< II Samuela 13 >
1 Później stało się tak: Absalom, syn Dawida, miał piękną siostrę imieniem Tamar. I zakochał się w niej Amnon, syn Dawida.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Absalomu ọmọ Dafidi ní àbúrò obìnrin kan tí ó ṣe arẹwà, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Tamari; Amnoni ọmọ Dafidi sì fẹ́ràn rẹ̀.
2 I dręczył się Amnon tak, że zachorował z powodu swojej siostry Tamar. Była bowiem dziewicą i Amnonowi zdawało się rzeczą trudną, aby uczynić jej cokolwiek.
Amnoni sì banújẹ́ títí ó fi ṣe àìsàn nítorí Tamari àbúrò rẹ̀ obìnrin; nítorí pé wúńdíá ni; ó sì ṣe ohun tí ó ṣòro lójú Amnoni láti bá a dàpọ̀.
3 Lecz Amnon miał przyjaciela imieniem Jonadab, syna Szimy, brata Dawida. A Jonadab był człowiekiem bardzo przebiegłym.
Ṣùgbọ́n Amnoni ní ọ̀rẹ́ kan, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Jonadabu, ọmọ Ṣimea ẹ̀gbọ́n Dafidi, Jonadabu sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn gidigidi.
4 Ten go zapytał: Dlaczego ty, synu królewski, tak mizerniejesz z dnia na dzień? Dlaczego mi nic nie mówisz? Amnon odpowiedział: Zakochałem się w Tamar, siostrze mojego brata Absaloma.
Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ ọmọ ọba ń fi ń rù lójoojúmọ́ báyìí? Ǹjẹ́ o kò ní sọ fún mi?” Amnoni sì wí fún un pé, “Èmi fẹ́ Tamari àbúrò Absalomu arákùnrin mi.”
5 Jonadab powiedział mu: Połóż się do łóżka i udawaj chorego. Gdy twój ojciec przyjdzie, aby cię odwiedzić, powiesz mu: Pozwól, proszę, aby przyszła moja siostra Tamar i dała mi jeść, aby przygotowała posiłek na moich oczach, bym to widział i jadł z jej ręki.
Jonadabu sì wí fún un pé, “Dùbúlẹ̀ ní ibùsùn rẹ kí ìwọ sì díbọ́n pé, ìwọ kò sàn, baba rẹ yóò sì wá wò ọ́, ìwọ ó sì wí fún un pé, ‘Jọ̀wọ́ jẹ́ kí Tamari àbúrò mi wá kí ó sì fún mi ní oúnjẹ kí ó sì ṣe oúnjẹ náà níwájú mi kí èmi ó rí i, èmi ó sì jẹ ẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀.’”
6 Amnon położył się więc i udawał chorego. A gdy król przyszedł go odwiedzić, Amnon powiedział do króla: Pozwól, proszę, aby moja siostra Tamar przyszła i przygotowała na moich oczach dwa placki, abym jadł z jej ręki.
Amnoni sì dùbúlẹ̀, ó sì díbọ́n pé òun ṣàìsàn, ọba sì wá wò ó, Amnoni sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, jẹ́ kí Tamari àbúrò mi ó wá, kí ó sì dín àkàrà méjì lójú mi, èmi ó sì jẹ ní ọwọ́ rẹ̀.”
7 Wtedy Dawid posłał Tamar do domu, mówiąc: Idź teraz do domu twego brata Amnona i przygotuj mu posiłek.
Dafidi sì ránṣẹ́ sí Tamari ní ilé pé, “Lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ, kí ó sì se oúnjẹ fún un.”
8 Tamar przyszła więc do domu swego brata Amnona, a on leżał. Wzięła mąkę i zagniotła [ciasto], po czym uczyniła placki na jego oczach i upiekła je.
Tamari sì lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀, òun sì ń bẹ ní ìdùbúlẹ̀. Tamari sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà lójú rẹ̀, ó sì dín àkàrà náà.
9 Potem wzięła patelnię i wyłożyła [je] przed nim, lecz nie chciał jeść. I Amnon rozkazał: Niech wszyscy wyjdą ode mnie. Wszyscy wyszli więc od niego.
Òun sì mú àwo náà, ó sì dà á sínú àwo mìíràn níwájú rẹ̀; ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti jẹ. Amnoni sì wí pé, “Jẹ́ kí gbogbo ọkùnrin jáde kúrò lọ́dọ̀ mi!” Wọ́n sì jáde olúkúlùkù ọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
10 Wtedy Amnon powiedział do Tamar: Przynieś jedzenie do sypialni, abym jadł z twojej ręki. Tamar wzięła więc placki, które przyrządziła, i przyniosła je swemu bratu Amnonowi do sypialni.
Amnoni sì wí fún Tamari pé, “Mú oúnjẹ náà wá sí yàrá, èmi ó sì jẹ ẹ́ lọ́wọ́ rẹ.” Tamari sì mú àkàrà tí ó ṣe, ó sì mú un tọ Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ní yàrá.
11 A gdy podawała mu [je] do jedzenia, pochwycił ją i powiedział do niej: Chodź, połóż się ze mną, moja siostro.
Nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti fi oúnjẹ fún un, òun sì dìímú, ó sì wí fún un pé, “Wá dùbúlẹ̀ tì mí, àbúrò mi.”
12 Ona mu odpowiedziała: Nie, mój bracie, nie hańb mnie, bo tak się nie postępuje w Izraelu. Nie popełniaj tego haniebnego czynu.
Òun sì dá a lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀gbọ́n mi, má ṣe tẹ́ mi; nítorí pé kò tọ kí a ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ní Israẹli, ìwọ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
13 Dokąd bowiem się udam ze swoją hańbą? A ty staniesz się jak jeden z [ludzi] nikczemnych w Izraelu. Proszę, porozmawiaj raczej z królem, bo on ci mnie nie odmówi.
Àti èmi, níbo ni èmi ó gbé ìtìjú mi wọ̀? Ìwọ ó sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn aṣiwèrè ní Israẹli. Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́, sọ fún ọba; nítorí pé òun kì yóò kọ̀ láti fi mí fún ọ.”
14 Lecz on nie chciał posłuchać jej głosu, ale przemógł ją i zhańbił, i położył się z nią.
Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti gbọ́ ohùn rẹ̀; ó sì fi agbára mú un, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀, ó sì bá a dàpọ̀.
15 Potem Amnon znienawidził ją tak bardzo, że nienawiść, którą ją znienawidził, była większa niż miłość, jaką ją miłował. I Amnon powiedział jej: Wstań, idź stąd!
Amnoni sì kórìíra rẹ̀ gidigidi, ìríra náà sì wá ju ìfẹ́ tí òun ti ní sí i rí lọ. Amnoni sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ!”
16 Odpowiedziała: Z jakiego powodu? Wyrzucając mnie, czynisz [mi] większą krzywdę niż ta, którą już wyrządziłeś. Ale nie chciał jej posłuchać.
Òun sì wí fún un pé, “Kó ha ní ìdí bí! Lílé tí ìwọ ń lé mi yìí burú ju èyí tí ìwọ ti ṣe sí mi lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀.
17 Wtedy zawołał swego sługę, który mu usługiwał, i rozkazał: Wyprowadź tę [kobietę] ode mnie i zarygluj za nią drzwi.
Òun sì pe ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́, ti obìnrin yìí sóde fún mi, kí o sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.”
18 A miała na sobie kolorową suknię, gdyż w takie szaty ubierały się córki króla, które były dziewicami. Wtedy jego sługa wyprowadził ją i zaryglował za nią drzwi.
Òun sì ní aṣọ aláràbarà kan lára rẹ̀, nítorí irú aṣọ àwọ̀lékè bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọbìnrin ọba tí í ṣe wúńdíá máa ń wọ̀. Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì mú un jáde, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.
19 I Tamar posypała swą głowę popiołem, rozdarła kolorową suknię, którą [nosiła], położyła rękę na głowie i odeszła, głośno płacząc.
Tamari sì bu eérú sí orí rẹ̀, ó sì fa aṣọ aláràbarà tí ń bẹ lára rẹ̀ ya, ó sì ká ọwọ́ rẹ̀ lé orí, ó sì ń kígbe bí ó ti ń lọ.
20 Wtedy jej brat Absalom zapytał ją: Czy twój brat Amnon był z tobą? [Ale] milcz, moja siostro. To twój brat. Nie bierz tego do serca. Tamar mieszkała więc w osamotnieniu w domu swego brata Absaloma.
Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ sì bí i léèrè pé, “Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ bá ọ sùn bí? Ǹjẹ́ àbúrò mi, dákẹ́; ẹ̀gbọ́n rẹ ní í ṣe; má fi nǹkan yìí sí ọkàn rẹ.” Tamari sì jókòó ní ìbànújẹ́ ní ilé Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
21 Gdy król Dawid usłyszał o tym wszystkim, bardzo się rozgniewał.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Dafidi ọba gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi.
22 Absalom zaś nie rozmawiał z Amnonem ani źle, ani dobrze. Absalom bowiem nienawidził Amnona za to, że zhańbił jego siostrę Tamar.
Absalomu kò sì bá Amnoni sọ nǹkan rere, tàbí búburú, nítorí pé Absalomu kórìíra Amnoni nítorí èyí tí ó ṣe, àní tí ó fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
23 Po upływie dwóch lat, gdy strzyżono [owce] Absaloma w Baal-Chasor, które znajduje się w pobliżu Efraim, Absalom zaprosił wszystkich synów króla.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọdún méjì, Absalomu sì ní olùrẹ́run àgùntàn ní Baali-Hasori, èyí tí ó gbé Efraimu, Absalomu sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba.
24 Absalom przyszedł do króla i powiedział: Oto teraz strzygą [owce] twemu słudze. Proszę, niech król i jego słudzy pójdą z twoim sługą.
Absalomu sì tọ ọba wá, ó sì wí pé, “Wò ó, jọ̀wọ́, ìránṣẹ́ rẹ ní olùrẹ́run àgùntàn, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ọba, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá ìránṣẹ́ rẹ lọ.”
25 Lecz król powiedział do Absaloma: Nie, mój synu. Teraz nie pójdziemy wszyscy, aby nie być dla ciebie ciężarem. A chociaż nalegał na niego, on nie chciał iść, ale go błogosławił.
Ọba sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ, ọmọ mi, mo bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí gbogbo wa lọ, kí a má bá à mú ọ náwó púpọ̀.” Ó sì rọ̀ ọ́ gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ lọ, òun sì súre fún un.
26 Wtedy Absalom powiedział: Jeśli nie, proszę, niech pójdzie z nami mój brat Amnon. Król zapytał go: Po cóż miałby iść z tobą?
Absalomu sì wí pé, “Bí kò bá le rí bẹ́ẹ̀, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí Amnoni ẹ̀gbọ́n mi bá wa lọ.” Ọba sì wí pé, “Ìdí rẹ̀ tí yóò fi bá ọ lọ.”
27 A gdy Absalom nalegał na niego, posłał z nim Amnona i wszystkich synów króla.
Absalomu sì rọ̀ ọ́, òun sì jẹ́ kí Amnoni àti gbogbo àwọn ọmọ ọba bá a lọ.
28 Absalom zaś nakazał swoim sługom: Zauważcie, kiedy serce Amnona podochoci się winem, a gdy powiem wam: Zabijcie Amnona, zabijcie go, nie bójcie się. Ja bowiem nakazuję to wam. Bądźcie odważni i sprawcie się dzielnie.
Absalomu sì fi àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Kí ẹ̀yin máa kíyèsi àkókò tí ọtí-wáinì yóò mú ọkàn Amnoni dùn, èmi ó sì wí fún yín pé, ‘Kọlu Amnoni,’ kí ẹ sì pa á. Ẹ má bẹ̀rù. Ṣé èmi ni ó fi àṣẹ fún yin? Ẹ ṣe gírí, kí ẹ ṣe bí alágbára ọmọ.”
29 I słudzy Absaloma uczynili z Amnonem tak, jak im nakazał Absalom. Wtedy wszyscy synowie króla wstali, każdy z nich dosiadł swego muła, i uciekli.
Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì ṣe sí Amnoni gẹ́gẹ́ bí Absalomu ti pàṣẹ. Gbogbo àwọn ọmọ ọba sì dìde, olúkúlùkù gun ìbáaka rẹ̀, wọ́n sì sá.
30 A gdy jeszcze byli w drodze, dotarła do Dawida wieść: Absalom pozabijał wszystkich synów króla i nie pozostał z nich ani jeden.
Nígbà tí wọ́n ń bẹ lọ́nà, ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Dafidi pé, “Absalomu pa gbogbo àwọn ọmọ ọba, ọ̀kan kò sì kù nínú wọn.”
31 Wtedy król wstał i rozdarł swoje szaty, i położył się na ziemi. Wszyscy jego słudzy stali dokoła niego w rozdartych szatach.
Ọba sì dìde, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dùbúlẹ̀ ni ilẹ̀; gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n dúró tì í sì fà aṣọ wọn ya.
32 Wtedy odezwał się Jonadab, syn Szimy, brata Dawida: Niech mój pan nie myśli, [że] zabito wszystkich młodzieńców, synów króla, bo tylko Amnon został zabity. Takie bowiem było postanowienie w umyśle Absaloma od tego dnia, w którym zhańbił jego siostrę Tamar.
Jonadabu ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì dáhùn ó sì wí pé, “Kí olúwa mi ọba má ṣe rò pé wọ́n ti pa gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin àwọn ọmọ ọba; nítorí pé Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú, nítorí láti ẹnu Absalomu wá ni a ti pinnu rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
33 Teraz więc niech mój pan, król, nie dopuszcza tego do serca, myśląc, że zginęli wszyscy synowie króla, gdyż tylko Amnon zginął.
Ǹjẹ́ kí olúwa mi ọba má ṣe fi nǹkan yìí sí ọkàn pé gbogbo àwọn ọmọ ọba ni o kú, nítorí Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú.”
34 Absalom zaś uciekł. A gdy młodzieniec pełniący straż podniósł oczy i spojrzał, oto za nim mnóstwo ludzi przychodziło drogą ze zbocza góry.
Absalomu sì sá. Ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ń ṣọ́nà sì gbé ojú rẹ̀ sókè, o si rí i pé, “Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń bọ́ lọ́nà lẹ́yìn rẹ̀ láti ìhà òkè wá.”
35 I Jonadab powiedział do króla: Oto synowie króla nadchodzą. Stało się tak, jak twój sługa powiedział.
Jonadabu sì wí fún ọba pé, “Wò ó, àwọn ọmọ ọba ń bọ́; gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí.”
36 A gdy przestał mówić, oto przybyli synowie króla, podnieśli głos i płakali. Król i wszyscy jego słudzy również gorzko płakali.
Nígbà tí ó sì parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ, sì wò ó àwọn ọmọ ọba dé, wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún, ọba àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú sì sọkún ńlá ńlá.
37 Absalom zaś uciekł i poszedł do Talmaja, syna Ammihuda, króla Geszur. A [Dawid] opłakiwał swego syna przez wszystkie te dni.
Absalomu sì sá, ó sì tọ Talmai lọ, ọmọ Ammihudu, ọba Geṣuri. Dafidi sì ń káàánú nítorí ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́.
38 Absalom uciekł więc i przyszedł do Geszur, gdzie przebywał przez trzy lata.
Absalomu sì sá, ó sì lọ sí Geṣuri ó sì gbé ibẹ̀ lọ́dún mẹ́ta.
39 Potem król Dawid zapragnął zobaczyć Absaloma. Był już bowiem pocieszony po śmierci Amnona.
Ọkàn Dafidi ọba sì fà gidigidi sí Absalomu, nítorí tí ó tí gba ìpẹ̀ ní ti Amnoni: ó sá à ti kú.