< II Samuela 15 >
1 Potem Absalom sprawił sobie rydwany i konie, a także pięćdziesięciu mężczyzn, którzy przed nim biegali.
Lẹ́yìn èyí náà, Absalomu sì pèsè kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin fún ara rẹ̀, àti àádọ́ta ọmọkùnrin tí yóò máa sáré níwájú rẹ̀.
2 Absalom wstawał wcześnie rano i stawał przy drodze do bramy. A każdego, kto miał sprawę i udawał się do króla na sąd, Absalom przyzywał do siebie i pytał: Z jakiego miasta jesteś? Ten odpowiadał: Twój sługa jest z jednego z pokoleń Izraela.
Absalomu sì dìde ní kùtùkùtù, ó sì dúró ní apá kan ọ̀nà ẹnu ibodè. Bí ẹnìkan bá ní ẹjọ́ tí ó ń fẹ́ mú tọ ọba wá fún ìdájọ́, a sì pè é sọ́dọ̀ rẹ̀, a sì bi í pé, “Ará ìlú wo ni ìwọ?” Òun a sì dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti inú ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli wá.”
3 Wtedy Absalom mówił mu: Patrz, twoja sprawa jest dobra i sprawiedliwa, ale u króla nie ma nikogo, kto by cię wysłuchał.
Absalomu yóò sì wí fún un pé, “Wò ó, ọ̀ràn rẹ ṣá dára, ó sì tọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ọba fi àṣẹ fún láti gbọ́ ọ̀ràn rẹ.”
4 Potem Absalom mówił: O gdyby mnie ustanowiono sędzią w tej ziemi, aby mógł przychodzić do mnie każdy, kto ma sprawę lub spór, to wymierzałbym mu sprawiedliwość.
Absalomu a sì wí pé, “À bá jẹ́ fi mi ṣe onídàájọ́ ní ilẹ̀ yìí! Kí olúkúlùkù ẹni tí ó ní ẹjọ́ tàbí ọ̀ràn kan bá à lè máa tọ̀ mí wá, èmi ìbá sì ṣe ìdájọ́ òtítọ́ fún un.”
5 A gdy ktoś się zbliżał i pokłonił mu się, wyciągał rękę, obejmował go i całował.
Bẹ́ẹ̀ ni bí ẹnìkan bá sì súnmọ́ láti tẹríba fún un, òun a sì nawọ́ rẹ̀, a sì dìímú, a sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
6 Tak Absalom postępował z całym Izraelem, który przychodził do króla na sąd. I Absalom wykradał serca ludu Izraela.
Irú ìwà báyìí ni Absalomu a máa hù sí gbogbo Israẹli tí ó tọ́ ọba wá nítorí ìdájọ́, Absalomu sì fi fa ọkàn àwọn ènìyàn Israẹli sọ́dọ̀ rẹ̀.
7 Po upływie czterdziestu lat Absalom powiedział do króla: Proszę, pozwól mi iść i wypełnić w Hebronie ślub, który złożyłem PANU.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ogójì ọdún, Absalomu sì wí fún ọba pé, “Èmi bẹ́ ọ́, jẹ́ kí èmi ó lọ, kí èmi sì san ìlérí mi tí èmi ti ṣe fún Olúwa, ní Hebroni.
8 Twój sługa bowiem złożył ślub, kiedy przebywał w Geszur w Syrii, mówiąc: Jeśli PAN naprawdę przywróci mnie do Jerozolimy, wtedy będę służyć PANU.
Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ kan nígbà tí èmi ń bẹ ní Geṣuri ní Siria pé, ‘Bí Olúwa bá mú mi padà wá sí Jerusalẹmu, nítòótọ́, èmi ó sì sin Olúwa.’”
9 I król odpowiedział mu: Idź w pokoju. Wstał więc i udał się do Hebronu.
Ọba sì wí fún un pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Ó sì dìde, ó sì lọ sí Hebroni.
10 Lecz Absalom rozesłał szpiegów do wszystkich pokoleń Izraela, aby mówili: Gdy tylko usłyszycie dźwięk trąby, powiedzcie: Absalom króluje w Hebronie.
Ṣùgbọ́n Absalomu rán àmì sáàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbọ́ ìró ìpè, kí ẹ̀yin sì wí pé, ‘Absalomu jẹ ọba ní Hebroni.’”
11 Z Absalomem wyruszyło dwustu zaproszonych mężczyzn z Jerozolimy, którzy szli w swojej prostocie, nie wiedząc o niczym.
Igba ọkùnrin sì bá Absalomu ti Jerusalẹmu jáde, nínú àwọn tí a ti pè; wọ́n sì lọ nínú àìmọ̀kan wọn, wọn kò sì mọ nǹkan kan.
12 Gdy Absalom składał ofiary, wezwał [on] także Achitofela, Gilonitę, doradcę Dawida, z jego miasta Gilo. I spisek się wzmagał, bo coraz więcej ludzi przystawało do Absaloma.
Absalomu sì ránṣẹ́ pe Ahitofeli ará Giloni, ìgbìmọ̀ Dafidi, láti ìlú rẹ̀ wá, àní láti Giloni, nígbà tí ó ń rú ẹbọ. Ìdìmọ̀lù náà sì le; àwọn ènìyàn sì ń pọ̀ sọ́dọ̀ Absalomu.
13 Potem do Dawida przyszedł posłaniec, mówiąc: Serca ludzi Izraela zwróciły się do Absaloma.
Ẹnìkan sì wá rò fún Dafidi pé, “Ọkàn àwọn ọkùnrin Israẹli ṣí sí Absalomu.”
14 Wtedy Dawid powiedział do wszystkich swoich sług, którzy byli z nim w Jerozolimie: Wstańcie i uciekajmy, bo inaczej nie ujdziemy przed Absalomem. Spieszcie się z wymarszem, żeby czasem nie dopadł nas znienacka, nie sprowadził na nas nieszczęścia i nie wytępił miasta ostrzem miecza.
Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wá lọ́dọ̀ rẹ̀ ni Jerusalẹmu pé, “Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a sálọ, nítorí pé kò sí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ Absalomu; ẹ yára, kí a lọ kúrò, kí òun má bá à yára lé wa bá, kí ó má sì mú ibi bá wa, kí ó má sì fi ojú idà pa ìlú run.”
15 Słudzy króla powiedzieli do niego: Wszystko, co postanowi nasz pan, król, oto twoi słudzy uczynią.
Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa wa ọba ń fẹ́, wò ó, àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ ti murá.”
16 Król wyszedł więc pieszo, a z nim cały jego dom. Król zostawił jednak dziesięć kobiet, nałożnic, aby pilnowały domu.
Ọba sì jáde, gbogbo ilé rẹ̀ sì tẹ̀lé e. Ọba sì fì mẹ́wàá nínú àwọn obìnrin rẹ̀ sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé.
17 A gdy król wyszedł pieszo wraz z całym ludem, zatrzymali się w pewnym odległym miejscu.
Ọba sì jáde, gbogbo ènìyàn sì tẹ̀lé e, wọ́n sì dúró ní ibìkan tí ó jìnnà.
18 Wszyscy jego słudzy szli przy nim, a wszyscy Keretyci, wszyscy Peletyci, wszyscy Gittyci, w liczbie sześciuset mężczyzn, którzy przyszli za nim z Gat, przeszli przed królem.
Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì kọjá sí iwájú rẹ̀, àti gbogbo àwọn Kereti, àti gbogbo àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ará Gitti, ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Gati wá, sì kọjá níwájú ọba.
19 Wtedy król zapytał Ittaja Gittytę: Czemu i ty idziesz z nami? Wróć do siebie i pozostań przy królu. Jesteś bowiem cudzoziemcem, a nawet wygnańcem.
Ọba sì wí fún Ittai ará Gitti pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá wa lọ pẹ̀lú, padà, kí o sì ba ọba jókòó; nítorí pé àlejò ni ìwọ, ìwọ sì ti fi ìlú rẹ sílẹ̀.
20 Dopiero wczoraj przyszedłeś, a dziś miałbym cię zabrać, abyś się tułał z nami? Skoro sam nie wiem, dokąd idę, ty wróć i odprowadź swoich braci. [Niech będą] z tobą miłosierdzie i prawda.
Lánàá yìí ni ìwọ dé, èmi ó ha sì mú kí ìwọ máa bá wá lọ káàkiri lónìí bí? Èmi ń lọ sí ibikíbi tí mo bá rí: padà, kí o sì mú àwọn arákùnrin rẹ padà, kí àánú àti òtítọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
21 Ale Ittaj odpowiedział królowi: Jak żyje PAN i jak żyje mój pan, król, gdziekolwiek będzie mój pan, król, czy to na śmierć, czy na życie, tam też będzie twój sługa.
Ittai sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ láààyè, àti bí olúwa mi ọba ti ń bẹ láààyè, nítòótọ́ níbikíbi tí olúwa mi ọba bá gbé wà, ìbá à ṣe nínú ikú, tàbí nínú ìyè, níbẹ̀ pẹ̀lú ni ìránṣẹ́ rẹ yóò gbé wà.”
22 I Dawid powiedział do Ittaja: Idź więc i przejdź. Przeszedł więc Ittaj Gittyta i wszyscy jego mężczyźni, i wszystkie dzieci, które z nim [były].
Dafidi sì wí fún Ittai pé, “Lọ kí o sì rékọjá!” Ittai ará Gitti náà sì rékọjá, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
23 I cała ziemia głośno płakała, cały lud zaś przeszedł. Potem sam król przeszedł przez potok Cedron i w ten sposób cały lud przeszedł, i [skierował się] na drogę ku pustyni.
Gbogbo ìlú náà sì fi ohùn rara sọkún, gbogbo ènìyàn sì rékọjá; ọba sì rékọjá àfonífojì Kidironi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì rékọjá, sí ìhà ọ̀nà ijù.
24 A oto [był] z nim i Sadok, i wszyscy Lewici niosący arkę przymierza Boga. Postawili arkę Boga, a Abiatar wstąpił, aż cały lud wyszedł z miasta.
Sì wò ó, Sadoku pẹ̀lú àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ń ru àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà sọ̀kalẹ̀; Abiatari sí gòkè, títí gbogbo àwọn ènìyàn sì fi dẹ́kun àti máa kọjá láti ìlú wá.
25 Potem król powiedział do Sadoka: Odnieś arkę Boga do miasta. Jeśli znajdę łaskę w oczach PANA, to przywróci mnie i pokaże mi ją oraz jej przybytek.
Ọba sì wí fún Sadoku pé, “Sì tún gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà padà sí ìlú, bí èmi bá rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa, yóò sì tún mú mi padà wá, yóò sì fi àpótí ẹ̀rí náà hàn mí àti ibùgbé rẹ̀.
26 Ale jeśli powie: Nie mam w tobie upodobania – oto jestem, niech mi uczyni, co jest dobre w jego oczach.
Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nìyìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”
27 Król powiedział jeszcze do kapłana Sadoka: Czy nie jesteś widzącym? Wróć do miasta w pokoju wraz ze swoimi dwoma synami – Achimaasem, twoim synem, i Jonatanem, synem Abiatara.
Ọba sì wí fún Sadoku àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Ahimasi ọmọ rẹ, àti Jonatani ọmọ Abiatari.
28 Oto będę czekał na równinach pustyni, dopóki nie nadejdzie od was słowo dające mi znać.
Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”
29 Sadok i Abiatar odnieśli więc arkę Boga do Jerozolimy i tam pozostali.
Sadoku àti Abiatari sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé ibẹ̀.
30 Dawid zaś wstępował na Górę Oliwną, wstępował i płakał, a głowę miał zakrytą i szedł boso. Cały lud, który był z nim, każdy z nakrytą głową, wstępował i płakał.
Dafidi sì ń gòkè lọ ní òkè igi olifi, o sì ń sọkún bí ó ti ń gòkè lọ, ó sì bo orí rẹ̀, ó ń lọ láìní bàtà ní ẹsẹ̀, gbogbo ènìyàn tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀, olúkúlùkù ọkùnrin sì bo orí rẹ̀, wọ́n sì ń gòkè lọ, wọ́n ń sọkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ.
31 Wtedy doniesiono Dawidowi: Achitofel [jest] wśród spiskowców z Absalomem. Dawid powiedział: O PANIE, proszę, obróć w głupstwo radę Achitofela.
Ẹnìkan sì sọ fún Dafidi pé, “Ahitofeli wà nínú àwọn aṣọ̀tẹ̀ pẹ̀lú Absalomu.” Dafidi sì wí pé, “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, sọ ìmọ̀ Ahitofeli di asán.”
32 Kiedy Dawid dotarł na szczyt [góry], gdzie oddał pokłon Bogu, oto wyszedł mu na spotkanie Chuszaj Arkita w rozdartej szacie i z prochem na głowie.
Ó sì ṣe, Dafidi dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Huṣai ará Arki sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.
33 Dawid powiedział do niego: Jeśli pójdziesz ze mną, będziesz mi ciężarem;
Dafidi sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.
34 Lecz jeśli wrócisz do miasta i powiesz Absalomowi: Królu, będę twoim sługą. Jak byłem dotąd sługą twego ojca, tak teraz będę twoim sługą – wtedy na moją korzyść obrócisz wniwecz radę Achitofela.
Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Absalomu pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtijọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísinsin yìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Ahitofeli jẹ́.
35 Czyż nie ma tam z tobą kapłanów Sadoka i Abiatara? Cokolwiek więc usłyszysz z domu króla, doniesiesz [o tym] kapłanom Sadokowi i Abiatarowi.
Ṣé Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà.
36 Oto są tam też z nimi ich dwaj synowie, Achimaas, syn Sadoka, i Jonatan, syn Abiatara. Przez nich przyślecie do mnie każde słowo, które usłyszycie.
Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Ahimasi ọmọ Sadoku, àti Jonatani ọmọ Abiatari; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yin ó sì rán ohunkóhun tí ẹ̀yin bá gbọ́ sí mi.”
37 Przybył więc Chuszaj, przyjaciel Dawida, do miasta, a Absalom także wjechał do Jerozolimy.
Huṣai ọ̀rẹ́ Dafidi sì wá sí ìlú, Absalomu sì wá sí Jerusalẹmu.