< I Królewska 8 >
1 Potem Salomon zebrał starszych Izraela i wszystkich naczelników pokoleń, przywódców rodów synów Izraela, u siebie w Jerozolimie, aby przenieść arkę przymierza PANA z miasta Dawida, którym jest Syjon.
Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
2 Zebrali się więc u króla Salomona wszyscy mężczyźni Izraela na święto w miesiącu Etanim, to [jest] siódmym miesiącu.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
3 A gdy przybyli wszyscy starsi Izraela, kapłani wzięli arkę.
Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
4 I przenieśli arkę PANA, Namiot Zgromadzenia i wszystkie święte naczynia, które [były] w Namiocie. Przenieśli je kapłani i Lewici.
wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
5 Król Salomon i całe zgromadzenie Izraela zebrane u niego przed arką złożyli wraz z nim w ofierze owce i woły, których nie można było zliczyć ani spisać z powodu wielkiej liczby.
àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
6 Następnie kapłani wnieśli arkę przymierza PANA na jej miejsce do wnętrza domu, do Miejsca Najświętszego, pod skrzydła cherubinów.
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
7 Cherubiny bowiem miały rozpostarte skrzydła nad miejscem arki i okrywały od góry arkę i jej drążki.
Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
8 I powyciągali drążki, tak że ich końce było widać z Miejsca Świętego przed Miejscem Najświętszym, ale nie były widoczne na zewnątrz. I są tam aż do dziś.
Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
9 W arce nie było nic oprócz dwóch kamiennych tablic, które Mojżesz włożył do niej na Horebie, gdy PAN zawarł przymierze z synami Izraela po ich wyjściu z Egiptu.
Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 A gdy kapłani wyszli z Miejsca Świętego, obłok napełnił dom PANA;
Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
11 Tak że kapłani nie mogli pozostać i pełnić służby z powodu tego obłoku, bo chwała PANA napełniła dom PANA.
Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
12 Wtedy przemówił Salomon: PAN powiedział, że będzie mieszkać w mroku.
Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
13 Już zbudowałem ci dom na mieszkanie – miejsce, w którym będziesz przebywać na wieki.
Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
14 Potem król obrócił swą twarz i błogosławił całemu zgromadzeniu Izraela, a całe zgromadzenie Izraela stało.
Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
15 I przemówił: Błogosławiony niech będzie PAN, Bóg Izraela, który swymi ustami mówił do mego ojca Dawida i swą ręką wypełnił to, co obiecał:
Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
16 Od dnia, w którym wyprowadziłem swój lud Izraela z Egiptu, nie wybrałem żadnego miasta spośród wszystkich pokoleń Izraela do zbudowania domu, by moje imię tam przebywało. Lecz wybrałem Dawida, aby był [postawiony] nad moim ludem Izraela.
‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
17 Dawid, mój ojciec, postanowił w [swoim] sercu, że zbuduje dom dla imienia PANA, Boga Izraela.
“Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
18 Lecz PAN powiedział do mego ojca Dawida: Ponieważ postanowiłeś w swoim sercu, by zbudować dom dla mojego imienia, dobrze uczyniłeś, że tak postanowiłeś w sercu.
Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
19 Nie ty jednak będziesz budował ten dom, ale twój syn, który wyjdzie z twoich bioder, on zbuduje dom dla mego imienia.
Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
20 PAN wypełnił swoje słowo, które powiedział. A [ja] powstałem w miejsce Dawida, swego ojca, i usiadłem na tronie Izraela, jak PAN zapowiedział, i zbudowałem dom dla imienia PANA, Boga Izraela.
“Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
21 I przeznaczyłem tam miejsce dla arki, w której znajduje się przymierze PANA, które zawarł z naszymi ojcami, gdy wyprowadził ich z ziemi Egiptu.
Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
22 Następnie Salomon stanął przed ołtarzem PANA wobec całego zgromadzenia Izraela i wyciągnął swoje ręce ku niebu;
Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
23 I powiedział: PANIE, Boże Izraela, nie ma Boga w górze na niebie ani w dole na ziemi podobnego tobie, który przestrzegałby przymierza i miłosierdzia wobec swoich sług, którzy postępują przed tobą całym swoim sercem.
Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
24 Dotrzymałeś swojemu słudze Dawidowi, memu ojcu, tego, co mu obiecałeś. Swoimi ustami [to] powiedziałeś i swoją ręką [to] wypełniłeś, jak to jest dziś.
O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
25 Teraz więc, PANIE, Boże Izraela, dotrzymaj swemu słudze Dawidowi, memu ojcu, obietnicy, którą mu dałeś, kiedy mówiłeś: Nie zabraknie ci przede mną potomka, który zasiadałby na tronie Izraela, jeśli tylko twoi synowie będą strzec swej drogi, postępując przede mną tak, jak ty postępowałeś przede mną.
“Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
26 A teraz, Boże Izraela, proszę, niech będzie potwierdzone twoje słowo, które wypowiedziałeś do swego sługi Dawida, mego ojca.
Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
27 Czyż naprawdę jednak Bóg zamieszka na ziemi? Oto niebiosa i niebiosa niebios nie mogą cię ogarnąć, a cóż dopiero ten dom, który zbudowałem?
“Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
28 Zważ na modlitwę swego sługi i na jego prośbę, PANIE, mój Boże, wysłuchaj wołania i modlitwy, które twój sługa zanosi dziś do ciebie;
Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
29 Aby twoje oczy były otwarte nad tym domem w nocy i we dnie, nad tym miejscem, o którym powiedziałeś: Tam będzie moje imię; abyś wysłuchał modlitwy, którą w tym miejscu zanosi twój sługa.
Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
30 Wysłuchaj prośby swego sługi i swego ludu Izraela, gdy będą się modlić w tym miejscu. Wysłuchaj z miejsca swojego zamieszkania – z nieba, a gdy wysłuchasz, przebacz.
Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
31 Jeśli ktoś zgrzeszy przeciw swemu bliźniemu, a ten zobowiąże go do przysięgi, a ta przysięga przyjdzie przed twój ołtarz w tym domu;
“Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
32 Ty wysłuchaj w niebie, racz działać i osądź swoje sługi, potępiaj niegodziwego, sprowadzając mu na głowę jego czyny, a usprawiedliwiaj sprawiedliwego, oddając mu według jego sprawiedliwości.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
33 Gdy twój lud Izraela zostanie pobity przez wroga za to, że zgrzeszył przeciw tobie, a nawróci się do ciebie, wyzna twoje imię i będzie się modlić, i błagać cię w tym domu;
“Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
34 Ty wysłuchaj w niebie i przebacz grzech swemu ludowi Izraela, i przyprowadź ich znów do ziemi, którą dałeś ich ojcom.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
35 Kiedy niebo będzie zamknięte i nie będzie deszczu z powodu tego, że zgrzeszyli przeciwko tobie, ale będą się modlić w tym miejscu i wyznawać twoje imię, i odwrócą się od swoich grzechów, bo ich upokorzyłeś;
“Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
36 Ty wysłuchaj z nieba i przebacz grzech swoich sług i swego ludu Izraela, naucz ich dobrej drogi, po której mają kroczyć, i spuść deszcz na swoją ziemię, którą dałeś swojemu ludowi w dziedzictwo.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
37 Jeśli będzie w ziemi głód, jeśli będzie zaraza, susza, rdza, szarańcza lub robactwo, jeśli jego wróg będzie go uciskał w ziemi jego zamieszkania, [jeśli będzie] jakakolwiek plaga [lub] choroba;
“Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
38 Wszelkiej modlitwy i wszelkiego błagania, jakie zaniesie jakikolwiek człowiek [lub] cały twój lud Izraela, kto tylko uzna plagę swego serca i wyciągnie swoje ręce ku temu domowi;
nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
39 Wtedy ty wysłuchaj w niebie, w miejscu swego zamieszkania, i przebacz, racz działać i oddaj każdemu według wszystkich jego dróg, bo ty znasz jego serce – gdyż jedynie ty znasz serca wszystkich synów ludzkich;
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
40 Aby się ciebie bali po wszystkie dni, które będą żyć na ziemi, którą dałeś naszym ojcom.
Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
41 Również i cudzoziemca, który nie jest z twego ludu Izraela, a jednak przybędzie z dalekiej ziemi przez wzgląd na twoje imię;
“Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
42 (Usłyszą bowiem o twoim wielkim imieniu, twojej mocnej ręce i twoim wyciągniętym ramieniu), gdy przyjdzie i będzie się modlić ku temu domowi;
nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
43 Ty wysłuchaj w niebie, w miejscu swego zamieszkania, i uczyń wszystko, o co ten cudzoziemiec będzie do ciebie wołać, aby wszystkie narody ziemi poznały twoje imię i bały się ciebie tak, jak twój lud Izraela, i aby wiedziały, że twoje imię jest wzywane nad tym domem, który zbudowałem.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
44 Jeśli twój lud wyruszy na wojnę przeciwko swemu wrogowi drogą, którą go poślesz, i będzie się modlić do PANA, zwracając się ku miastu, które wybrałeś, i ku domowi, który zbudowałem dla twego imienia;
“Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
45 To wysłuchaj w niebie ich modlitwy i błagania i broń ich sprawy.
nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
46 Jeśli zgrzeszą przeciw tobie – bo nie ma człowieka, który by nie zgrzeszył – i rozgniewasz się na nich, i podasz ich wrogowi, który uprowadzi ich w niewolę, do ziemi nieprzyjaciół, dalekiej czy bliskiej;
“Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
47 Lecz jeśli wezmą to do serca w tej ziemi, do której zostali uprowadzeni w niewolę, i odwrócą się, i będą cię błagać w ziemi tych, którzy ich pojmali, mówiąc: Zgrzeszyliśmy i postąpiliśmy przewrotnie, popełniliśmy niegodziwość;
bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
48 I zawrócą do ciebie całym swym sercem i całą swą duszą, w ziemi swoich wrogów, którzy ich pojmali, i będą się modlić do ciebie zwróceni ku swojej ziemi, którą dałeś ich ojcom, ku miastu, które wybrałeś, i ku domowi, który zbudowałem dla twego imienia;
bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
49 Wtedy wysłuchaj w niebie, w miejscu swego zamieszkania, ich modlitwy i ich prośby i broń ich sprawy;
nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
50 Przebacz swemu ludowi, który zgrzeszył przeciw tobie, i wszystkie ich występki, które popełnili przeciw tobie, a skłoń do miłosierdzia tych, którzy ich pojmali, aby zmiłowali się nad nimi.
Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
51 Są bowiem twoim ludem i twoim dziedzictwem, które wyprowadziłeś z Egiptu, z wnętrza pieca do wytopu żelaza.
nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
52 Niech twoje oczy będą otwarte na prośbę twego sługi i na prośbę twego ludu Izraela, abyś ich wysłuchał we wszystkim, o co będą wołać do ciebie.
“Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
53 Ty bowiem oddzieliłeś ich sobie od wszystkich narodów ziemi na dziedzictwo, jak to powiedziałeś przez swego sługę Mojżesza, gdy wyprowadziłeś naszych ojców z Egiptu, o Panie BOŻE!
Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
54 Gdy Salomon skończył zanosić do PANA wszystkie te modlitwy i prośby, powstał sprzed ołtarza PANA, [gdzie] klęczał, i ręce wyciągał ku niebu;
Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
55 Stanął i błogosławił całe zgromadzenie Izraela, mówiąc donośnym głosem:
Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
56 Błogosławiony [niech będzie] PAN, który dał odpoczynek swemu ludowi Izraela, zgodnie z tym wszystkim, co powiedział. Nie uchybił jednemu słowu ze wszystkich swoich dobrych obietnic, które wypowiedział przez swego sługę Mojżesza.
“Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
57 Niech PAN, nasz Bóg, będzie z nami, jak był z naszymi ojcami. Niech nas nie opuści ani nas nie porzuci;
Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
58 Niech skłoni ku sobie nasze serca, abyśmy kroczyli wszystkimi jego drogami i strzegli jego przykazań, nakazów i praw, które rozkazał naszym ojcom.
Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
59 A niech te moje słowa, którymi wyraziłem swoje błaganie przed PANEM, będą bliskie PANU, naszemu Bogu we dnie i w nocy, aby bronił sprawy swego sługi i sprawy swego ludu Izraela, według potrzeby każdego dnia;
Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
60 Żeby wszystkie narody ziemi poznały, że PAN jest Bogiem, a innego nie ma.
kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
61 Niech więc wasze serce będzie doskonałe wobec PANA, naszego Boga, abyście postępowali według jego nakazów i przestrzegali jego przykazań tak jak dzisiaj.
Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
62 Potem król, a z nim cały Izrael, złożyli ofiary przed PANEM.
Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
63 Salomon złożył jako ofiarę pojednawczą, którą ofiarował PANU, dwadzieścia dwa tysiące wołów i sto dwadzieścia tysięcy owiec. Tak król i wszyscy synowie Izraela poświęcili dom PANU.
Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
64 W tym samym dniu król poświęcił środkową część dziedzińca, która była przed domem PANA. Tam bowiem złożył całopalenia, ofiary z pokarmów i tłuszcz ofiar pojednawczych, ponieważ ołtarz z brązu, który znajdował się przed PANEM, był zbyt mały, aby pomieścić całopalenia, ofiary z pokarmów i tłuszcz ofiar pojednawczych.
Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
65 W tym czasie Salomon, a wraz z nim cały Izrael, wielkie zgromadzenie od wejścia do Chamat aż do rzeki Egiptu, obchodzili święto przed PANEM, naszym Bogiem, przez siedem dni i przez siedem dni, [razem] czternaście dni.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
66 A w ósmym dniu odprawił lud. Błogosławili króla i rozeszli się do swoich namiotów radośni i ciesząc się w [swoich] sercach z powodu całego dobra, które PAN wyświadczył Dawidowi, swemu słudze, oraz Izraelowi, swemu ludowi.
Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.