< II Królewska 2 >
1 I kiedy PAN miał unieść Eliasza wśród wichru do nieba, Eliasz wyruszył z Elizeuszem z Gilgal.
Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
2 I Eliasz powiedział do Elizeusza: Proszę, zostań tu, bo PAN posyła mnie do Betel. Elizeusz odpowiedział: Jak żyje PAN i jak żyje twoja dusza, nie opuszczę cię. Przyszli więc do Betel.
Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
3 Wtedy synowie proroków, którzy [byli] w Betel, wyszli do Elizeusza i zapytali go: Czy wiesz, że PAN dzisiaj zabierze twego pana znad twojej głowy? Odpowiedział: Wiem, [lecz] milczcie.
Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
4 A Eliasz ponownie powiedział mu: Elizeuszu, proszę, zostań tu, bo PAN posyła mnie do Jerycha. Odpowiedział: Jak żyje PAN i jak żyje twoja dusza, nie opuszczę cię. Przyszli więc do Jerycha.
Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
5 Wtedy synowie proroków, którzy byli w Jerychu, zapytali Elizeusza: Czy wiesz, że PAN dzisiaj zabierze twego pana znad twojej głowy? Odpowiedział: Tak, wiem, lecz milczcie.
Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
6 Eliasz znowu powiedział mu: Proszę, zostań tu, bo PAN posyła mnie do Jordanu. Odpowiedział: Jak żyje PAN i jak żyje twoja dusza, nie opuszczę cię. Szli więc dalej obydwaj.
Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
7 A pięćdziesięciu mężów spośród synów proroków poszło i stanęło naprzeciwko [nich] z daleka. Oni zaś obaj stanęli nad Jordanem.
Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
8 Wtedy Eliasz wziął swój płaszcz, zwinął go i uderzył nim wody, a one rozdzieliły się w obydwie strony, tak że przeszli obaj po suchej ziemi.
Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
9 A gdy przeszli, Eliasz powiedział do Elizeusza: Proś [o to], co mam dla ciebie uczynić, zanim będę od ciebie zabrany. Elizeusz odpowiedział: Proszę, niech spocznie na mnie podwójna część twojego ducha;
Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
10 On zaś powiedział: Poprosiłeś o trudną rzecz. Jeśli mnie zobaczysz, gdy będę zabierany od ciebie, tak ci się stanie. Lecz jeśli nie, to się nie stanie.
“Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
11 Kiedy więc szli i rozmawiali, oto ognisty rydwan i ogniste konie oddzieliły ich obu. I Eliasz wstąpił wśród wichru do nieba.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
12 Elizeusz zaś zobaczył to i zawołał: Mój ojcze, mój ojcze! Rydwanie Izraela i jego jeźdźcze. I nie zobaczył go już więcej. Chwycił swoje szaty i rozdarł je na dwie części.
Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
13 Potem podniósł płaszcz Eliasza, który spadł z niego, zawrócił i stanął nad brzegiem Jordanu;
Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
14 I wziął płaszcz Eliasza, który spadł z niego, uderzył nim wody i powiedział: Gdzie jest PAN, Bóg Eliasza? Również gdy on uderzył nim wody, rozdzieliły się na dwie strony. I Elizeusz przeszedł.
Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
15 A gdy synowie proroków, którzy [byli] w Jerychu, zobaczyli go z naprzeciwka, powiedzieli: Duch Eliasza spoczął na Elizeuszu. Wyruszyli mu więc naprzeciw i pokłonili mu się aż do ziemi.
Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
16 I powiedzieli do niego: Oto teraz wśród twoich sług jest pięćdziesięciu dzielnych mężczyzn. Proszę, niech idą i niech szukają twego pana; może Duch PANA uniósł go i spuścił na jakąś górę albo w jakąś dolinę. Lecz on powiedział: Nie posyłajcie.
“Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
17 A gdy tak nalegali, aż do uprzykrzenia, powiedział: Poślijcie. Posłali więc tych pięćdziesięciu mężczyzn, którzy szukali przez trzy dni, lecz nie znaleźli go.
Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
18 A gdy wrócili do niego – bo przebywał w Jerychu – powiedział do nich: Czyż nie mówiłem wam: Nie idźcie?
Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
19 Potem ludzie tego miasta powiedzieli do Elizeusza: Oto położenie tego miasta jest dobre – jak ty, mój panie, widzisz. Lecz woda jest niedobra i ziemia nieurodzajna.
Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
20 Wtedy powiedział: Przynieście mi nowy dzbanek i włóżcie do niego soli. I przynieśli mu.
Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
21 Wówczas poszedł do źródła wód, wrzucił do niego sól i powiedział: Tak mówi PAN: Uzdrowiłem te wody, już nie wyjdzie stąd ani śmierć, ani nieurodzaj.
Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
22 Wody więc zostały uzdrowione [i są takie] aż do dziś, według słowa Elizeusza, które wypowiedział.
Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
23 Potem wyruszył stamtąd do Betel. A gdy podążał drogą, małe dzieci wyszły z miasta i naśmiewały się z niego, mówiąc mu: Wstąp łysy, wstąp łysy!
Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
24 On zaś odwrócił się, spojrzał na nie i przeklął je w imieniu PANA. Wtedy dwie niedźwiedzice wyszły z lasu i rozszarpały czterdzieścioro dwoje dzieci spośród nich.
Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
25 Stamtąd poszedł na górę Karmel, skąd wrócił do Samarii.
Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.