sì wà láààyè.
30 Nie pojmie mężczyzna żony swego ojca i nie odkryje brzegu szaty swego ojca.
Ọkùnrin kò gbọdọ̀ fẹ́ ìyàwó baba rẹ̀; kò gbọdọ̀ sọ ìtẹ́ baba rẹ̀ di àìlọ́wọ̀.