< I Samuela 25 >
1 Tymczasem Samuel umarł. I zebrali się wszyscy Izraelici, opłakiwali go i pogrzebali go w jego domu w Rama. Wtedy Dawid wstał i udał się na pustynię Paran.
Samuẹli sì kú; gbogbo ènìyàn Israẹli sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sọkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama. Dafidi sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Parani.
2 A [był pewien] człowiek w Maon, który miał posiadłość w Karmelu. Był to człowiek zamożny: miał bowiem trzy tysiące owiec i tysiąc kóz. Wtedy właśnie strzygł swoje owce w Karmelu.
Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Maoni, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Karmeli; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Karmeli.
3 Człowiek ten [miał] na imię Nabal, a jego żona nazywała się Abigail. Była to kobieta roztropna i piękna, ale jej mąż był nieokrzesany i występny, [pochodził] z [rodu] Kaleba.
Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nabali, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Abigaili; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kalebu ni òun jẹ́.
4 Gdy Dawid dowiedział się na pustyni, że Nabal strzyże swoje owce;
Dafidi sì gbọ́ ní aginjù pé Nabali ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.
5 Posłał dziesięciu sług i powiedział im: Idźcie do Karmelu i udajcie się do Nabala, i pozdrówcie go w moim imieniu;
Dafidi sì rán ọmọkùnrin mẹ́wàá, Dafidi sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Karmeli, kí ẹ sì tọ Nabali lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.
6 I tak powiecie do tego, który żyje [spokojnie]: Pokój niech będzie tobie, pokój twemu domowi i pokój wszystkiemu, co posiadasz!
Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!
7 Właśnie słyszałem, że u ciebie strzygą [owce]. Gdy twoi pasterze przebywali z nami, nie wyrządziliśmy im żadnej krzywdy i nic im nie zginęło przez cały czas ich pobytu w Karmelu.
“‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ́run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ. Wò ó, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pa wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Karmeli.
8 Zapytaj swoich sług, a powiedzą ci. Niech więc [my, twoi] słudzy, znajdziemy łaskę w twoich oczach, gdyż przybyliśmy w dobrym dniu. Daj, proszę, swoim sługom i twemu synowi Dawidowi cokolwiek znajdzie twoja ręka.
Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojúrere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àsè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àti fún Dafidi ọmọ rẹ.’”
9 Przyszli więc słudzy Dawida i powtórzyli Nabalowi wszystkie te słowa w imieniu Dawida, i czekali.
Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nabali gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dafidi, wọ́n sì sinmi.
10 Nabal odpowiedział sługom Dawida: Któż to jest Dawid? Któż to jest syn Jessego? Wielu sług ucieka dziś od swoich panów.
Nabali sì dá àwọn ìránṣẹ́ Dafidi lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dafidi? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jese? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìránṣẹ́ ni ń bẹ ni ìsinsin yìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.
11 Czyż mam wziąć swój chleb, swoją wodę i mięso swego [bydła], które zabiłem dla strzygących moje owce, i dać ludziom, o których nie wiem, skąd są?
Ǹjẹ́ ki èmi o mú oúnjẹ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pa fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi sì fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”
12 Słudzy Dawida zawrócili i udali się w drogę, a gdy przybyli, powiedzieli mu wszystkie te słowa.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì padà, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
13 Wtedy Dawid powiedział swym ludziom: Niech każdy przypasze swój miecz. Każdy więc przypasał swój miecz, Dawid również przypasał swój miecz. I wyruszyło za Dawidem około czterystu ludzi, a dwustu zostało przy taborze.
Dafidi sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idà rẹ́ mọ́ ìdí,” olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ̀ mọ́ ìdí; àti Dafidi pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin si gòkè tọ Dafidi lẹ́yìn; igba si jókòó níbi ẹrù.
14 Tymczasem jeden ze sług doniósł [o tym] Abigail, żonie Nabala: Oto Dawid przysłał posłańców z pustyni, aby błogosławić naszemu panu, lecz on ich zwymyślał.
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Abigaili aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dafidi rán oníṣẹ́ láti aginjù wá láti kí olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.
15 Ale ludzie ci byli dla nas bardzo dobrzy i nie wyrządzili nam żadnej krzywdy ani nic nam nie zginęło przez cały czas, gdy przebywaliśmy z nimi w polu.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.
16 Byli dla nas murem zarówno w nocy, jak i w dzień, przez cały czas, kiedy byliśmy z nimi, pasąc trzodę.
Odi ni wọ́n sá à jásí fún wa lọ́sàn án, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.
17 Teraz zatem wiedz o tym i rozważ to, co masz czynić, gdyż postanowiono nieszczęście wobec naszego pana i całego jego domu. On bowiem jest synem Beliala, tak że nie można z nim rozmawiać.
Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Beliali tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”
18 Wtedy Abigail pośpieszyła się, wzięła dwieście chlebów, dwa bukłaki wina, pięć przyrządzonych owiec, pięć miar prażonego ziarna, sto pęczków rodzynków oraz dwieście placków figowych i załadowała to na osły.
Abigaili sì yára, ó sì mú igbá ìṣù àkàrà àti ìgò ọtí wáìnì méjì, àti àgùntàn márùn-ún, tí a ti ṣè, àti òsùwọ̀n àgbàdo yíyan márùn-ún, àti ọgọ́rùn-ún ìdì àjàrà, àti igba àkàrà èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì dìwọ́n ru kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
19 Potem powiedziała swoim sługom: Idźcie przede mną, a ja podążę za wami. Lecz swemu mężowi Nabalowi nie powiedziała o tym.
Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Máa lọ níwájú mi; wò ó, èmi ń bọ̀ lẹ́yìn yín,” ṣùgbọ́n òun kò wí fún Nabali baálé rẹ̀.
20 I gdy jechała na ośle, i zjeżdżała pod osłoną góry, oto Dawid i jego ludzie zjeżdżali naprzeciwko niej i spotkała ich.
Bí o ti gun orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sì ń sọ̀kalẹ̀ sí ibi ìkọ̀kọ̀ òkè náà, wò ó, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ níwájú rẹ̀; òun sì wá pàdé wọn.
21 Tymczasem Dawid powiedział: Naprawdę, niepotrzebnie strzegłem na pustyni wszystkiego, co należało do tego człowieka, tak że nic nie zginęło ze wszystkiego, co ma, bo on odpłaca mi złem za dobre.
Dafidi sì ti wí pé, “Ǹjẹ́ lásán ni èmi ti pa gbogbo èyí tí i ṣe ti eléyìí ní aginjù, ti ohunkóhun kò sì nù nínú gbogbo èyí ti í ṣe tirẹ̀: òun ni ó sì fi ibi san ìre fún mi yìí.
22 Niech to uczyni Bóg wrogom Dawida i niech do tego dorzuci, jeśli do rana pozostawię ze wszystkich, co do niego należą, aż do najmniejszego szczenięcia.
Bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni ki Ọlọ́run ó ṣe sí àwọn ọ̀tá Dafidi, bi èmi bá fi ọkùnrin kan sílẹ̀ nínú gbogbo èyí tí i ṣe tirẹ̀ títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀.”
23 Kiedy Abigail zobaczyła Dawida, pośpiesznie zsiadła z osła i upadła przed Dawidem na twarz, i pokłoniła się aż do ziemi;
Abigaili sì rí Dafidi, ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi, ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.
24 Potem upadła mu do nóg i powiedziała: Niech na mnie spadnie nieprawość, mój panie. Pozwól, proszę, by twoja służąca przemówiła do ciebie i posłuchaj słów swojej służącej.
Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa mi, fi ẹ̀ṣẹ̀ yìí yá mi: kí ó sì jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, sọ̀rọ̀ létí rẹ, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
25 Niech mój pan, proszę, nie obraża się na tego syna Beliala, Nabala, gdyż jest on jak jego imię. Na imię [ma] Nabal i jest w nim głupota. Ja zaś, twoja służąca, nie widziałam sług mego pana, które przysłałeś.
Olúwa mi, èmi bẹ̀ ọ́ má ka ọkùnrin Beliali yìí sí, àní Nabali. Nítorí pé bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni òun náà rí. Nabali ni orúkọ rẹ̀, àìmoye si wà pẹ̀lú rẹ̀; ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò ri àwọn ọmọkùnrin olúwa mi, ti ìwọ rán.
26 Teraz więc, mój panie, jak żyje PAN i jak żyje twoja dusza, skoro PAN powstrzymał cię od [rozlewu] krwi i od dokonania zemsty twoją własną ręką, to niech teraz będą jak Nabal twoi wrogowie i ci, którzy pragną krzywdy mego pana.
Ǹjẹ́ olúwa mi, bi Olúwa ti wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ̀ si ti wà láààyè, bi Olúwa sì ti dá ọ dúró láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ ara rẹ gba ẹ̀san; ǹjẹ́, kí àwọn ọ̀tá rẹ, àti àwọn ẹni tí ń gbèrò ibi sí olúwa mi rí bi i Nabali.
27 Teraz więc to błogosławieństwo, które twoja służąca przyniosła swemu panu, niech będzie oddane sługom, którzy chodzą za moim panem.
Ǹjẹ́ èyí ni ẹ̀bùn tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi, jẹ́ kí a sì fi fún àwọn ọmọkùnrin ti ń tọ olúwa mi lẹ́yìn.
28 Przebacz, proszę, występek swojej służącej, gdyż PAN z pewnością uczyni memu panu trwały dom, ponieważ mój pan prowadzi walki PANA, a nie znaleziono zła w tobie przez wszystkie twoje dni.
“Èmi bẹ̀ ọ́, fi ìrékọjá arábìnrin rẹ jìn ín, nítorí Olúwa yóò sá ṣe ilé òdodo fún olúwa mi, nítorí pé ó ja ogun Olúwa. Nítorí náà kí a má ri ibi kan ni ọwọ́ rẹ níwọ̀n ìgbà tí ó wà láààyè.
29 Lecz pewien człowiek powstał, by cię prześladować i czyhać na twoje życie, ale dusza mego pana będzie zachowana w wiązance życia u PANA, twego Boga. Dusze zaś twych wrogów wyrzuci on jak z procy.
Bí ọkùnrin kan bá sì dìde láti máa lépa rẹ, àti máa wá ẹ̀mí rẹ, a ó sì di ẹ̀mí olúwa mi nínú ìdì ìyè lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ; àti ẹ̀mí àwọn ọ̀tá rẹ ni a ó sì gbọ̀n sọnù gẹ́gẹ́ bí kànnàkànnà jáde.
30 A gdy PAN uczyni memu panu wszystko dobre, co wypowiedział o tobie, i ustanowi cię władcą nad Izraelem;
Yóò sì ṣe, Olúwa yóò ṣe sí olúwa mi gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìre tí ó ti wí nípa tirẹ̀, yóò sì yàn ọ́ ni aláṣẹ lórí Israẹli.
31 Wtedy nie będzie to dla ciebie strapieniem ani wyrzutem sumienia mego pana, że przelałeś niewinną krew bądź dokonałeś zemsty. Gdy więc PAN dobrze uczyni memu panu, wspomnij na swoją służącą.
Èyí kì yóò sì jásí ìbànújẹ́ fún ọ, tàbí ìbànújẹ́ ọkàn fún olúwa mi, nítorí pé ìwọ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, tàbí pé olúwa mi gba ẹ̀san fún ara rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí Olúwa ba ṣe oore fún olúwa mi, ǹjẹ́ rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ!”
32 I Dawid powiedział do Abigail: Błogosławiony niech będzie PAN, Bóg Izraela, który wysłał cię dziś na spotkanie ze mną.
Dafidi sì wí fún Abigaili pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó rán ọ lónìí yìí láti pàdé mi.
33 Błogosławiony twój rozsądek, błogosławiona bądź i ty, która powstrzymałaś mnie dzisiaj od rozlewu krwi i od dokonania zemsty moją własną ręką.
Ìbùkún ni fún ọgbọ́n rẹ, alábùkún sì ni ìwọ, tí ó da mi dúró lónìí yìí láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ mi gba ẹ̀san fún ara mi.
34 Zaprawdę bowiem, jak żyje PAN, Bóg Izraela, który powstrzymał mnie od wyrządzenia ci krzywdy, gdybyś się nie pośpieszyła i nie zajechała mi drogi, to Nabalowi nie pozostałby do świtu nikt, aż do najmniejszego szczenięcia.
Nítòótọ́, bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí ń bẹ, tí ó da mi dúró láti pa ọ́ lára bí kò ṣe pé bí ìwọ ti yára tí ó sì wá pàdé mi, nítòótọ́ kì bá tí kù fún Nabali di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀.”
35 Dawid przyjął więc z jej ręki to, co mu przyniosła, i powiedział do niej: Idź w pokoju do swego domu. Oto wysłuchałem twego głosu i przyjąłem cię łaskawie.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gba nǹkan tí ó mú wá fún un lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Gòkè lọ ni àlàáfíà sí ilé rẹ, wò ó, èmi ti gbọ́ ohùn rẹ, inú mi sì dùn sí ọ.”
36 A gdy Abigail wróciła do Nabala, oto wyprawiał ucztę w swoim domu niczym ucztę królewską. A serce Nabala było w nim wesołe, gdyż był bardzo pijany, toteż nie powiedziała mu żadnego słowa aż do świtu.
Abigaili sì tọ Nabali wá, sì wò ó, òun sì ṣe àsè ni ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àsè ọba: inú Nabali sì dùn nítorí pé, ó ti mú ọtí ni àmupara; òun kò si sọ nǹkan fún un, díẹ̀ tàbí púpọ̀: títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀
37 Lecz rano, gdy Nabal wytrzeźwiał od wina, jego żona opowiedziała mu o wszystkim, a jego serce w nim zamarło i stał się on [jak] kamień.
Ó sì ṣe; ni òwúrọ̀, nígbà ti ọtí náà si dá tán lójú Nabali, obìnrin rẹ̀ sì ro nǹkan wọ̀nyí fún un, ọkàn rẹ sì kú nínú rẹ̀, òun sì dàbí òkúta.
38 A gdy minęło mniej więcej dziesięć dni, PAN poraził Nabala, tak że umarł.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́wàá, Olúwa lu Nabali, ó sì kú.
39 Gdy Dawid usłyszał, że Nabal umarł, powiedział: Błogosławiony PAN, który pomścił mnie na Nabalu za wyrządzoną mi zniewagę, swego sługę powstrzymał od zła, a niegodziwość Nabala zwrócił PAN na jego głowę. Potem Dawid posłał po Abigail i rozmówił się z [nią], chcąc ją pojąć za żonę.
Dafidi sì gbọ́ pé Nabali kú, ó sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí o gbèjà gígàn mi láti ọwọ́ Nabali wá, tí ó sì dá ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró láti ṣe ibi: Olúwa sì yí ìkà Nabali sí orí òun tìkára rẹ̀.” Dafidi sì ránṣẹ́, ó sì ba Abigaili sọ̀rọ̀ láti mú un fi ṣe aya fún ara rẹ̀.
40 Słudzy Dawida przybyli więc do Abigail do Karmelu i powiedzieli do niej: Dawid przysłał nas do ciebie, by pojąć cię za żonę.
Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì lọ sọ́dọ̀ Abigaili ni Karmeli, wọn sì sọ fún un pé, “Dafidi rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”
41 Ona wstała, pokłoniła się twarzą do ziemi i powiedziała: Oto niech twoja służąca będzie sługą do obmywania stóp sługom mego pana.
Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
42 Wtedy Abigail wstała pośpiesznie i wsiadła na osła z pięcioma swymi dziewczętami, które z nią chodziły. I tak pojechała za posłańcami Dawida, i została jego żoną.
Abigaili sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùn-ún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; òun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, o sì wá di aya rẹ̀.
43 Dawid wziął też Achinoam z Jizreel i obie zostały jego żonami.
Dafidi sì mú Ahinoamu ará Jesreeli; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
44 Tymczasem Saul oddał swoją córkę Mikal, żonę Dawida, Paltiemu, synowi Lajisza z Gallim.
Ṣùgbọ́n Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dafidi, fún Palti ọmọ Laiṣi tí i ṣe ara Galimu.