< II Kronik 24 >
1 Joasz [miał] siedem lat, kiedy zaczął królować, i królował czterdzieści lat w Jerozolimie. Jego matka miała na imię Sibia, [była] z Beer-Szeby.
Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
2 I Joasz czynił [to, co] dobre w oczach PANA, przez wszystkie dni kapłana Jehojady.
Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
3 A Jehojada dał mu dwie żony; i spłodził synów i córki.
Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
4 Potem w sercu Joasza powstał zamiar, aby odnowić dom PANA.
Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
5 Zebrał więc kapłanów i Lewitów i powiedział do nich: Wyjdźcie do miast Judy i zbierajcie od całego Izraela pieniądze na coroczną naprawę domu waszego Boga. Pospieszcie się z tym. Lewici jednak nie spieszyli się.
Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
6 Wówczas król wezwał najwyższego [kapłana] Jehojadę i zapytał go: Czemu nie pilnujesz Lewitów, aby przynosili z Judy i Jerozolimy ofiarę na Namiot Świadectwa [ustanowioną] przez Mojżesza, sługę PANA, i zgromadzenie Izraela?
Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
7 Bezbożna Atalia i jej synowie złupili bowiem dom Boży, a wszystkie rzeczy poświęcone z domu PANA oddali Baalom.
Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
8 Król więc rozkazał, aby wykonano skrzynię i umieszczono ją przed bramą domu PANA.
Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
9 I ogłoszono w Judzie i Jerozolimie, aby przynoszono PANU ofiarę [nałożoną] na Izraela [przez] Mojżesza, sługę Bożego, na pustyni.
A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
10 I radowali się wszyscy książęta oraz cały lud. Przynosili [ją] i rzucali do tej skrzyni, aż ją napełnili.
Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
11 A kiedy Lewici przynosili skrzynię do urzędu królewskiego i gdy widzieli, że [było] już wiele pieniędzy, przychodził pisarz królewski oraz pełnomocnik najwyższego kapłana i wypróżniali skrzynię, a potem ją odnosili z powrotem na swoje miejsce. Tak czynili codziennie i zebrali bardzo dużo pieniędzy.
Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
12 Król i Jehojada dawali je kierownikom robót domu PANA, a ci najmowali kamieniarzy i cieśli do naprawy domu PANA, a także kowali i brązowników – do umocnienia domu PANA.
Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
13 Tak więc robotnicy pracowali i dzięki nim dzieło zostało wykonane. Doprowadzili dom Boży do właściwego stanu i umocnili go.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
14 A gdy skończyli, przynieśli przed króla i Jehojadę resztę pieniędzy, za które sporządzono naczynia do domu PANA: naczynia do służby i składania ofiar, czasze oraz [inne] naczynia złote i srebrne. I nieustannie składali całopalenia w domu PANA przez wszystkie dni Jehojady.
Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
15 Potem Jehojada zestarzał się i umarł, będąc syty dni. Miał sto trzydzieści lat, gdy umarł.
Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
16 I pogrzebano go w mieście Dawida razem z królami, dlatego że czynił dobrze w Izraelu: i względem Boga, i względem jego domu.
Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
17 Po śmierci Jehojady przyszli książęta Judy i pokłonili się królowi. Wtedy król ich usłuchał.
Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
18 Opuścili dom PANA, Boga swoich ojców, i służyli gajom oraz posągom. Spadł więc gniew na Judę i Jerozolimę z powodu tego występku.
Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
19 I posyłał do nich proroków, żeby ich nawrócić do PANA. A [choć] świadczyli przeciwko nim, nie usłuchali ich.
Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
20 Wówczas Duch Boży zstąpił na Zachariasza, syna kapłana Jehojady, który stanął przed ludem i powiedział im: Tak mówi Bóg: Czemu przekraczacie przykazania PANA? Nie powodzi się wam. Skoro wy opuściliście PANA, [on] też was opuścił.
Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’”
21 Wtedy sprzysięgli się przeciwko niemu i ukamienowali go na rozkaz króla na dziedzińcu domu PANA.
Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
22 I nie pamiętał król Joasz o dobrodziejstwie, jakie wyświadczył mu jego ojciec Jehojada, ale zabił jego syna. Kiedy ten umierał, powiedział: Niech PAN [to] zobaczy i zemści się.
Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
23 A po upływie roku przeciwko niemu nadciągnęło wojsko Syrii. Przybyło do Judy i Jerozolimy i wyniszczyło z ludu wszystkich książąt, a wszystkie jego łupy posłano królowi Damaszku.
Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
24 Przybyło bowiem wojsko Syrii z niewielką liczbą ludzi, a PAN wydał w ich ręce bardzo liczne wojsko, dlatego że opuścili PANA, Boga swoich ojców. I tak dokonano sądu nad Joaszem.
Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
25 A gdy się od niego oddalili, zostawiając go w ciężkiej chorobie, jego słudzy sprzysięgli się przeciwko niemu, z powodu krwi synów kapłana Jehojady, i zabili go na jego łożu. [Tak więc] umarł i pogrzebano go w mieście Dawida, ale nie w grobach królewskich.
Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
26 A oto są ci, którzy sprzysięgli się przeciw niemu: Zabad, syn Szimeata, Ammonitki, i Jehozabad, syn Szimrit, Moabitki.
Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
27 O jego synach zaś, o wielkim ciężarze nałożonym na niego i o naprawie domu Bożego, jest zapisane w księdze królewskiej. I królował jego syn Amazjasz w jego miejsce.
Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.