< II Kronik 1 >
1 Salomon, syn Dawida, umocnił się w swoim królestwie, a PAN, jego Bóg, [był] z nim i bardzo go wywyższył.
Solomoni ọmọ Dafidi fìdí ara rẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin lórí ìjọba rẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú u rẹ̀, ó sì jẹ́ kí ó ga lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
2 I Salomon przemówił do całego Izraela, do dowódców nad tysiącami, setników i sędziów oraz wszystkich przełożonych nad całym Izraelem, naczelników rodów.
Nígbà náà, Solomoni bá gbogbo Israẹli sọ̀rọ̀ sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún, sí àwọn adájọ́ àti sí gbogbo àwọn olórí Israẹli, àwọn olórí ìdílé
3 Salomon więc poszedł, a z nim całe zgromadzenie, na wyżynę, która [była] w Gibeonie. Tam bowiem znajdował się Namiot Zgromadzenia Bożego, który sporządził Mojżesz, sługa PANA, na pustyni.
pẹ̀lú Solomoni, àti gbogbo àpéjọ lọ sí ibi gíga ní Gibeoni, nítorí àgọ́ Ọlọ́run fún pípàdé wà níbẹ̀, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pa ní aginjù.
4 Ale arkę Boga przeniósł Dawid z Kiriat-Jearim [na miejsce], które dla niej przygotował, bo rozbił namiot dla niej w Jerozolimie.
Nísinsin yìí, Dafidi ti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run wá láti Kiriati-Jearimu sí ibi tí ó ti pèsè fún un, nítorí ó ti kọ́ àgọ́ fún un ni Jerusalẹmu.
5 A także ołtarz z brązu, który zrobił Besaleel, syn Uriego, syna Chura, znajdował się tam przed przybytkiem PANA. I tam udał się po radę Salomon oraz [całe] zgromadzenie.
Ṣùgbọ́n pẹpẹ idẹ tí Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ṣe wà ní Gibeoni níwájú àgọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Solomoni àti gbogbo àpéjọ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ níbẹ̀.
6 I Salomon przystąpił przed PANEM do ołtarza z brązu, który [był] przed Namiotem Zgromadzenia, i złożył na nim tysiąc ofiar całopalnych.
Solomoni gòkè lọ sí ibi pẹpẹ idẹ níwájú Olúwa ní ibi àgọ́ ìpàdé, ó sì rú ẹgbẹ̀rún ẹbọ sísun lórí rẹ̀.
7 Tej samej nocy Bóg ukazał się Salomonowi i powiedział do niego: Proś, o co [chcesz], a dam tobie.
Ní òru ọjọ́ náà, Ọlọ́run farahàn Solomoni, ó sì wí fún un pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́ kí n fún ọ.”
8 Wtedy Salomon powiedział do Boga: Ty okazałeś mojemu ojcu Dawidowi wielkie miłosierdzie i ustanowiłeś mnie królem w jego miejsce.
Solomoni dá Ọlọ́run lóhùn pé, “Ìwọ ti fi àánú ńlá han Dafidi baba mi, ìwọ sì ti fi mí jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
9 A teraz, PANIE Boże, niech się spełni twoje słowo, [które powiedziałeś] do mego ojca Dawida, bo uczyniłeś mnie królem nad ludem, który jest tak liczny, jak proch ziemi.
Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ìlérí rẹ sí baba à mi Dafidi wá sí ìmúṣẹ, nítorí ìwọ ti fi mí jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn tí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀.
10 Daj mi więc mądrość i wiedzę, abym wychodził i wchodził przed tym ludem; któż bowiem zdoła sądzić ten twój lud, [który jest] tak wielki?
Fún mi ní ọgbọ́n àti ìmọ̀, kí èmi kí ó lè máa wọ ilé kí ń sì máa jáde níwájú ènìyàn wọ̀nyí, nítorí ta ni ó le è ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ tí ó pọ̀ yanturu wọ̀nyí?”
11 Wtedy Bóg powiedział do Salomona: Ponieważ było to w twoim sercu, a nie prosiłeś o bogactwo, majętności i sławę ani o śmierć tych, którzy cię nienawidzą, ani też nie prosiłeś o długie życie, ale prosiłeś dla siebie o mądrość i wiedzę, abyś mógł sądzić mój lud, nad którym ustanowiłem cię królem;
Ọlọ́run wí fún Solomoni pé, “Níwọ́n ìgbà tí ó jẹ́ pé ìfẹ́ ọkàn rẹ nìyí, tí ìwọ kò sì béèrè, fún ọrọ̀, ọlá tàbí ọ̀wọ̀, tàbí fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, àti nígbà tí ìwọ kò ti béèrè fún ẹ̀mí gígùn, ṣùgbọ́n tí ìwọ béèrè fún ọgbọ́n àti ìmọ̀ láti ṣàkóso àwọn ènìyàn mi tí èmi fi ọ́ jẹ ọba lé lórí.
12 Mądrość i umiejętność będzie ci dana, ponadto dam ci bogactwo, majętności i sławę, jakich nie miał żaden z królów, którzy byli przed tobą, ani nie będzie miał żaden z tych, którzy po tobie nastąpią.
Nítorí náà, ọgbọ́n àti ìmọ̀ ni a ó fi fún ọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ọrọ̀, ọlá àti ọ̀wọ̀, irú èyí tí ọba ti ó wà ṣáájú rẹ kò ní, tí àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ kò sì ní ní irú rẹ̀.”
13 Salomon wrócił z tej wyżyny, która [była] w Gibeonie, sprzed Namiotu Zgromadzenia, do Jerozolimy i królował nad Izraelem.
Nígbà náà ni Solomoni sì ti ibi gíga Gibeoni lọ sí Jerusalẹmu láti iwájú àgọ́ ìpàdé. Ó sì jẹ ọba lórí Israẹli.
14 I Salomon zgromadził rydwany i jeźdźców, tak że miał tysiąc czterysta rydwanów i dwanaście tysięcy jeźdźców, których rozmieścił w miastach rydwanów i przy sobie w Jerozolimie.
Solomoni kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ, ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin, tí ó kó pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ ogun àti pẹ̀lú rẹ̀ ni Jerusalẹmu.
15 Król złożył w Jerozolimie złota i srebra, jak kamieni, a cedrów złożył jak sykomor, których na równinie rośnie bardzo dużo.
Ọba náà ṣe fàdákà àti wúrà gẹ́gẹ́ bí ó ti wọ́pọ̀ ní Jerusalẹmu bí òkúta, àti kedari ó pọ̀ bí igi sikamore ní àwọn ẹsẹ̀ òkè.
16 Sprowadzono też dla Salomona konie z Egiptu i nić lnianą, bo kupcy króla nabywali ją za określoną cenę.
Àwọn ẹṣin Solomoni ní a gbà láti ìlú òkèrè Ejibiti àti láti kún ọ̀gbọ̀ oníṣòwò ti ọba ni gba okun náà ní iye kan.
17 I wychodzili, i przywozili z Egiptu rydwan za sześćset syklów srebra, a konia za sto pięćdziesiąt. W ten sposób wszyscy królowie chetyccy i królowie Syrii dostawali [je] za ich pośrednictwem.
Wọ́n ra kẹ̀kẹ́ kan láti Ejibiti. Fún ẹgbẹ̀ta ṣékélì fàdákà àti ẹṣin kan fún ọgọ́rin méjìdínláàádọ́ta. Wọ́n ko wọn lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba mìíràn ti Hiti àti ti àwọn ará Aramu.