< I Samuela 2 >
1 Wtedy Anna modliła się i powiedziała: Moje serce raduje się w PANU, mój róg jest wywyższony w PANU. Moje usta szeroko otworzyły się przeciwko moim wrogom, gdyż raduję się z twego zbawienia.
Hana sì gbàdúrà pé, “Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa; ìwo agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa. Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀tá mi, nítorí ti èmi yọ̀ ni ìgbàlà rẹ̀.
2 Nikt nie jest tak święty jak PAN. Nie ma bowiem nikogo oprócz ciebie i nikt nie jest taką skałą jak nasz Bóg.
“Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa; kò sí ẹlòmíràn bí kò ṣe ìwọ; kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.
3 Nie mówcie już pysznych słów i niech z waszych ust nie wychodzą słowa wyniosłe. PAN bowiem [jest] Bogiem wiedzy, on waży czyny.
“Má ṣe halẹ̀; má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jáde nítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa, láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.
4 Łuki mocarzy [zostały] złamane, a słabi są przepasani mocą.
“Ọ̀run àwọn alágbára ti ṣẹ́, àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.
5 Syci najmują się za chleb, a głodni przestali [głodować]. Nawet niepłodna urodziła siedmioro, a wielodzietna więdnie.
Àwọn tí ó yọ̀ fún oúnjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe, àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní. Tó bẹ́ẹ̀ tí àgàn fi bí méje. Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.
6 PAN zabija i ożywia, wprowadza do grobu i wyprowadza. (Sheol )
“Olúwa pa ó sì sọ di ààyè; ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú, ó sì gbé dìde. (Sheol )
7 PAN czyni ubogim i bogatym, poniża i wywyższa.
Olúwa sọ di tálákà; ó sì sọ di ọlọ́rọ̀; ó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì gbé sókè.
8 Podnosi z prochu ubogiego, a z gnoju podnosi żebraka, by posadzić ich z książętami i pozwolić im odziedziczyć tron chwały. Do PANA bowiem należą filary ziemi, na nich osadził świat.
Ó gbé tálákà sókè láti inú erùpẹ̀ wá, ó gbé alágbe sókè láti orí òkìtì eérú wá, láti mú wọn jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé, láti mu wọn jogún ìtẹ́ ògo, “Nítorí pé ọ̀wọ́n ayé ti Olúwa ni, ó sì ti gbé ayé ka orí wọn.
9 Strzeże stóp swych świętych, a bezbożni zamilkną w ciemności, bo nie swoją siłą zwycięży człowiek.
Yóò pa ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́, àwọn ènìyàn búburú ni yóò dákẹ́ ní òkùnkùn. “Nípa agbára kò sí ọkùnrin tí yóò borí.
10 PAN pokruszy swoich przeciwników i zagrzmi przeciwko nim z nieba. PAN będzie sądził krańce ziemi, udzieli siły swemu królowi i wywyższy róg swego pomazańca.
A ó fọ́ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú; láti ọ̀run wá ni yóò sán àrá sí wọn; Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé. “Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀, yóò si gbé ìwo ẹni àmì òróró rẹ̀ sókè.”
11 Potem Elkana wrócił do Rama, do swego domu, a dziecko służyło PANU przy kapłanie Helim.
Elkana sì lọ sí Rama, sí ilé rẹ̀, ọmọ náà sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Olúwa níwájú Eli àlùfáà.
12 Lecz synowie Heliego byli synami Beliala i nie znali PANA.
Àwọn ọmọ Eli sì jẹ́ ọmọ Beliali; wọn kò mọ Olúwa.
13 Był bowiem taki zwyczaj kapłanów wobec ludu: kiedy ktoś składał ofiarę, sługa kapłana przychodził, gdy mięso się gotowało, z trójzębnymi widelcami w ręce.
Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀.
14 I wkładał je do garnka, kotła, rondla lub misy i to, co wyjął widełkami, kapłan zabierał dla siebie. Tak czynili w Szilo wszystkim Izraelitom, którzy tam przychodzili.
Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí àgé tàbí ọpọ́n, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Israẹli tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣilo.
15 Ponadto, zanim jeszcze spalono tłuszcz, przychodził sługa kapłana i mówił do człowieka składającego ofiary: Daj mięso na pieczeń dla kapłana, bo nie weźmie on od ciebie mięsa gotowanego, tylko surowe.
Pẹ̀lú, kí wọn tó sun ọ̀rá náà, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, á sì wí fún ọkùnrin tí ó ń ṣe ìrúbọ pé, “Fi ẹran fún mi láti sun fún àlùfáà; nítorí tí kì yóò gba ẹran sísè lọ́wọ́ rẹ, bí kò ṣe tútù.”
16 A jeśli taki człowiek mu odpowiedział: Niech najpierw spalą tłuszcz, a potem weź sobie, czego pragnie twoja dusza, wtedy on mówił: Nic z tego! Daj teraz! A jeśli nie dasz, zabiorę siłą.
Bí ọkùnrin náà bá sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí wọn ó sun ọ̀rá náà nísinsin yìí, kí o sì mú iyekíye tí ọkàn rẹ̀ bá fẹ́,” nígbà náà ni yóò dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó fi í fún mi nísinsin yìí, bí kó ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó fi agbára gbà á.”
17 Tak więc grzech tych sług był bardzo wielki przed PANEM, gdyż ludzie lekceważyli ofiary PANA.
Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì tóbi gidigidi níwájú Olúwa: nítorí tí àwọn ènìyàn kórìíra ẹbọ Olúwa.
18 Samuel zaś służył przed PANEM jako chłopiec, przepasany lnianym efodem.
Ṣùgbọ́n Samuẹli ń ṣe ìránṣẹ́ níwájú Olúwa, ọmọdé, ti a wọ̀ ní efodu ọ̀gbọ̀.
19 A jego matka robiła mu mały płaszcz i przynosiła mu [go] co roku, gdy chodziła z mężem składać doroczną ofiarę.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, ìyá rẹ̀ máa ń dá aṣọ ìlekè péńpé fún un, a sì máa mú wá fún un lọ́dọọdún, nígbà tí ó bá bá ọkọ rẹ̀ gòkè wá láti ṣe ìrúbọ ọdún.
20 I Heli błogosławił Elkanie i jego żonie, mówiąc: Niech PAN da ci potomstwo z tej kobiety za uproszonego, którego oddała PANU. I wracali do swojego domu.
Eli súre fún Elkana àti aya rẹ̀ pé, “Kí Olúwa fún ọ ní irú-ọmọ láti ara obìnrin yìí wá, nítorí ẹ̀bùn tí ó béèrè tí ó sì tún fún Olúwa.” Wọ́n sì lọ sí ilé wọn.
21 I PAN nawiedził Annę, a ona poczęła i urodziła trzech synów i dwie córki. A chłopiec Samuel dorastał przed PANEM.
Olúwa si bojú wo Hana, ó sì lóyún, ó bí ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì. Samuẹli ọmọ náà sì ń dàgbà níwájú Olúwa.
22 Heli zaś bardzo się zestarzał i usłyszał o wszystkim, co jego synowie czynili wobec całego Izraela, oraz o tym, że obcowali z kobietami, które się zbierały przy wejściu do Namiotu Zgromadzenia.
Eli sì di arúgbó gidigidi, ó sì gbọ́ gbogbo èyí ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe sí gbogbo Israẹli; àti bi wọ́n ti máa ń bá àwọn obìnrin sùn, tí wọ́n máa ń péjọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
23 I powiedział do nich: Dlaczego czynicie takie rzeczy? Słyszę o waszych złych czynach od całego ludu.
Ó sì wí fún wọn pé, kí ni ó ti ri “Èétirí tí èmi fi ń gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí yín? Nítorí tí èmi ń gbọ́ iṣẹ́ búburú yín láti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn.
24 Nie, moi synowie, gdyż niedobra to wieść, którą słyszę. Doprowadzacie lud PANA do przestępstwa.
Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí kì ṣe ìròyìn rere èmi gbọ́; ẹ̀yin mú ènìyàn Olúwa dẹ́ṣẹ̀.
25 Jeśli człowiek zgrzeszy przeciw człowiekowi, będzie go sądzić sędzia, ale jeśli człowiek zgrzeszy przeciw PANU, któż się za nim wstawi? Oni jednak nie posłuchali głosu swego ojca, bo PAN chciał ich zabić.
Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì, onídàájọ́ yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí Olúwa, ta ni yóò bẹ̀bẹ̀ fún un?” Wọn kò sì fi etí sí ohùn baba wọn, nítorí tí Olúwa ń fẹ́ pa wọ́n.
26 A chłopiec Samuel rósł i podobał się zarówno PANU, jak i ludziom.
Ọmọ náà Samuẹli ń dàgbà, ó sì rí ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa, àti ènìyàn pẹ̀lú.
27 Potem przyszedł mąż Boży do Heliego i powiedział mu: Tak mówi PAN: Czy nie objawiłem się wyraźnie domowi twego ojca, gdy byli w Egipcie w domu faraona?
Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ Eli wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí, ‘Èmi fi ara mi hàn ní gbangba fún ilé baba rẹ, nígbà tí wọ́n ń bẹ ní Ejibiti nínú ilé Farao.
28 I wybrałem go sobie spośród wszystkich pokoleń Izraela na kapłana, aby składał ofiary na moim ołtarzu, palił kadzidło i nosił efod przede mną. Dałem też domowi twego ojca wszystkie ofiary ogniowe od synów Izraela.
Èmi sì yàn án kúrò láàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti jẹ́ àlùfáà mi, láti rú ẹbọ lórí pẹpẹ mi, láti fi tùràrí jóná, láti wọ efodu níwájú mi, èmi sì fi gbogbo ẹbọ tí ọmọ Israẹli máa ń fi iná sun fún ìdílé baba rẹ̀.
29 Dlaczego podeptaliście moją ofiarę krwawą i pokarmową, które rozkazałem [składać] w przybytku? Dlaczego [bardziej] uczciłeś swoich synów ode mnie, abyście utuczyli się z pierwocin wszystkich ofiar pokarmowych Izraela, mojego ludu?
Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi tàpá sí ẹbọ àti ọrẹ mi, tí mo pàṣẹ ní ibùjókòó mi, ìwọ sì bu ọlá fún àwọn ọmọ rẹ jù mí lọ, tí ẹ sì fi gbogbo àṣàyàn ẹbọ Israẹli àwọn ènìyàn mi mú ara yín sanra.’
30 Dlatego PAN, Bóg Izraela, mówi: Wprawdzie powiedziałem: Twój dom i dom twego ojca będzie chodzić przede mną na wieki, ale teraz PAN mówi: Nie będzie tak! Tych bowiem, którzy mnie czczą, ja będę czcić, a ci, którzy mną gardzą, będą wzgardzeni.
“Nítorí náà Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Èmi ti wí nítòótọ́ pé, ilé rẹ àti ilé baba rẹ, yóò máa rìn níwájú mi títí.’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa wí pé, ‘Kí á má rí i! Àwọn tí ó bú ọlá fún mi ni èmi yóò bu ọlá fún, àti àwọn tí kò kà mí sí ni a ó sì ṣe aláìkàsí.
31 Oto nadchodzą dni, gdy odetnę twe ramię i ramię domu twego ojca, aby już nie było starca w twoim domu;
Kíyèsi i, àwọn ọjọ́ ń bọ̀ tí èmi ó gé agbára rẹ kúrò, àti agbára baba rẹ, tí kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ.
32 I zobaczysz przeciwnika w przybytku, wśród całego szczęścia, którego Bóg udzieli Izraelowi, i nie będzie starca w twoim domu po wszystkie dni.
Ìwọ yóò rí wàhálà ti Àgọ́, nínú gbogbo ọlá tí Ọlọ́run yóò fi fún Israẹli; kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ láéláé.
33 Lecz nie wytracę od swego ołtarza każdego człowieka spośród ciebie, aby trapić twe oczy i ścisnąć boleścią twoją duszę. Cały przyrost twego domu umrze w sile wieku.
Ọkùnrin tí ó jẹ́ tìrẹ, tí èmi kì yóò gé kúrò ní ibi pẹpẹ mi ni a ó dá sí láti sọkún yọ lójú àti láti banújẹ́. Ṣùgbọ́n gbogbo irú-ọmọ ilé rẹ̀ ni a ó fi idà pa ní ààbọ̀ ọjọ́ wọn.
34 A to będzie znakiem, który przyjdzie na twoich dwóch synów, Chofniego i Pinchasa: obydwaj umrą tego samego dnia.
“‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ ọkùnrin rẹ̀ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, yóò jẹ́ àmì fún ọ—àwọn méjèèjì yóò kú ní ọjọ́ kan náà.
35 I wzbudzę sobie kapłana wiernego, [który] będzie postępował według mego serca i mojej myśli. Zbuduję mu trwały dom, a on będzie chodził przed moim pomazańcem po wszystkie dni.
Èmi yóò dìde fún ara mi láti gbé àlùfáà olódodo dìde fún ara mi, ẹni tí yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó wà ní ọkàn mi àti inú mi. Èmi yóò fi ẹsẹ̀ ilé rẹ̀ múlẹ̀ gbọningbọnin òun yóò sì ṣe òjíṣẹ́ níwájú ẹni òróró mi ní ọjọ́ gbogbo.
36 I stanie się tak, że ktokolwiek pozostanie w twoim domu, ten przyjdzie i pokłoni mu się za srebrną monetę i za kawałek chleba, mówiąc: Dopuść mnie, proszę, do jednego z [urzędów] kapłańskich, abym mógł jeść kawałek chleba.
Nígbà náà olúkúlùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá kù ní ìdílé yín, yóò jáde wá yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀ nítorí ẹyọ fàdákà àti nítorí èépá àkàrà àti ẹ̀bẹ̀ pé, “Jọ̀wọ́ yàn mí sí ọ̀kan nínú iṣẹ́ àwọn àlùfáà, kí èmi kí ó le máa rí oúnjẹ jẹ.”’”