< II Samuela 7 >
1 Gdy król zamieszkał w swoim domu, a PAN dał mu odpoczynek od wszystkich jego wrogów wokoło;
Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
2 Król powiedział do proroka Natana: Zobacz, proszę, ja mieszkam w domu cedrowym, a arka Boga mieszka za zasłoną.
Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
3 Wtedy Natan odpowiedział królowi: Idź i uczyń wszystko, co jest w twoim sercu, gdyż PAN jest z tobą.
Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
4 Lecz tej samej nocy doszło do Natana słowo PANA:
Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
5 Idź i powiedz mojemu słudze Dawidowi: Tak mówi PAN: Czy ty zbudujesz mi dom, abym w nim mieszkał?
“Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
6 Nie mieszkałem bowiem w żadnym domu od dnia, w którym wyprowadziłem synów Izraela z Egiptu, aż do dziś, lecz wędrowałem w namiocie i w przybytku.
Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
7 I wszędzie, gdzie wędrowałem ze wszystkimi synami Izraela, czy powiedziałem do któregoś z sędziów Izraela, którym nakazałem paść mój lud Izraela: Dlaczego nie budujecie mi domu cedrowego?
Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
8 Teraz więc tak powiesz mojemu słudze Dawidowi: Tak mówi PAN zastępów: Wziąłem ciebie z owczarni, gdzie chodziłeś za owcami, abyś był wodzem nad moim ludem, nad Izraelem.
“Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
9 I byłem z tobą wszędzie, dokądkolwiek chodziłeś, wytraciłem przed tobą wszystkich twoich wrogów i uczyniłem twoje imię wielkim jak imię wielkich ludzi, którzy są na ziemi.
Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
10 Ustanowię miejsce dla mojego ludu Izraela i zasadzę go [tam], by mógł mieszkać na swoim miejscu, i nie poruszy się więcej ani już nie będą go uciskać synowie nieprawości jak dawniej;
Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
11 Od czasu, kiedy ustanowiłem sędziów nad moim ludem Izraelem i dałem ci odpoczynek od wszystkich twoich wrogów. Tobie też PAN oznajmia, że zbuduje ci dom.
Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
12 Gdy się dopełnią twoje dni i zaśniesz ze swoimi ojcami, wzbudzę po tobie twojego potomka, który wyjdzie z twego wnętrza, i umocnię jego królestwo.
Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
13 On zbuduje dom dla mojego imienia, a [ja] utwierdzę tron jego królestwa na wieki.
Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
14 Ja będę mu ojcem, a on będzie mi synem. Jeśli zgrzeszy, skarcę go rózgą ludzką i razami synów ludzkich.
Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
15 Lecz moje miłosierdzie nie odstąpi od niego, tak jak je cofnąłem od Saula, którego odrzuciłem przed tobą.
Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
16 I twój dom, i twoje królestwo będą utwierdzone na wieki przed tobą, a twój tron będzie trwał na wieki.
A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
17 Zgodnie z tymi wszystkimi słowami i zgodnie z tym całym widzeniem mówił Natan do Dawida.
Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
18 Wtedy wszedł król Dawid, usiadł przed PANEM i przemówił: Kimże ja [jestem], Panie BOŻE, i czymże jest mój dom, że doprowadziłeś mnie aż dotąd?
Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
19 Lecz i to było jeszcze mało w twoich oczach, Panie BOŻE, gdyż złożyłeś również obietnicę o domu twojego sługi na daleką przyszłość. Czy taki jest zwyczaj u ludzi, Panie BOŻE?
Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
20 I cóż więcej może powiedzieć ci Dawid? Ty bowiem znasz swojego sługę, Panie BOŻE.
“Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
21 Ze względu na twoje słowo i zgodnie z twoim sercem uczyniłeś wszystkie te wielkie rzeczy, dając poznać je twemu słudze.
Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
22 Dlatego jesteś wielki, PANIE Boże. Nie ma bowiem nikogo podobnego do ciebie i nie ma Boga oprócz ciebie, zgodnie z tym, co usłyszeliśmy na własne uszy.
“Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
23 I czyż jest taki naród na ziemi jak twój lud Izrael, dla którego Bóg wyruszył, aby wykupić [go] sobie jako lud, by uczynić [wielkim] swoje imię i dokonać dla nich wielkich i straszliwych rzeczy w twojej ziemi, przed twoim ludem, który wykupiłeś sobie z Egiptu, spośród narodów i ich bogów?
Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
24 Ustanowiłeś sobie bowiem swój lud, Izraela, aby był dla ciebie ludem na wieki. A ty, PANIE, stałeś się jego Bogiem.
Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
25 Teraz więc, PANIE Boże, utwierdź na wieki słowo, które wypowiedziałeś o swoim słudze i o jego domu, i czyń, jak powiedziałeś;
“Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
26 Aby twoje imię było wielbione na wieki, aby mówiono: PAN zastępów jest Bogiem nad Izraelem, a dom twego sługi Dawida będzie utwierdzony przed tobą.
Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
27 Ty bowiem, PANIE zastępów, Boże Izraela, objawiłeś swemu słudze, mówiąc: Zbuduję ci dom. Dlatego twój sługa ośmielił się skierować do ciebie tę modlitwę.
“Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
28 A teraz, Panie BOŻE, ty jesteś tym Bogiem, a twoje słowa są prawdą, obiecałeś swemu słudze tę dobroć.
Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
29 Teraz więc racz pobłogosławić dom swego sługi, aby przed tobą trwał na wieki. Ty bowiem, Panie BOŻE, to powiedziałeś i dzięki twojemu błogosławieństwu dom twego sługi będzie błogosławiony na wieki.
Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”