< II Samuela 6 >
1 I Dawid ponownie zebrał wszystkich doborowych [mężczyzn] z Izraela, trzydzieści tysięcy.
Dafidi sì tún kó gbogbo àwọn akọni ọkùnrin ní Israẹli jọ, wọ́n sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
2 Potem Dawid wraz z całym ludem, który z nim był, powstał i wyruszył z Baali judzkiej, aby przenieść stamtąd arkę Boga, która nosi imię PANA zastępów zasiadającego [między] cherubinami.
Dafidi sì dìde, ó sì lọ àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ́ lọ́dọ̀ rẹ́, láti Baalahi ní Juda wá, láti mú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run tí ibẹ̀ wá, èyí tí a ń pe orúkọ rẹ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó jókòó láàrín àwọn kérúbù.
3 I umieścili arkę Boga na nowym wozie, i wywieźli ją z domu Abinadaba położonego w Gibea. A Uzza i Achio, synowie Abinadaba, prowadzili ten nowy wóz.
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà gun kẹ̀kẹ́ tuntun kan, wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu wá, èyí tí ó wà ní Gibeah: Ussa àti Ahio, àwọn ọmọ Abinadabu sì ń dá kẹ̀kẹ́ tuntun náà.
4 I wyprowadzili go z domu Abinadaba położonego w Gibea wraz z arką Boga. A Achio szedł przed arką.
Wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu jáde wá, tí ó wà ní Gibeah, pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, Ahio sì ń rìn níwájú àpótí ẹ̀rí náà.
5 Dawid zaś i cały Izrael grali przed PANEM na wszelkich [instrumentach] z drewna jodłowego: na harfach, cytrach, bębnach, piszczałkach i cymbałach.
Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì ṣiré níwájú Olúwa lára gbogbo onírúurú ohun èlò orin tí a fi igi arère ṣe àti lára ìlù haapu, ní ara tambori, sisitirumu àti lára kimbali.
6 A [gdy] przybyli do klepiska Nachona, Uzza wyciągnął [rękę] do arki Boga i pochwycił ją, gdyż woły ją szarpnęły.
Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Nakoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, ó sì dìímú, nítorí tí màlúù kọsẹ̀.
7 I zapłonął gniew PANA przeciwko Uzzie, i Bóg zabił go za uchybienie. I umarł tam przy arce Boga.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Ussa; Ọlọ́run sì pa á níbẹ̀ nítorí ìṣísẹ̀ rẹ̀; níbẹ̀ ni ó sì kù ní ẹ̀bá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
8 I Dawid był wielce niezadowolony, że PAN tak srogo poraził Uzzę, i nazwał to miejsce Peres-Uzza, i tak jest do dziś.
Inú Dafidi sì bàjẹ́ nítorí tí Olúwa gé Ussa kúrò, ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Peresi-Usa títí ó fi di òní yìí.
9 Dawid zląkł się PANA tego dnia i powiedział: Jakże ma przyjść do mnie arka PANA?
Dafidi sì bẹ̀rù Olúwa ní ọjọ́ náà, ó sì wí pé, “Àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò ti ṣe tọ̀ mí wá?”
10 Dlatego Dawid nie chciał sprowadzić arki PANA do siebie, do swego miasta, lecz wprowadził ją do domu Obed-Edoma, Gittyty.
Dafidi kò sì fẹ́ mú àpótí ẹ̀rí Olúwa sọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìlú Dafidi; ṣùgbọ́n Dafidi sì mú un yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti.
11 I arka PANA pozostała w domu Obed-Edoma, Gittyty, przez trzy miesiące. A PAN błogosławił Obed-Edomowi i całemu jego domowi.
Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì gbé ní ilé Obedi-Edomu ará Gitti ní oṣù mẹ́ta; Olúwa sì bùkún fún Obedi-Edomu, àti gbogbo ilé rẹ̀.
12 A doniesiono królowi Dawidowi: PAN błogosławi domowi Obed-Edoma i wszystkiemu, co posiada, ze względu na arkę Boga. Dawid poszedł więc i sprowadził z wielką radością arkę Boga z domu Obed-Edoma do miasta Dawida.
A sì rò fún Dafidi ọba pé, “Olúwa ti bùkún fún ilé Obedi-Edomu, àti gbogbo èyí tí í ṣe tirẹ̀, nítorí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.” Dafidi sì lọ, ó sì mú àpótí ẹ̀rí náà gòkè láti ilé Obedi-Edomu wá sí ìlú Dafidi pẹ̀lú ayọ̀.
13 A gdy ci, którzy nieśli arkę PANA, zrobili sześć kroków, składał w ofierze woły i tuczne [zwierzęta].
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa bá sì ṣí ẹsẹ̀ mẹ́fà, òun a sì fi màlúù àti ẹran àbọ́pa rú ẹbọ.
14 I Dawid tańczył przed PANEM z całych sił; był przepasany lnianym efodem.
Dafidi sì fi gbogbo agbára rẹ̀ jó níwájú Olúwa; Dafidi sì wọ efodu ọ̀gbọ̀.
15 Tak Dawid i cały dom Izraela sprowadzili arkę PANA z okrzykami i przy dźwiękach trąby.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, pẹ̀lú ìhó ayọ̀, àti pẹ̀lú ìró ìpè.
16 A gdy arka PANA weszła do miasta Dawida, Mikal, córka Saula, wyglądała przez okno i zobaczyła króla Dawida, jak skakał i tańczył przed PANEM, i wzgardziła nim w swoim sercu.
Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wọ ìlú Dafidi wá; Mikali ọmọbìnrin Saulu sì wo láti ojú fèrèsé, ó sì rí Dafidi ọba ń fò sókè ó sì ń jó níwájú Olúwa; òun sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
17 Sprowadzili więc arkę PANA i ustawili ją na swoim miejscu w środku namiotu, który rozpiął dla niej Dawid. I Dawid złożył przed PANEM całopalenia i ofiary pojednawcze.
Wọ́n sì mú àpótí ẹ̀rí Olúwa náà wá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ sípò rẹ̀ láàrín àgọ́ náà tí Dafidi pa fún un. Dafidi sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ níwájú Olúwa.
18 A gdy Dawid skończył składać całopalenia i ofiary pojednawcze, błogosławił ludowi w imię PANA zastępów.
Dafidi sì parí ìṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ náà, ó sì súre fún àwọn ènìyàn náà ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
19 I rozdał wśród całego ludu i całego zgromadzenia Izraela, zarówno mężczyznom, jak i kobietom, każdemu po jednym bochenku chleba, po jednym kawałku mięsa i po jednym bukłaku [wina]. Potem cały lud odszedł, każdy do swojego domu.
Ó sì pín fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, àní fún gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn Israẹli, àti ọkùnrin àti obìnrin; fún olúkúlùkù ìṣù àkàrà kan àti ekìrí ẹran kan, àti àkàrà díndín kan. Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì túká lọ, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
20 Potem Dawid wrócił, aby pobłogosławić swój dom. I Mikal, córka Saula, wyszła naprzeciw Dawidowi, i powiedziała: O jakże wspaniały był dziś król Izraela, który się obnażył dziś na oczach służących swych sług, tak jak się obnaża jakiś niepoważny [człowiek]!
Dafidi sì yípadà láti súre fún àwọn ará ilé rẹ̀, Mikali ọmọbìnrin Saulu sì jáde láti wá pàdé Dafidi, ó sì wí pé, “Báwo ni ọba Israẹli ṣe ṣe ara rẹ̀ lógo bẹ́ẹ̀ lónìí, tí ó bọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ lónìí lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn lásán tí ń bọ́ra rẹ̀ sílẹ̀.”
21 Wtedy Dawid powiedział do Mikal: [Grałem] przed PANEM, który wybrał raczej mnie niż twego ojca i niż cały jego dom, aby ustanowić mnie wodzem nad ludem PANA, nad Izraelem. Będę więc grał przed PANEM.
Dafidi sì wí fún Mikali pé, “Níwájú Olúwa ni, ẹni tí ó yàn mí fẹ́ ju baba rẹ lọ, àti ju gbogbo ìdílé rẹ lọ, láti fi èmi ṣe olórí àwọn ènìyàn Olúwa, àní lórí Israẹli, èmi ó sì súre níwájú Olúwa.
22 I poniżę się jeszcze bardziej niż dotąd, i będę jeszcze bardziej godny pogardy w swoich oczach, lecz u służących, o których mi mówiłaś, będę poważany.
Èmi ó sì tún rẹ ara mi sílẹ̀ jú bẹ́ẹ̀ lọ, èmi ó sì ṣe aláìníyìn lójú ara mi, àti lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà ti ìwọ wí, lọ́dọ̀ wọn náà ni èmi ó sì ní ògo.”
23 Mikal, córka Saula, nie miała więc dzieci aż do dnia swej śmierci.
Mikali ọmọbìnrin Saulu kò sì bí ọmọ, títí o fi di ọjọ́ ikú rẹ̀ nítorí tí ó sọ̀rọ̀-òdì yìí sí Dafidi.