< I Królewska 4 >
1 Tak więc król Salomon był królem nad całym Izraelem.
Solomoni ọba sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli.
2 A oto jego dostojnicy: Azariasz, syn Sadoka, kapłan.
Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀: Asariah ọmọ Sadoku àlùfáà:
3 Elichoref i Achiasz, synowie Sziszy, pisarze; Jehoszafat, syn Achiluda, kronikarz.
Elihorefu àti Ahijah àwọn ọmọ Ṣisa akọ̀wé; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi ni akọ̀wé ìlú;
4 Benajasz, syn Jehojady, dowódca wojska; Sadok i Abiatar, kapłani.
Benaiah ọmọ Jehoiada ni olórí ogun; Sadoku àti Abiatari ni àwọn àlùfáà;
5 Azariasz, syn Natana, przełożony namiestników, Zabud, syn Natana, naczelny dostojnik, przyjaciel króla.
Asariah ọmọ Natani ni olórí àwọn agbègbè; Sabudu ọmọ Natani, àlùfáà àti olùgba ọba ní ìmọ̀ràn;
6 Achiszar, przełożony dworu, i Adoniram, syn Abdy, odpowiedzialny za daninę.
Ahiṣari ni olùtọ́jú ààfin; Adoniramu ọmọ Abida ni ó ń ṣe olórí iṣẹ́-ìlú.
7 Salomon miał też dwunastu namiestników nad całym Izraelem, którzy zaopatrywali króla i cały jego dwór w żywność. Każdy z nich przez jeden miesiąc w roku miał dostarczać żywność.
Solomoni sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbègbè Israẹli, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.
8 A oto ich imiona: syn Chura – na górze Efraim;
Orúkọ wọn ni wọ̀nyí: Bene-Huri ní ìlú olókè Efraimu.
9 Syn Dekara – w Makas, Szaalbim – w Bet-Szemesz i Elon-Bet-Chanan;
Bene-Dekeri ní Makasi, Ṣaalbimu, Beti-Ṣemeṣi, àti Eloni Beti-Hanani;
10 Syn Cheseda – w Arubot, do niego [należało] Soko i cała ziemia Chefer;
Bene-Hesedi, ní Aruboti (tirẹ̀ ni Soko àti gbogbo ilẹ̀ Heferi ń ṣe);
11 Syn Abinadaba – nad całym obszarem Dor; jego żoną była Tafat, córka Salomona.
Bene-Abinadabu, ní Napoti (Dori; òun ni ó fẹ́ Tafati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
12 Baana, syn Achiluda, [do którego należały] Tanak i Megiddo oraz całe Bet-Szean, które leży przy Sartan pod Jizreelem, od Bet-Szean aż do Abel-Mechola, aż poza Jokmeam.
Baana ọmọ Ahiludi, ní Taanaki àti Megido, àti ní gbogbo Beti-Ṣeani tí ń bẹ níhà Saretani ní ìsàlẹ̀ Jesreeli, láti Beti-Ṣeani dé Abeli-Mehola títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jokimeamu.
13 Syn Geber – w Ramot-Gilead, do niego należały wsie Jaira, syna Manassesa, które [leżą] w Gileadzie. Do niego też należała kraina Argob, która [jest] w Baszanie – sześćdziesiąt wielkich miast mających mury i brązowe rygle.
Ọmọ Geberi ní Ramoti Gileadi (tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jairi ọmọ Manase tí ń bẹ ní Gileadi, tirẹ̀ sì ni agbègbè Argobu, tí ń bẹ ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin).
14 Achinadab, syn Iddo – w Machanaim.
Ahinadabu ọmọ Iddo ní Mahanaimu
15 Achimaas – w Neftalim; on też pojął za żonę Basemat, córkę Salomona.
Ahimasi ní Naftali (ó fẹ́ Basemati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
16 Baana, syn Chuszaia – w Aszer i Alot.
Baana ọmọ Huṣai ní Aṣeri àti ní Aloti;
17 Jehoszafat, syn Paruacha – w Issacharze.
Jehoṣafati ọmọ Parua ni ó wà ní Isakari;
18 Szimei, syn Eli – w Beniaminie.
Ṣimei ọmọ Ela ni Benjamini;
19 Geber, syn Uriego – w ziemi Gilead, ziemi Sichona, króla Amorytów, i Oga, króla Baszanu. Był on jedynym namiestnikiem tej ziemi.
Geberi ọmọ Uri ní Gileadi (orílẹ̀-èdè Sihoni ọba àwọn ará Amori àti orílẹ̀-èdè Ogu ọba Baṣani). Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.
20 A Juda i Izrael [byli] tak liczni jak piasek nad morzem. Jedli, pili i radowali się.
Àwọn ènìyàn Juda àti ti Israẹli pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí Òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.
21 A Salomon panował nad wszystkimi królestwami od rzeki aż do ziemi Filistynów, aż do granicy Egiptu. Płaciły one daninę i służyły Salomonowi po wszystkie dni jego życia.
Solomoni sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ìjọba láti odò Eufurate títí dé ilẹ̀ àwọn ará Filistini, àti títí dé etí ilẹ̀ Ejibiti. Àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Solomoni ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
22 Wyżywienie dla Salomona na jeden dzień wynosiło trzydzieści kor najlepszej mąki i sześćdziesiąt kor zwykłej mąki.
Oúnjẹ Solomoni fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná àti ọgọ́ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun,
23 Dziesięć tucznych wołów, dwadzieścia wołów z pastwiska, sto owiec, nie licząc jeleni, saren, danieli i tucznego drobiu.
Màlúù mẹ́wàá tí ó sanra, àti ogún màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti èsúró, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.
24 Panował bowiem nad całym obszarem z tej strony rzeki, od Tifsach aż do Gazy, nad wszystkimi królami z tej strony rzeki. I miał pokój ze wszystkich stron dokoła.
Nítorí òun ni ó ṣàkóso lórí gbogbo agbègbè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn odò Eufurate, láti Tifisa títí dé Gasa, lórí gbogbo àwọn ọba ní ìhà ìhín odò, ó sì ní àlàáfíà ní gbogbo ìlú tí ó yí i káàkiri.
25 Juda i Izrael mieszkali bezpiecznie, każdy pod swoją winoroślą i pod swoim drzewem figowym, od Dan aż do Beer-Szeby, po wszystkie dni Salomona.
Nígbà ayé Solomoni, Juda àti Israẹli, láti Dani títí dé Beerṣeba, wọ́n ń gbé ní àlàáfíà, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀.
26 Salomon miał też czterdzieści tysięcy koni w stajniach do swoich rydwanów i dwanaście tysięcy jeźdźców.
Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé ẹṣin fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin.
27 Namiestnicy, każdy w swoim miesiącu, zaopatrywali w żywność króla Salomona i wszystkich, którzy przychodzili do stołu króla Salomona, tak że niczego nie brakowało.
Àwọn ìjòyè agbègbè, olúkúlùkù ní oṣù rẹ̀, ń pèsè oúnjẹ fún Solomoni ọba àti gbogbo àwọn tí ń wá sí ibi tábìlì ọba, wọ́n sì rí i pé ohun kankan kò ṣẹ́kù.
28 Także jęczmień i słomę dla koni i mułów sprowadzali na to miejsce, gdzie [one] przebywały, każdy według swojego obowiązku.
Wọ́n tún máa ń mú ọkà barle àti koríko fún ẹṣin àti fún ẹṣin sísáré wá pẹ̀lú sí ibi tí ó yẹ, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ìlànà tirẹ̀.
29 A Bóg dał Salomonowi mądrość i bardzo wielkie zrozumienie oraz przestronność serca jak piasek, który jest na brzegu morskim.
Ọlọ́run sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, àti òye ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, àti ìmọ̀ gbígbòòrò òye tí a kò le è fiwé iyanrìn tí ó wà létí Òkun.
30 I mądrość Salomona była większa od mądrości wszystkich narodów wschodnich i od wszelkiej mądrości Egiptu.
Ọgbọ́n Solomoni sì pọ̀ ju ọgbọ́n ọkùnrin ìlà-oòrùn lọ, ó sì pọ̀ ju gbogbo ọgbọ́n Ejibiti lọ.
31 Był mądrzejszy niż wszyscy ludzie, niż Etan Ezrachita, Heman, Kalkol i Darda, synowie Machola. Był sławny wśród wszystkich okolicznych narodów.
Ó sì ní òye ju gbogbo ènìyàn lọ, ju Etani, ará Esra, àti Hemani àti Kalkoli, àti Darda àwọn ọmọ Maholi lọ. Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yíká.
32 Wypowiedział trzy tysiące przysłów, a jego pieśni było tysiąc pięć.
Ó sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta òwe, àwọn orin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé márùn-ún.
33 Wypowiadał się też o drzewach, [poczynając] od cedru na Libanie aż do hizopu, który wyrasta z muru. Mówił też o zwierzętach, ptakach, płazach i rybach.
Ó sì sọ̀rọ̀ ti igi, láti kedari tí ń bẹ ní Lebanoni dé Hísópù tí ń dàgbà lára ògiri. Ó sì tún sọ ti àwọn ẹranko àti ti àwọn ẹyẹ, àti ohun tí ń rákò àti ti ẹja.
34 Przychodzili więc [ludzie] ze wszystkich narodów, aby słuchać mądrości Salomona, od wszystkich królów ziemi, którzy słyszeli o jego mądrości.
Àwọn ènìyàn sì ń wá láti gbogbo orílẹ̀-èdè láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé láti wá gbọ́ nípa ọgbọ́n rẹ̀.