< I Samuela 10 >
1 Wtedy Samuel wziął flakonik oliwy i wylał ją na jego głowę, pocałował go i powiedział: Czyż PAN nie namaścił cię na wodza nad swoim dziedzictwem?
Samuẹli sì mú ìgò kékeré tí òróró wà nínú rẹ̀, ó sì dà á sí orí Saulu. Ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu, wí pé, “Olúwa kò ha tí fi òróró yàn ọ ní olórí lórí ohun ìní rẹ̀?
2 Gdy dziś odejdziesz ode mnie, spotkasz dwóch mężczyzn przy grobie Racheli, na granicy Beniamina w Celcach, którzy ci powiedzą: Znalazły się oślice, których poszedłeś szukać, a twój ojciec zaniechał troski o oślice i martwi się o was, mówiąc: Cóż mam uczynić dla swego syna?
Bí ìwọ bá kúrò lọ́dọ̀ mi lónìí, ìwọ yóò bá ọkùnrin méjì pàdé lẹ́bàá ibojì Rakeli ní Selsa, ní agbègbè Benjamini. Wọ́n yóò sọ fún ọ pé, ‘Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ìwọ jáde lọ láti wá ní wọn tí rí. Nísinsin yìí, baba à rẹ tí dákẹ́ kò ronú nípa wọn mọ́, ó sì ń dààmú nípa à rẹ. Ó ń béèrè, “Kí ni èmi yóò ṣe nípa ọmọ mi?”’
3 A gdy odejdziesz stamtąd dalej i przyjdziesz aż na pole Tabor, spotkają cię tam trzej mężczyźni idący do Boga, do Betel. Jeden będzie niósł troje koźląt, drugi będzie niósł trzy bochenki chleba, a trzeci będzie niósł bukłak wina.
“Nígbà náà, ìwọ yóò lọ láti ibẹ̀ títí yóò fi dé ibi igi ńlá Tabori. Ọkùnrin mẹ́ta tí wọ́n ń gòkè lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run ní Beteli yóò pàdé rẹ níbẹ̀. Ọ̀kan yóò mú ọmọ ewúrẹ́ mẹ́ta lọ́wọ́, èkejì, ìṣù àkàrà mẹ́ta àti ẹ̀kẹta yóò mú ìgò wáìnì.
4 I pozdrowią cię w pokoju, i dadzą ci dwa chleby, które weźmiesz z ich rąk.
Wọ́n yóò kí ọ, wọn yóò sì fún ọ ní ìṣù àkàrà méjì, tí ìwọ yóò gbà lọ́wọ́ wọn.
5 Potem przyjdziesz na pagórek Boży, gdzie jest załoga filistyńska. A gdy tam będziesz wchodził do miasta, spotkasz się z gromadą proroków schodzących z wyżyny. Przed nimi będą: cytra, bęben, flet i harfa, a oni będą prorokować.
“Lẹ́yìn náà, ìwọ yóò lọ sí òkè Ọlọ́run, níbi tí ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini wà. Bí ìwọ ti ń súnmọ́ ìlú náà, ìwọ yóò bá àwọn wòlíì tí ó tò lọ́wọ̀ọ̀wọ́ bọ̀ láti ibi gíga, pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn, tambori àti fèrè àti haapu níwájú wọn, wọn yóò sì máa sọ àsọtẹ́lẹ̀.
6 Wtedy zstąpi na ciebie Duch PANA i będziesz prorokował wraz z nimi, i przemienisz się w innego człowieka.
Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé ọ, ìwọ yóò sì sọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú wọn, ìwọ yóò sì di ẹni ọ̀tọ̀.
7 A gdy te znaki spełnią się na tobie, czyń wszystko, co zdoła [zrobić] twoja ręka, gdyż Bóg [jest] z tobą.
Bí ìwọ bá ti rí àmì wọ̀nyí, ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà láti ṣe, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.
8 Potem pójdziesz przede mną do Gilgal, a ja przyjdę do ciebie, aby złożyć całopalenia i ofiary pojednawcze. Przez siedem dni będziesz czekał, aż przyjdę do ciebie i pokażę to, co masz czynić.
“Lọ ṣáájú mi sí Gilgali. Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá láti rú ẹbọ sísun àti láti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ dúró fún ọjọ́ méje títí èmi yóò fi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti sọ fún ọ ohun tí ó yẹ tí ìwọ yóò ṣe.”
9 I kiedy odwrócił się, aby odejść od Samuela, Bóg przemienił mu serce na inne i w tym dniu spełniły się wszystkie te znaki.
Bí Saulu ti yípadà láti fi Samuẹli sílẹ̀, Ọlọ́run yí ọkàn Saulu padà àti pé gbogbo àmì wọ̀nyí sì wá sí ìmúṣẹ ní ọjọ́ náà.
10 I gdy przybyli na pagórek, spotkała go gromada proroków i spoczął na nim Duch Boży, i prorokował pośród nich.
Nígbà tí wọ́n dé òkè Gibeah náà, àwọn wòlíì tí ó ń tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ pàdé rẹ̀, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e nínú agbára, ó sì darapọ̀ bá wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
11 A kiedy wszyscy, którzy go wcześniej znali, zobaczyli, że prorokuje razem z prorokami, mówili jeden do drugiego: Cóż się stało synowi Kisza? Czy również Saul [jest] wśród proroków?
Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó ti mọ̀ ọ́n tẹ́lẹ̀ rí i tó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú àwọn wòlíì, wọ́n bi ara wọn, “Kí ni ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí ọmọ Kiṣi yìí. Ṣé Saulu wà lára àwọn wòlíì ni?”
12 [Pewien] człowiek spośród nich zapytał: A kto jest ich ojcem? Dlatego powstało przysłowie: Czyż i Saul [jest] wśród proroków?
Ọkùnrin kan tí ó ń gbé níbẹ̀ dáhùn pé, “Ta ni baba wọn?” Ó ti di ohun tí a fi ń pa òwe pé, ǹjẹ́ Saulu náà wà lára àwọn wòlíì bí?
13 A kiedy przestał prorokować, przyszedł na wyżynę.
Lẹ́yìn tí Saulu dákẹ́ sísọ àsọtẹ́lẹ̀, ó lọ sí ibi gíga.
14 Potem stryj Saula powiedział do niego i do jego sługi: Gdzie byliście? I odpowiedział: Szukaliśmy oślic. A widząc, że ich nie ma, poszliśmy do Samuela.
Nísinsin yìí, arákùnrin baba Saulu béèrè lọ́wọ́ Saulu àti ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Níbo ni ẹ lọ?” Ó wí pé, “À ń wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,” ṣùgbọ́n nígbà tí a kò rí wọn, a lọ sí ọ̀dọ̀ Samuẹli.
15 I stryj Saula powiedział: Powiedz mi, proszę, co wam powiedział Samuel.
Arákùnrin baba Saulu wí pé, “Sọ fún mi ohun tí Samuẹli wí fún un yín.”
16 Saul odpowiedział swemu stryjowi: Zapewnił nas, że oślice się znalazły. Lecz nie powiedział mu o sprawie królestwa, o którym Samuel mówił.
Saulu dáhùn pé, “Ó fi dá wa lójú pé wọ́n ti rí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún arákùnrin baba a rẹ̀ ohun tí Samuẹli sọ nípa ọba jíjẹ.
17 Potem Samuel zwołał lud do PANA do Mispy.
Samuẹli pé àwọn ọmọ Israẹli jọ sí iwájú Olúwa ní Mispa.
18 I przemówił do synów Izraela: Tak mówi PAN, Bóg Izraela: Ja wyprowadziłem Izraela z Egiptu i wybawiłem was z rąk Egipcjan oraz z rąk wszystkich królestw, które was uciskały;
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Èmi mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, Èmi sì gbà yín kúrò lọ́wọ́ agbára Ejibiti àti gbogbo ìjọba tí ó ń pọ́n ọn yín lójú.’
19 Lecz wy dziś odrzuciliście waszego Boga, który was wybawił od wszystkich nieszczęść i ucisków, i powiedzieliście mu: Ustanów króla nad nami. Teraz więc ustawcie się przed PANEM według waszych pokoleń i według waszych tysięcy.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti kọ Ọlọ́run yín, tí ó gbà yín kúrò nínú gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú yín. Ẹ̀yin sì ti sọ pé, ‘Rárá, yan ọba kan fún wa.’ Báyìí, ẹ kó ara yín jọ níwájú Olúwa ní ẹ̀yà àti ìdílé yín.”
20 A gdy Samuel kazał zbliżyć się wszystkim pokoleniom Izraela, [los] padł na pokolenie Beniamina.
Nígbà tí Samuẹli mú gbogbo ẹ̀yà Israẹli súnmọ́ tòsí, ó yan ẹ̀yà Benjamini.
21 Potem kazał zbliżyć się pokoleniu Beniamina według jego rodzin i [los] padł na dom Matriego i trafił na Saula, syna Kisza. I szukali go, lecz go nie znaleźli.
Ó kó ẹ̀yà Benjamini síwájú ní ìdílé ìdílé, a sì yan ìdílé Matiri. Ní ìparí a sì yan Saulu ọmọ Kiṣi. Ṣùgbọ́n ní ìgbà tí wọ́n wá a, a kò rí i,
22 Pytali więc PANA znowu: Czy przyjdzie jeszcze ten człowiek? PAN odpowiedział: Oto ukrył się wśród tobołów.
bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Olúwa pé, “Ṣé ọkùnrin náà ti wá sí bí ni?” Olúwa sì sọ pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ láàrín àwọn ẹrù.”
23 Pobiegli i przyprowadzili go stamtąd. Gdy stanął pośród ludu, wzrostem przewyższał o głowę cały lud.
Wọ́n sáré, wọ́n sì mú un jáde wá. Bí ó ti dúró láàrín àwọn ènìyàn, ó sì ga ju gbogbo àwọn tí ó kù lọ láti èjìká rẹ̀ sókè.
24 I Samuel powiedział do całego ludu: Widzicie, kogo wybrał sobie PAN – że wśród całego ludu nie ma mu równego? A cały lud krzyknął: Niech żyje król!
Samuẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ṣé ẹ ti ri ọkùnrin tí Olúwa ti yàn? Kò sí ẹnìkan bí i rẹ̀ láàrín gbogbo àwọn ènìyàn.” Nígbà náà àwọn ènìyàn kígbe pé, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn!”
25 Wtedy Samuel ogłosił ludowi prawo królewskie, spisał je w księdze i złożył przed PANEM. Potem Samuel odesłał cały lud, każdego do swego domu.
Samuẹli ṣàlàyé fún àwọn ènìyàn àwọn ìlànà ìjọba. Ó kọ wọ́n sínú ìwé, ó sì fi lélẹ̀ níwájú Olúwa. Lẹ́yìn náà, Samuẹli tú àwọn ènìyàn ká olúkúlùkù sí ilé e rẹ̀.
26 Również i Saul poszedł do swego domu do Gibea. A szli za nim wojownicy, których serca Bóg dotknął.
Saulu náà padà sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah. Àwọn akọni ọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi ọwọ́ tọ́ ọkàn wọ́n sì sìn ín.
27 Lecz synowie Beliala powiedzieli: Ten ma nas wybawić? Wzgardzili nim i nie przynieśli mu żadnych darów. On zaś milczał.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Beliali wí pé, “Báwo ni ọkùnrin yìí yóò ti ṣe gbà wá?” Wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọn kò sì mú ẹ̀bùn wá fún un, ṣùgbọ́n Saulu fọwọ́ lérán.