< I Samuela 6 >

1 I arka PANA przebywała w ziemi Filistynów przez siedem miesięcy.
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
2 Wtedy Filistyni zwołali kapłanów i wróżbitów i zapytali: Co mamy zrobić z arką PANA? Powiedzcie nam, jak mamy ją odesłać na swoje miejsce?
àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
3 Ci odpowiedzieli: Jeśli odsyłacie arkę Boga Izraela, nie odsyłajcie jej z niczym, lecz koniecznie oddajcie mu ofiarę za grzech: wtedy będziecie uzdrowieni i dowiecie się, czemu jego ręka nie odstąpiła od was.
Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
4 I powiedzieli: Jaką ofiarę za grzech mamy mu złożyć? Odpowiedzieli: Według liczby książąt filistyńskich pięć wrzodów złotych i pięć myszy złotych. Ta sama bowiem plaga dotknęła was wszystkich i waszych książąt.
Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
5 I sporządzicie podobizny waszych wrzodów i podobizny waszych myszy, które niszczą ziemię, i oddacie chwałę Bogu Izraela. Może odejmie swoją rękę od was, waszych bogów i waszej ziemi.
Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
6 Dlaczego zatwardzacie swoje serca tak, jak Egipcjanie i faraon zatwardzali swoje serca? Czy [nie dopiero] wtedy, gdy czynił wśród nich cudowne rzeczy, wypuścili ich, aby wyszli?
Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
7 Teraz więc przygotujcie nowy wóz, weźcie dwie mleczne krowy, na które nie nałożono jarzma, i zaprzęgnijcie te krowy do wozu, a ich cielęta odprowadźcie od nich do domu.
“Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
8 Weźcie też arkę PANA i włóżcie ją na wóz; a złote przedmioty, które oddajecie jako ofiarę za grzech, włóżcie do skrzynki obok niej. Po czym puśćcie go i niech jedzie.
Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
9 Wtedy patrzcie – jeśli pojedzie drogą własnej granicy do Bet-Szemesz, [to PAN] wyrządził nam to wielkie zło. Lecz jeśli nie, to będziemy wiedzieli, że to nie jego ręka nas dotknęła, [ale] to, co nas spotkało, było przypadkiem.
ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
10 I ci ludzie tak uczynili: wzięli dwie mleczne krowy i zaprzęgli je do wozu, a ich cielęta zamknęli w domu.
Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
11 Potem włożyli arkę PANA na wóz oraz skrzynkę ze złotymi myszami i z podobiznami swoich wrzodów.
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
12 I krowy poszły prostą drogą ku Bet-Szemesz. Szły jednym gościńcem, a idąc, ryczały i nie zbaczały ani w prawo, ani w lewo. A książęta filistyńscy szli za nimi aż do granicy Bet-Szemesz.
Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
13 W tym czasie mieszkańcy Bet-Szemesz żęli pszenicę w dolinie, a gdy podnieśli swe oczy, zobaczyli arkę i uradowali się na jej widok.
Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
14 Wóz zaś dotarł na pole Jozuego z Bet-Szemesz i tam się zatrzymał, tam też był wielki kamień. Wtedy porąbali drewno [z tego] wozu i złożyli PANU krowy na ofiarę całopalną.
Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
15 Lewici zdjęli arkę PANA oraz skrzynkę obok niej, w której [były] złote przedmioty, i postawili to na tym wielkim kamieniu. Ludzie zaś z Bet-Szemesz w tym dniu złożyli PANU całopalenia i ofiary.
Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
16 Gdy pięciu książąt filistyńskich zobaczyło to [wszystko], tego samego dnia powrócili do Ekronu.
Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
17 A oto złote wrzody, które Filistyni oddali PANU jako ofiarę za grzech: za Aszdod – jeden, za Gazę – jeden, za Aszkelon – jeden, za Gat – jeden i za Ekron – jeden.
Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
18 Dodatkowo złote myszy według liczby wszystkich miast filistyńskich [należących] do pięciu książąt, [zarówno] warownych miast, jak i wiosek bez muru, i aż do [tego] wielkiego kamienia, na którym postawili arkę PANA. [Znajduje się] aż do dziś na polu Jozuego z Bet-Szemesz.
Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
19 Lecz PAN wytracił spośród ludzi z Bet-Szemesz, ponieważ zaglądali do arki PANA, zabił z ludu pięćdziesiąt tysięcy siedemdziesiąt osób. I lud [ich] opłakiwał, ponieważ PAN zadał ludowi wielką klęskę.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
20 Ludzie z Bet-Szemesz mówili: Któż zdoła ostać się przed tym świętym PANEM Bogiem? I do kogo on pójdzie od nas?
Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
21 Wyprawili więc posłańców do mieszkańców Kiriat-Jearim z wiadomością: Filistyni zwrócili arkę PANA. Przyjdźcie i zabierzcie ją do siebie.
Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”

< I Samuela 6 >