< I Królewska 1 >

1 Gdy król Dawid zestarzał się [i] posunął w latach, to choć okrywano go szatami, nie mógł się rozgrzać.
Nígbà tí Dafidi ọba di arúgbó, ọjọ́ rẹ̀ sì pọ̀, ara rẹ̀ kò le è móoru bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n da ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ bò ó.
2 Jego słudzy powiedzieli mu więc: Niech poszukają dla naszego pana, króla, młodej dziewicy, która stawałaby przed królem i pielęgnowała go. Niech kładzie się na twoim łonie, żeby nasz pan, król, mógł się rozgrzać.
Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí fún un pé, “Ẹ jẹ́ kí a wá ọ̀dọ́mọbìnrin wúńdíá kan kí ó dúró ti ọba, kì ó sì máa tọ́jú rẹ̀. Kí ó dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀ kí ara ọba olúwa wa lè móoru.”
3 Szukali więc pięknej dziewczyny po wszystkich obszarach Izraela i znaleźli Abiszag Szunamitkę, i przyprowadzili ją do króla.
Nígbà náà ni wọ́n lọ jákèjádò ilẹ̀ Israẹli láti wá ọ̀dọ́mọbìnrin arẹwà, wọ́n sì rí Abiṣagi, ará Ṣunemu, wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ ọba.
4 Dziewczyna ta [była] bardzo piękna; pielęgnowała króla i służyła mu, ale król z nią nie obcował.
Ọmọbìnrin náà rẹwà gidigidi; ó sì ń ṣe ìtọ́jú ọba, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n ọba kò sì bá a lòpọ̀.
5 Lecz Adoniasz, syn Chaggity, wywyższał się, mówiąc: Ja zostanę królem. Zaopatrzył się w rydwany i jeźdźców oraz pięćdziesięciu mężczyzn, którzy biegali przed nim.
Adonijah ẹni tí ìyá rẹ̀ ń ṣe Haggiti sì gbé ara rẹ̀ ga, ó sì wí pé, “Èmi yóò jẹ ọba.” Ó sì ṣètò kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin, pẹ̀lú àádọ́ta ọkùnrin láti máa sáré níwájú rẹ̀.
6 Jego ojciec nigdy go nie upominał, mówiąc: Czemu to uczyniłeś? Był on też bardzo przystojny, [jego matka] urodziła go po Absalomie.
(Baba rẹ̀ kò bà á nínú jẹ́ rí nípa bíbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi hùwà báyìí?” Ó sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin, òun ni a bí lé Absalomu.)
7 Porozumiał się z Joabem, synem Serui, i z kapłanem Abiatarem, a oni przystali z Adoniaszem i pomogli [mu].
Adonijah sì gbèrò pẹ̀lú Joabu, ọmọ Seruiah àti Abiatari àlùfáà, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
8 Lecz kapłan Sadok, Benajasz, syn Jehojady, prorok Natan, Szimei, Rei oraz dzielni wojownicy Dawida nie sprzyjali Adoniaszowi.
Ṣùgbọ́n Sadoku àlùfáà, Benaiah ọmọ Jehoiada, Natani wòlíì, Ṣimei àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ Rei àti olórí ogun Dafidi ni kò darapọ̀ mọ́ Adonijah.
9 Potem Adoniasz zabił owce, woły i tuczne bydło przy kamieniu Zochelet, blisko źródła Rogel, i zaprosił wszystkich swych braci, synów króla, oraz wszystkich mężczyzn Judy, sługi króla.
Nígbà náà ni Adonijah fi àgùntàn àti màlúù àti ẹran ọ̀sìn tí ó sanra rú ẹbọ níbi Òkúta Soheleti tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ En-Rogeli. Ó sì pe gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ ọba, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ ọba.
10 Lecz nie zaprosił proroka Natana, Benajasza i dzielnych wojowników oraz swego brata Salomona.
Ṣùgbọ́n kò pe Natani wòlíì tàbí Benaiah tàbí àwọn olórí tàbí Solomoni arákùnrin rẹ̀.
11 Wtedy Natan zapytał Batszebę, matkę Salomona: Czy nie słyszałaś, że Adoniasz, syn Chaggity, króluje, a nasz pan, Dawid, [o tym] nie wie?
Nígbà náà ni Natani béèrè lọ́wọ́ Batṣeba, ìyá Solomoni pé, “Ǹjẹ́ ìwọ kò gbọ́ pé Adonijah, ọmọ Haggiti ti jẹ ọba láìjẹ́ pé Dafidi olúwa wa mọ̀ sí i?
12 Chodź więc teraz, proszę, dam ci radę, abyś ocaliła swoje życie i życie swego syna, Salomona.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, jẹ́ kí èmi gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn bí ìwọ ṣe lè gba ẹ̀mí rẹ là àti ẹ̀mí ọmọ rẹ Solomoni.
13 Idź i wejdź do króla Dawida, i powiedz mu: Czyż ty, mój panie, królu, nie przysiągłeś swojej służącej: Twój syn Salomon będzie królował po mnie i on zasiądzie na moim tronie? Dlaczego więc króluje Adoniasz?
Lọ sọ́dọ̀ Dafidi ọba, kí o sì wí fún un pé, ‘Olúwa mi ọba, ǹjẹ́ ìwọ kò búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, “Dájúdájú Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi?” Èéṣe nígbà náà tí Adonijah fi jẹ ọba?’
14 A oto gdy ty będziesz tam jeszcze rozmawiała z królem, ja wejdę za tobą i potwierdzę twoje słowa.
Níwọ́n ìgbà tí ìwọ sì wà níbẹ̀, tí o sì ń bá ọba sọ̀rọ̀ èmi yóò wá, láti wádìí ohun tí o ti sọ.”
15 Batszeba weszła więc do króla do komnaty. Król już się bardzo zestarzał, a Abiszag Szunamitka usługiwała królowi.
Bẹ́ẹ̀ ni Batṣeba lọ rí ọba ní inú yàrá rẹ̀, ọba sì gbó gidigidi níbi tí Abiṣagi ará Ṣunemu ti ń ṣe ìránṣẹ́ fún ọba.
16 Wtedy Batszeba uklękła i oddała pokłon królowi, a król zapytał: Czego chcesz?
Batṣeba sì tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba. Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”
17 A [ona] mu odpowiedziała: Mój panie, ty przysiągłeś swojej służącej na PANA, swego Boga: Twój syn, Salomon, będzie królował po mnie i on zasiądzie na moim tronie.
Ó sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi; ìwọ fúnra rẹ̀ fi Olúwa Ọlọ́run rẹ búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, ‘Solomoni ọmọ rẹ yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi.’
18 A oto teraz Adoniasz króluje, a ty, mój panie, królu, [o tym] nie wiesz.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Adonijah ti di ọba, ìwọ, ọba olúwa mi kò sì mọ̀ nípa rẹ̀.
19 Zabił bowiem woły, tuczne bydło i bardzo dużo owiec i zaprosił wszystkich synów króla, kapłana Abiatara oraz dowódcę wojska, Joaba, ale twego sługi Salomona nie zaprosił.
Òun sì ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran tí ó ní ọ̀rá, àti àgùntàn rú ẹbọ, ó sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, àti Abiatari àlùfáà àti Joabu balógun, ṣùgbọ́n kò sì pe Solomoni ìránṣẹ́ rẹ.
20 Lecz ty, mój panie, królu, [wiesz], że oczy całego Izraela są zwrócone na ciebie, abyś im oznajmił, kto zasiądzie na tronie mego pana, króla, po nim.
Olúwa mi ọba, ojú gbogbo Israẹli ń bẹ lára rẹ, láti mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ.
21 W przeciwnym razie, gdy mój pan, król, zaśnie ze swymi ojcami, ja i mój syn Salomon będziemy uważani za przestępców.
Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí olúwa mi ọba bá sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, wọn yóò sì ka èmi àti Solomoni sí ẹlẹ́ṣẹ̀.”
22 A gdy jeszcze rozmawiała z królem, przyszedł prorok Natan.
Bí ó sì ti ń bá ọba sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Natani wòlíì sì wọlé.
23 I oznajmiono królowi: Oto prorok Natan. I gdy wszedł przed oblicze króla, pokłonił się królowi twarzą do ziemi.
Wọ́n sì sọ fún ọba pé, “Natani wòlíì wà níbí.” Ó sì lọ síwájú ọba, ó wólẹ̀, ó sì dojúbolẹ̀.
24 Potem Natan powiedział: Mój panie, królu, czy ty powiedziałeś: Adoniasz będzie królował po mnie i on zasiądzie na moim tronie?
Natani sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ, olúwa mi ọba, ti sọ pé Adonijah ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn rẹ àti pé òun ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ?
25 Dziś bowiem zstąpił i zabił woły, tuczne bydło oraz bardzo dużo owiec, i zaprosił wszystkich synów króla, dowódców wojsk oraz kapłana Abiatara, a oto oni jedzą z nim i piją, i mówią: Niech żyje król Adoniasz!
Ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ ní òní, ó sì ti rú ẹbọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran ọlọ́ràá àti àgùntàn. Ó sì ti pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, balógun àti Abiatari àlùfáà. Nísìnsinyìí, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Kí Adonijah ọba kí ó pẹ́!’
26 Lecz mnie, twego sługi, i kapłana Sadoka, i Benajasza, syna Jehojady, oraz twego sługi Salomona nie zaprosił.
Ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́ rẹ, àti Sadoku àlùfáà, àti Benaiah ọmọ Jehoiada, àti Solomoni ìránṣẹ́ rẹ ni kò pè.
27 Czy wyszło to od mego pana, króla, a nie oznajmiłeś swemu słudze, kto zasiądzie po nim na tronie mego pana, króla?
Ṣé nǹkan yìí ni olúwa mi ọba ti ṣe láìjẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ?”
28 Król Dawid odpowiedział: Zawołajcie mi Batszebę. Ta weszła przed oblicze króla i stanęła przed nim.
Nígbà náà ni Dafidi ọba wí pé, “Pe Batṣeba wọlé wá.” Ó sì wá síwájú ọba, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
29 Wtedy król przysiągł: Jak żyje PAN, który wybawił moją duszę z wszelkiego ucisku;
Ọba sì búra pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti wà ẹni tí ó ti gbà mí kúrò nínú gbogbo wàhálà
30 Jak przysiągłem ci na PANA, Boga Izraela: Twój syn Salomon będzie królować po mnie i on zasiądzie na moim tronie zamiast mnie, tak dziś uczynię.
Lónìí dandan ni èmi yóò gbé ohun tí mo ti fi Olúwa Ọlọ́run Israẹli búra fún yọ pé, Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, àti pé yóò jókòó lórí ìtẹ́ mi ní ipò mi.”
31 Batszeba schyliła się twarzą ku ziemi i pokłoniła się królowi, i powiedziała: Niech żyje mój pan, król Dawid, na wieki!
Nígbà náà ni Batṣeba tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba pé, “Kí olúwa mi Dafidi ọba kí ó pẹ́!”
32 Potem król Dawid rozkazał: Zawołajcie mi kapłana Sadoka, proroka Natana i Benajasza, syna Jehojady. I [tamci] weszli przed oblicze króla.
Dafidi ọba sì wí pé, “Ẹ pe Sadoku àlùfáà wọlé fún mi àti Natani wòlíì àti Benaiah ọmọ Jehoiada.” Nígbà tí wọ́n wá síwájú ọba,
33 A król powiedział im: Weźcie ze sobą sługi waszego pana, wsadźcie mego syna Salomona na moją mulicę i sprowadźcie go do Gichonu.
ọba sì wí fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa yín pẹ̀lú yín kí ẹ sì mú kí Solomoni ọmọ mi kí ó gun ìbáaka mi, kí ẹ sì mú un sọ̀kalẹ̀ wá sí Gihoni.
34 A tam niech kapłan Sadok i prorok Natan namaszczą go na króla nad Izraelem. Następnie zadmijcie w trąbę i powiedzcie: Niech żyje król Salomon!
Níbẹ̀ ni Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì yóò ti fi òróró yàn án ní ọba lórí Israẹli. Ẹ fọn fèrè, kí ẹ sì ké pé, ‘Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!’
35 Potem pójdziecie za nim, a on przyjdzie i zasiądzie na moim tronie, i będzie królował na moje miejsce. Jego bowiem ustanowiłem wodzem nad Izraelem i nad Judą.
Nígbà náà ni kí ẹ sì gòkè pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì wá, kí ó sì jókòó sórí ìtẹ́ mi, kí ó sì jẹ ọba ní ipò mi. Èmi ti yàn án ní ọba lórí gbogbo Israẹli àti Juda.”
36 Benajasz, syn Jehojady, odpowiedział królowi: Amen. Niech to stwierdzi PAN, Bóg mego pana, króla.
Benaiah ọmọ Jehoiada sì dá ọba lóhùn pé, “Àmín! Kí Olúwa Ọlọ́run olúwa mi ọba, kéde rẹ̀ bẹ́ẹ̀.
37 Jak PAN był z moim panem, królem, tak niech będzie z Salomonem i niech wywyższy jego tron nad tron mego pana, króla Dawida.
Bí Olúwa ti wà pẹ̀lú olúwa mi ọba, bẹ́ẹ̀ ni kí ó wà pẹ̀lú Solomoni kí ó lè mú kí ìjọba rẹ̀ pẹ́ ju ìtẹ́ olúwa mi Dafidi ọba lọ!”
38 Poszli więc kapłan Sadok, prorok Natan i Benajasz, syn Jehojady, oraz Keretyci i Peletyci i wsadzili Salomona na mulicę króla Dawida, i zaprowadzili go do Gichonu.
Nígbà náà ni Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada, àwọn ará Kereti àti Peleti sì sọ̀kalẹ̀ wá wọ́n sì gbé Solomoni gun ìbáaka Dafidi ọba wá sí Gihoni.
39 Wtedy kapłan Sadok wziął róg olejku z namiotu i namaścił Salomona. Potem zadęto w trąbę, a cały lud powiedział: Niech żyje król Salomon!
Sadoku àlùfáà sì mú ìwo òróró láti inú àgọ́, ó sì dà á sí Solomoni lórí. Nígbà náà ni wọ́n sì fọn fèrè, gbogbo àwọn ènìyàn sì ké pé, “Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!”
40 I cały lud szedł za nim. Lud także grał na fletach i tak bardzo się radował, że ziemia drżała od jego głosu.
Gbogbo ènìyàn sì gòkè tọ̀ ọ́ lẹ́yìn wọ́n ń fọn ìpè, wọ́n sì ń yọ ayọ̀ ńlá, tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ mì fún ìró wọn.
41 I usłyszeli to Adoniasz oraz wszyscy zaproszeni, którzy z nim byli, a właśnie skończyli ucztę. A gdy Joab usłyszał głos trąby, zapytał: Cóż to za krzyk poruszonego miasta?
Adonijah àti gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ ọ́ bí wọ́n ti ń jẹun tán, wọ́n ń gbọ́ ìpè, Joabu sì wí pé, “Kí ní ìtumọ̀ gbogbo ariwo nínú ìlú yìí?”
42 A gdy on jeszcze mówił, przyszedł Jonatan, syn kapłana Abiatara. Adoniasz powiedział mu: Wejdź, jesteś bowiem dzielnym człowiekiem i przynosisz dobrą nowinę.
Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Jonatani ọmọ Abiatari àlùfáà sì dé, Adonijah sì wí pé, “Wọlé wá, ọkùnrin yíyẹ ìwọ gbọdọ̀ mú ìròyìn rere wá.”
43 Wtedy Jonatan odpowiedział Adoniaszowi: Nasz pan, król Dawid, ustanowił królem Salomona.
Jonatani sì dáhùn, ó sì wí fún Adonijah pé, “Lóòótọ́ ni olúwa wa Dafidi ọba, fi Solomoni jẹ ọba.
44 Król bowiem posłał z nim kapłana Sadoka i proroka Natana oraz Benajasza, syna Jehojady, do tego Keretytów i Peletytów, którzy wsadzili go na mulicę króla;
Ọba sì ti rán Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada àti àwọn ará Kereti àti Peleti pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì ti gbé e gun ìbáaka ọba,
45 Następnie kapłan Sadok i prorok Natan namaścili go na króla w Gichonie. I wyruszyli stamtąd, tak się radując, że miasto zadrżało. Stąd ten krzyk, który usłyszeliście.
Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì ti fi òróró yàn án ní ọba ní Gihoni. Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gòkè wá pẹ̀lú ayọ̀, ìlú sì ń hó pẹ̀lú rẹ̀. Èyí ni ariwo tí ẹ̀yin ń gbọ́.
46 A Salomon zasiadł już na tronie królestwa.
Solomoni sì ti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀.
47 Ponadto przyszli słudzy króla, aby błogosławić naszemu panu, królowi Dawidowi, mówiąc: Niech Bóg sławniejszym uczyni imię Salomona niż twoje imię i niech wywyższy jego tron ponad twój tron. A król skłonił się na [swym] łożu.
Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì ti tún wá láti bá olúwa wa Dafidi ọba yọ̀, wí pé, ‘Kí Ọlọ́run rẹ̀ mú orúkọ Solomoni lókìkí ju tirẹ̀ lọ àti kí ìtẹ́ rẹ̀ kí ó pọ̀ ju tirẹ̀ lọ!’ Ọba sì tẹ ara rẹ̀ ba lórí ibùsùn rẹ̀,
48 Również sam król powiedział: Błogosławiony [niech będzie] PAN, Bóg Izraela, który dał dziś zasiadającego na moim tronie, a moje oczy to widzą.
ọba sì wí pé, ‘Ògo ni fún Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti jẹ́ kí ojú mi rí ẹnìkan tí ó jókòó lórí ìtẹ́ mi lónìí.’”
49 Wtedy zlękli się wszyscy zaproszeni, którzy byli z Adoniaszem, i wstali, i poszli każdy swoją drogą.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ Adonijah dìde ní ìdágìrì, wọ́n sì túká.
50 Adoniasz także, bojąc się Salomona, wstał, poszedł i uchwycił się rogów ołtarza.
Ṣùgbọ́n Adonijah sì bẹ̀rù Solomoni, ó lọ, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
51 I doniesiono o tym Salomonowi: Oto Adoniasz boi się króla Salomona i uchwycił się rogów ołtarza, mówiąc: Niech mi dziś przysięgnie król Salomon, że nie zabije swego sługi mieczem.
Nígbà náà ni a sì sọ fún Solomoni pé, “Adonijah bẹ̀rù Solomoni ọba, ó sì di ìwo pẹpẹ mú, Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí ọba Solomoni búra fún mi lónìí pé, òun kì yóò fi idà pa ìránṣẹ́ rẹ̀.’”
52 Wtedy Salomon odpowiedział: Jeśli okaże się godziwym człowiekiem, nie spadnie mu nawet włos na ziemię, ale jeśli znajdzie się w nim zło, poniesie śmierć.
Solomoni sì dáhùn pé, “Bí ó bá fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ ẹni ọ̀wọ̀, irun orí rẹ̀ kan kì yóò sì bọ́ sílẹ̀; ṣùgbọ́n bí a bá rí búburú kan ní ọwọ́ rẹ̀ òun yóò kú.”
53 Król Salomon posłał więc, aby go sprowadzono od ołtarza. Kiedy przyszedł, pokłonił się królowi Salomonowi. A powiedział mu Salomon: Idź do swego domu.
Nígbà náà ni Solomoni ọba rán àwọn ènìyàn, wọ́n sì mú un sọ̀kalẹ̀ láti ibi pẹpẹ wá. Adonijah sì wá, ó sì foríbalẹ̀ fún Solomoni ọba, Solomoni sì wí pé, “Lọ ilé rẹ.”

< I Królewska 1 >