< II Królewska 13 >
1 W dwudziestym trzecim roku Joasza, syna Achazjasza, króla Judy, Jehoachaz, syn Jehu, zaczął królować nad Izraelem w Samarii [i królował] siedemnaście lat.
Ní ọdún kẹtàlélógún ti Joaṣi ọmọ ọba Ahasiah ti Juda, Jehoahasi ọmọ Jehu di ọba Israẹli ní Samaria. Ó sì jẹ ọba fún ọdún mẹ́tàdínlógún.
2 A czynił to, co złe w oczach PANA, naśladując grzechy Jeroboama, syna Nebata, który przywiódł Izraela do grzechu, [i] nie odstąpił od nich.
Ó ṣe búburú níwájú Olúwa nípa títẹ̀lé ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá, kò sì yípadà kúrò nínú wọn.
3 I zapalił się gniew PANA przeciw Izraelowi, i wydał go w rękę Chazaela, króla Syrii, i w rękę Ben-Hadada, syna Chazaela, po wszystkie [ich] dni.
Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli, àti fún ìgbà pípẹ́, ó fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ agbára ọba Hasaeli ọba Siria àti Beni-Hadadi ọmọ rẹ̀.
4 Ale gdy Jehoachaz błagał PANA, PAN go wysłuchał. Widział bowiem ucisk Izraela dręczonego przez króla Syrii.
Nígbà náà Jehoahasi kígbe ó wá ojúrere Olúwa, Olúwa sì tẹ́tí sí i. Nítorí ó rí bí ọba Siria ti ń ni Israẹli lára gidigidi.
5 I PAN dał Izraelowi wybawcę, tak że wyszli spod ręki Syryjczyków, i synowie Izraela mieszkali w swoich namiotach jak dawniej.
Olúwa pèsè olùgbàlà fún Israẹli, wọ́n sì sá kúrò lọ́wọ́ agbára Siria. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli gbé nínú ilé ara wọn gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti wà tẹ́lẹ̀.
6 Jednakże nie odstąpili od grzechów domu Jeroboama, który przywiódł Izraela do grzechu, ale chodzili w nich. A do tego jeszcze w Samarii został gaj.
Ṣùgbọ́n wọn kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jeroboamu, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá, wọ́n tẹ̀síwájú nínú rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah sì wà síbẹ̀ ní Samaria pẹ̀lú.
7 I Jehoachazowi nie pozostało więcej wojska jak tylko pięćdziesięciu jeźdźców, dziesięć rydwanów i dziesięć tysięcy pieszych, gdyż król Syrii wytracił ich i starł w proch.
Kò sí ohùn kan tí wọ́n fi sílẹ̀ ní ti ọmọ-ogun Jehoahasi àyàfi àádọ́ta ọkùnrin ẹlẹ́ṣin, kẹ̀kẹ́ mẹ́wàá, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀, nítorí ọba Siria ti pa ìyókù run, ó sì ṣe wọ́n bí eruku nígbà pípa ọkà.
8 A pozostałe dzieje Jehoachaza i wszystko, co czynił, oraz jego potęga, czy nie są zapisane w kronikach królów Izraela?
Fún ti ìyókù ìṣe Jehoahasi fún ìgbà, tí ó fi jẹ ọba, gbogbo ohun tí ó ṣe àti àṣeyọrí rẹ̀ ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
9 I Jehoachaz zasnął ze swymi ojcami, i pogrzebano go w Samarii, a jego syn Joasz królował w jego miejsce.
Jehoahasi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sí Samaria. Jehoaṣi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
10 W trzydziestym siódmym roku Joasza, króla Judy, Jehoasz, syn Jehoachaza, zaczął królować nad Izraelem w Samarii [i królował] szesnaście lat;
Ní ọdún kẹtàdínlógójì tí Joaṣi ọba Juda, Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi di ọba Israẹli ní Samaria ó sì jẹ ọba fún ọdún mẹ́rìndínlógún.
11 I czynił to, co złe w oczach PANA, nie odstępując od żadnych grzechów Jeroboama, syna Nebata, który przywiódł Izraela do grzechu – ale chodząc w nich.
Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, kò sì yípadà kúrò nínú ọ̀kankan nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati èyí tí ó ti ti Israẹli láti fà. Ó sì tẹ̀síwájú nínú wọn.
12 A pozostałe dzieje Joasza i wszystko, co czynił, oraz jego potęga – [to], jak walczył z Amazjaszem, królem Judy, czy nie są zapisane w kronikach królów Izraela?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ Jehoaṣi fún ìgbà tí ó fi jẹ ọba, gbogbo ohun tí ó ṣe, pẹ̀lú àṣeyọrí rẹ̀ pẹ̀lú ogun rẹ̀ sí Amasiah ọba Juda, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
13 I Joasz zasnął ze swymi ojcami, a Jeroboam zasiadł na jego tronie. I Joasz został pogrzebany w Samarii razem z królami Izraela.
Jehoaṣi sinmi pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀. Jeroboamu sì rọ́pò rẹ̀ lórí ìtẹ́. A sin Jehoaṣi sí Samaria pẹ̀lú àwọn ọba Israẹli.
14 A Elizeusz zapadł na ciężką chorobę, na którą [miał] umrzeć. Przyszedł do niego Joasz, król Izraela, i płakał nad nim, mówiąc: Mój ojcze, mój ojcze! Rydwanie Izraela i jego jeźdźcze!
Nísinsin yìí, Eliṣa ń jìyà lọ́wọ́ àìsàn, lọ́wọ́ èyí tí ó sì kú. Jehoaṣi ọba Israẹli lọ láti lọ wò ó, ó sì sọkún lórí rẹ̀. “Baba mi! Baba mi!” Ó sọkún. “Àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin Israẹli!”
15 Wtedy Elizeusz powiedział mu: Weź łuk i strzały. Wziął więc łuk i strzały.
Eliṣa wí pé, “Mú ọrun kan àti àwọn ọfà,” ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
16 Potem powiedział do króla Izraela: Weź łuk w rękę. I wziął go w rękę. Elizeusz zaś położył swoje ręce na ręce króla.
“Mú ọrun ní ọwọ́ rẹ.” Ó wí fún ọba Israẹli. Nígbà tí ó ti mú u, Eliṣa mú ọwọ́ rẹ̀ lé ọwọ́ ọba.
17 I powiedział: Otwórz okno na wschód. A gdy [je] otworzył, Elizeusz polecił: Strzelaj! I strzelił, a on powiedział: Strzała wybawienia PANA i strzała wybawienia od Syryjczyków. Pobijesz bowiem Syryjczyków w Afek doszczętnie.
“Ṣí fèrèsé apá ìlà-oòrùn,” ó wí, pẹ̀lú ó sì ṣí i: “Ta á!” Eliṣa wí, ó sì ta á. “Ọfà ìṣẹ́gun Olúwa; ọfà ìṣẹ́gun lórí Siria!” Eliṣa kéde. “Ìwọ yóò pa àwọn ará Siria run pátápátá ní Afeki.”
18 Następnie powiedział: Weź strzały! I wziął. Wtedy rzekł do króla Izraela: Uderz w ziemię! I uderzył trzy razy, i zaprzestał.
Nígbà náà ó wí pé, “Mú àwọn ọfà náà,” ọba sì mú wọn. Eliṣa wí fún un pé, “Lu ilẹ̀.” Ó lù ú lẹ́ẹ̀mẹ́ta, ó sì dáwọ́ dúró.
19 Wtedy mąż Boży rozgniewał się na niego i powiedział: Trzeba było uderzyć pięć lub sześć razy. Wtedy byś pokonał Syrię doszczętnie. Lecz teraz pokonasz Syrię tylko trzy razy.
Ènìyàn Ọlọ́run sì bínú sí i, ó sì wí pé, “Ìwọ kò bá ti lu ilẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀márùn ún tàbí ní ẹ̀ẹ̀mẹ́fà, nígbà náà, ìwọ kò bá ti ṣẹ́gun Siria àti pa á run pátápátá ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ yóò ṣẹ́gun rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta péré.”
20 Potem Elizeusz umarł i pogrzebali go. A z nastaniem roku moabskie zgraje napadły na ziemię.
Eliṣa kú a sì sin ín. Ẹgbẹ́ àwọn ará Moabu máa ń wọ orílẹ̀-èdè ní gbogbo àmọ́dún.
21 I zdarzyło się, że gdy grzebano [pewnego] człowieka, zobaczyli [taką] zgraję. Wrzucili więc tego człowieka do grobu Elizeusza. A gdy ten człowiek został tam wrzucony, dotknął kości Elizeusza, ożył i wstał na nogi.
Bí àwọn ọmọ Israẹli kan ti ń sin òkú ọkùnrin kan, lójijì wọ́n rí ẹgbẹ́ àwọn oníjadì, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ju òkú ọkùnrin náà sínú ibojì Eliṣa. Nígbà tí ara ọkùnrin náà kan egungun Eliṣa, ó padà wá sí ayé, ó sì dúró ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
22 Chazael zaś, król Syrii, uciskał lud Izraela po wszystkie dni Jehoachaza.
Hasaeli ọba Siria ni Israẹli lára ní gbogbo àkókò tí Jehoahasi fi jẹ ọba.
23 PAN jednak zlitował się nad nimi, był dla nich miłosierny i zwrócił się ku nim ze względu na swoje przymierze z Abrahamem, Izaakiem i Jakubem. Nie chciał ich wytracić ani nie odrzucił ich sprzed swego oblicza aż dotąd.
Ṣùgbọ́n Olúwa ṣàánú fún wọn ó sì ní ìyọ́nú, ó sì fiyèsí wọn nítorí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu. Títí di ọjọ́ òní, kì í ṣe ìfẹ́ inú rẹ̀ láti pa wọ́n run tàbí lé wọn lọ níwájú rẹ̀.
24 I Chazael, król Syrii, umarł, a jego syn Ben-Hadad królował w jego miejsce.
Hasaeli ọba Siria kú, Beni-Hadadi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
25 Jehoasz, syn Jehoachaza, znowu odebrał z ręki Ben-Hadada, syna Chazaela, te miasta, które podczas wojny ten zabrał z ręki jego ojca Jehoachaza. Joasz pokonał go trzy razy i odzyskał miasta Izraela.
Nígbà náà, Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi gbà padà kúrò lọ́wọ́ Beni-Hadadi ọmọ Hasaeli àwọn ìlú tí ó ti gbà nínú ogun látọ̀dọ̀ baba rẹ̀ Jehoahasi. Ní ẹ̀ẹ̀mẹta, Jehoaṣi ṣẹ́gun rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó gba ìlú àwọn ọmọ Israẹli padà.