< II Kronik 10 >

1 Roboam udał się do Sychem, gdyż do Sychem przybył cały Izrael, aby ustanowić go królem.
Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu nítorí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi jẹ ọba.
2 A gdy usłyszał o tym Jeroboam, syn Nebata, który był w Egipcie, dokąd uciekł przed królem Salomonem, wrócił z Egiptu;
Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati gbọ́ ẹni ti ó wà ní Ejibiti, níbi tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ ọba Solomoni ó sì padà láti Ejibiti.
3 Wtedy posłano [po niego] i wezwano go. Przyszedł więc Jeroboam wraz z całym Izraelem i powiedzieli do Roboama:
Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà ó sì ránṣẹ́ sí Jeroboamu àti òun àti gbogbo àwọn Israẹli lọ sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu wọ́n sì wí fún pé,
4 Twój ojciec włożył na nas ciężkie jarzmo. Teraz więc [ty] ulżyj [nam] w srogiej niewoli swego ojca i w ciężkim jarzmie, które włożył na nas, a będziemy ci służyć.
“Baba rẹ gbé àjàgà tí ó wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ mú un fúyẹ́, iṣẹ́ líle àti àjàgà wúwo tí ó gbé ka orí wa, àwa yóò sì sìn ọ́.”
5 Odpowiedział im: Wróćcie do mnie po trzech dniach. I lud odszedł.
Rehoboamu sì dáhùn pé, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn náà sì lọ.
6 Wtedy król Roboam radził się starszych, którzy stawali przed Salomonem, jego ojcem, gdy jeszcze żył, pytając: Jaką odpowiedź radzicie dać temu ludowi?
Nígbà náà ni ọba Rehoboamu fi ọ̀ràn lọ̀ àwọn àgbàgbà tí ó ti ń sin baba rẹ̀ Solomoni nígbà ayé rẹ̀, ó sì bi wọ́n léèrè pe, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe gbà mí ní ìmọ̀ràn láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
7 Odpowiedzieli mu: Jeśli będziesz dla tego ludu dobry, okażesz im życzliwość i będziesz mówił do nich łagodne słowa, to będą twoimi sługami przez wszystkie dni.
Wọ́n sì dáhùn, “Tí ìwọ yóò bá ṣe rere sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kí o sì ṣe ìre fún wọn, kí o sì fún wọn ní ìdáhùn rere, wọn yóò sì máa jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nígbà gbogbo.”
8 Ale [on] odrzucił radę starszych, którą mu dali, i radził się młodzieńców, którzy razem z nim wzrośli i stawali przed nim.
Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn náà tí àwọn àgbàgbà fi fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn ọmọ ọkùnrin tí ó ti dàgbàsókè pẹ̀lú rẹ̀ tí wọ́n sì ń dúró níwájú rẹ̀.
9 I zapytał ich: A co wy radzicie odpowiedzieć temu ludowi, który poprosił mnie: Ulżyj nam w jarzmie, które włożył na nas twój ojciec?
Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni kí a ṣe dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Mú kí àjàgà tí baba rẹ gbé lé wa kí ó fúyẹ́ díẹ̀.’”
10 Wtedy młodzieńcy, którzy razem z nim wzrośli, odpowiedzieli mu: Tak odpowiesz temu ludowi, który powiedział tobie: Twój ojciec włożył na nas ciężkie jarzmo, ale ty nam ulżyj; tak im powiesz: Mój mały [palec] jest grubszy niż biodra mojego ojca.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé tí ó ti dàgbà pẹ̀lú rẹ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí ó wí fún ọ wí pé, ‘Baba rẹ gbé àjàgà wúwo lórí wa, ṣùgbọ́n mú àjàgà wa fúyẹ́,’ wí fún wọn pé, ‘Ìka ọwọ́ mi kékeré, ó nípọn ju ìbàdí baba mi lọ.
11 Teraz więc chociaż mój ojciec nałożył na was ciężkie jarzmo, ja dołożę do waszego jarzma. Mój ojciec karcił was biczami, ale ja [będę] was [karcił] skorpionami.
Baba mi gbé àjàgà wúwo ka orí yín; èmi yóò sì tún mú kí ó wúwo sì í. Baba mi fi pàṣán nà yín; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.’”
12 Przyszedł więc Jeroboam i cały lud do Roboama trzeciego dnia, tak jak król nakazał, mówiąc: Wróćcie do mnie na trzeci dzień.
Ní ọjọ́ kẹta Jeroboamu àti gbogbo ènìyàn sì padà sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu, gẹ́gẹ́ bí ọba ti sọ, “Ẹ padà wá sọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ kẹta.”
13 I król odpowiedział im surowo, bo odrzucił król Roboam radę starców.
Nígbà náà ni ọba dá wọn lóhùn ní ọ̀nà líle. Rehoboamu ọba sì kọ̀ ìmọ̀ràn àwọn àgbàgbà sílẹ̀,
14 I przemówił do nich według rady młodzieńców, mówiąc: Mój ojciec obciążył was ciężkim jarzmem, ale ja dołożę do niego. Mój ojciec karcił was biczami, ale ja będę was karcił skorpionami.
Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọ̀dọ́mọdé, ó sì wí pé, “Baba mi mú kí àjàgà yín wúwo; èmi yóò sì mú kí ó wúwo jù bẹ́ẹ̀ lọ. Baba mi nà yín pẹ̀lú pàṣán; èmi yóò sì nà yín pẹ̀lú àkéekèe.”
15 Król więc nie usłuchał ludu, sprawa bowiem wyszła od Boga, aby PAN spełnił swoje słowo, które wypowiedział przez Achiasza Szilonitę do Jeroboama, syna Nebata.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fetísí àwọn ènìyàn, nítorí ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni. Láti mú ọ̀rọ̀ Olúwa ṣẹ tí a ti sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati nípasẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
16 A gdy cały Izrael [zobaczył], że król ich nie usłuchał, lud odpowiedział królowi: Jakiż dział mamy w Dawidzie? Nie mamy dziedzictwa w synu Jessego. [Idźcie] każdy do swoich namiotów, Izraelu! A ty, Dawidzie, troszcz się teraz o swój dom. I rozszedł się cały Izrael do swoich namiotów.
Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i wí pé ọba kọ̀ láti gbọ́ tiwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn wí pé, “Ìpín kí ní a ní nínú Dafidi, ìní wo ni a ní nínú ọmọ Jese? Ẹ lọ sí àgọ́ yín, ẹ̀yin Israẹli! Bojútó ilé rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ní gbogbo àwọn ọmọ Israẹli lọ sí ilé wọn.
17 [Tylko] nad synami Izraela, którzy mieszkali w miastach Judy, królował Roboam.
Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé ní ìlú Juda, Rehoboamu ń jẹ ọba lórí wọn.
18 Wtedy król Roboam posłał do synów Izraela Hadorama, który był poborcą, a [oni] ukamienowali go tak, że umarł. Król Roboam wsiadł więc w pośpiechu na rydwan i uciekł do Jerozolimy.
Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
19 I w ten sposób Izrael zbuntował się przeciwko domowi Dawida aż do dziś.
Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli sì wà ní ìṣọ̀tẹ̀ lórí ilé Dafidi títí fi di òní yìí.

< II Kronik 10 >