< I Kronik 4 >
1 Synowie Judy: Peres, Chesron, Karmi, Chur i Szobal.
Àwọn ọmọ Juda: Peresi, Hesroni, Karmi, Huri àti Ṣobali.
2 A Reajasz, syn Szobala, spłodził Jachata, a Jachat spłodził Achumaja i Lahada. To są rody Soreatytów.
Reaiah ọmọ Ṣobali ni baba Jahati, àti Jahati baba Ahumai àti Lahadi. Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀yà ará Sorati.
3 A ci pochodzą od ojca Etama: Jizreel, Jiszma i Jidbasz, a ich siostra miała na imię Haselelponi.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Etamu: Jesreeli, Iṣima, Idbaṣi, orúkọ arábìnrin wọn sì ni Haseleponi
4 Penuel [był] ojcem Gedora, a Ezer – ojcem Chuszy. To są synowie Chura, pierworodnego Efraty, ojca Betlejema.
Penueli sì ni baba Gedori, àti Eseri baba Huṣa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata àti baba Bẹtilẹhẹmu.
5 A Aszur, ojciec Tekoa, miał dwie żony: Chelę i Naarę.
Aṣihuri baba Tekoa sì ní aya méjì, Hela àti Naara.
6 I Naara urodziła mu Achuzama, Chefera, Temniego i Achasztariego. Ci [byli] synami Naary.
Naara sì bí Ahussamu, Heferi Temeni àti Haaṣtari. Àwọn wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Naara.
7 Synowie Cheli: Seret, Jesochar i Etnan.
Àwọn ọmọ Hela: Sereti Sohari, Etani,
8 A Koz spłodził Anuba, Zobeba i rody Acharchela, syna Haruma.
àti Kosi ẹni tí ó jẹ́ baba Anubu àti Sobeba àti ti àwọn ẹ̀yà Aharheli ọmọ Harumu.
9 A Jabes był bardziej poważany niż jego bracia. Jego matka dała mu na imię Jabes, mówiąc: Ponieważ urodziłam go w bólu.
Jabesi sì ní ọlá ju àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jabesi wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”
10 I Jabes wzywał Boga Izraela, mówiąc: Obyś mi naprawdę błogosławił i rozszerzył moje granice, oby twoja ręka była ze mną, obyś zachował [mnie] od zła, abym nie był utrapiony. I Bóg spełnił to, o co go prosił.
Jabesi sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Israẹli wí pé, “Háà, Ìwọ yóò bùkún fún mi, ìwọ yóò sì mú agbègbè mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mi mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀.
11 A Kelub, brat Szuchy, spłodził Mechira, który był ojcem Esztona.
Kelubu arákùnrin Ṣuha, sì jẹ́ baba Mehiri, ẹni tí ó jẹ́ baba Eṣtoni.
12 A Eszton spłodził Betrafę, Paseacha i Techinnę, ojca Irnachasza. To [są] mężczyźni z Rechy.
Eṣtoni sì jẹ́ baba Beti-Rafa, Pasea àti Tehina ti baba ìlú Nahaṣi. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Reka.
13 Synowie Kenaza: Otniel i Serajasz, a synowie Otniela: Chatat [i Meonotaj].
Àwọn ọmọ Kenasi: Otnieli àti Seraiah. Àwọn ọmọ Otnieli: Hatati àti Meonotai.
14 Meonotaj spłodził Ofrę. Serajasz zaś spłodził Joaba, ojca Charaszimów mieszkających w dolinie – byli bowiem rzemieślnikami.
Meonotai sì ni baba Ofira. Seraiah sì jẹ́ baba Joabu, baba Geharaṣinu. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn oníṣọ̀nà ní ìwọ̀n.
15 Synowie Kaleba, syna Jefunnego: Iru, Ela i Naam. A synem Eli był Kenaz.
Àwọn ọmọ Kalebu ọmọ Jefunne: Iru, Ela, àti Naamu. Àwọn ọmọ Ela: Kenasi.
16 Synowie Jehalleleela: Zif, Zifa, Tiria i Asareel.
Àwọn ọmọ Jehaleeli: Sifi, àti Sifa, Tiria àti Asareeli.
17 Synowie Ezry: Jeter, Mered, Efer i Jalon. [A żona Mereda] urodziła Miriama, Szammaja i Iszbacha, ojca Esztemoi.
Àwọn ọmọ Esra: Jeteri, Meredi, Eferi àti Jaloni. Ọ̀kan lára àwọn aya Meredi sì bí Miriamu, Ṣammai àti Iṣba baba Eṣitemoa.
18 Jego żona Jehudaja urodziła Jereda, ojca Gedora, Chebera, ojca Soko, i Jekutiela, ojca Zanoacha. To [są] synowie Bitii, córki faraona, którą pojął za żonę Mered.
Aya rẹ̀ láti ẹ̀yà Juda sì bí Jaredi baba Gedori, àti Heberi baba Soko àti Jekutieli baba Sanoa. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọbìnrin Farao Bitia, ẹni ti Meredi ti fẹ́.
19 Synowie jego żony Hodijji, siostry Nahama, ojca Keili: Garmity i Esztemoa, Maakatyta.
Àwọn ọmọ aya Hodiah arábìnrin Nahamu, baba Keila ará Garimu, àti Eṣitemoa àwọn ará Maakati.
20 Synowie Szimona: Amnon, Rinna, Benchanan i Tilon. A synowie Jisziego: Zochet i Benzochet.
Àwọn ọmọ Ṣimoni: Amnoni, Rina, Beni-Hanani àti Tiloni. Àwọn ọmọ Iṣi: Soheti àti Beni-Soheti.
21 Synowie Szeli, syna Judy: Er, ojciec Leki, Laada, ojciec Mareszy i tych rodów, które wytwarzały bisior w domu Aszbea;
Àwọn ọmọ Ṣela ọmọ Juda: Eri baba Leka, Lada baba Meraṣa àti àwọn ìdílé ilé àwọn tí ń hun aṣọ oníṣẹ́ ní Beti-Aṣibea.
22 Jokim i mężczyźni Kozeby oraz Joasz i Saraf, którzy panowali w Moabie, a także Jaszubilechem. To [są] dawne wydarzenia.
Jokimu, ọkùnrin Koseba, àti Joaṣi àti Sarafi, olórí ní Moabu àti Jaṣubi Lehemu. (Àkọsílẹ̀ yìí sì wà láti ìgbà àtijọ́.)
23 Byli oni garncarzami i mieszkali w sadach i między płotami. Mieszkali tam przy królu i pracowali dla niego.
Àwọn sì ni amọ̀kòkò tí ń gbé ní Netaimu àti Gedera; wọ́n sì dúró níbẹ̀ wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ fún ọba.
24 Synowie Symeona: Nemuel, Jamin, Jarib, Zerach i Saul.
Àwọn ọmọ Simeoni: Nemueli, Jamini, Jaribi, Sera àti Saulu;
25 Jego syn Szallum, jego syn Mibsam, jego syn Miszma.
Ṣallumu sì jẹ́ ọmọ Saulu, Mibsamu ọmọ rẹ̀ Miṣima ọmọ rẹ̀.
26 A synowie Miszmy: jego syn Chamuel, jego syn Zakkur, jego syn Szimei.
Àwọn ọmọ Miṣima: Hamueli ọmọ rẹ̀ Sakkuri ọmọ rẹ̀ àti Ṣimei ọmọ rẹ̀.
27 Szimei miał szesnastu synów i sześć córek, lecz jego bracia nie mieli wielu synów i wszystkie ich rody nie były tak liczne jak [rody] synów Judy.
Ṣimei sì ní ọmọkùnrin mẹ́rìndínlógún àti ọmọbìnrin mẹ́fà, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin kò ní ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìdílé wọn kò sì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn Juda.
28 Mieszkali oni w Beer-Szebie, Molada i w Chasar-Szual;
Wọ́n sì ń gbé ní Beerṣeba, Molada, Hasari-Ṣuali,
29 W Bilha, Esem i Tolad;
àti ní Biliha, àti ní Esemu, àti ní Toladi,
30 W Betuel, Chorma i Siklag;
Betueli, Horma, Siklagi,
31 W Bet-Markabot, Chasar-Susim, Bet-Birei i Szaaraim. To były ich miasta aż do panowania Dawida.
Beti-Markaboti Hormah; Hasari Susimu, Beti-Biri àti Ṣaraimi. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dafidi,
32 A ich wioskami [były]: Etam, Ain, Rimmon, Token i Aszan, pięć miast;
agbègbè ìlú wọn ni Etamu, Aini, Rimoni, Tokeni, Aṣani àwọn ìlú márùn-ún,
33 Oraz wszystkie ich wioski [położone] dokoła tych miast aż do Baal. To były ich miejsca zamieszkania i spisy ich rodów.
àti gbogbo ìletò wọn, tí ó wà yí ìlú náà ká, dé Baali. Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn. Àti ìtàn ìdílé wọ́n.
34 Meszobab, Jamlek i Josza, syn Amazjasza;
Meṣobabu àti Jamleki, Josa ọmọ Amasiah,
35 Joel i Jehu, syn Joszibiasza, syna Serajasza, syna Asiela;
Joẹli, Jehu ọmọ Josibiah, ọmọ Seraiah, ọmọ Asieli,
36 I Elioenaj, Jaakoba, Jeszochajasz, Asajasz, Adiel, Jesimiel i Benajasz;
àti pẹ̀lú Elioenai, Jaakoba, Jeṣohaiah, Asaiah, Adieli, Jesimieli, Benaiah,
37 Ziza, syn Szifiego, syna Allona, syna Jedajasza, syna Szimriego, syna Semajasza.
àti Sisa ọmọ Ṣifi ọmọ Alloni, ọmọ Jedaiah, ọmọ Ṣimri ọmọ Ṣemaiah.
38 Ci wymienieni imiennie byli naczelnikami w swoich rodach, a rodziny ich ojców bardzo się rozrosły.
Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ sí i gidigidi,
39 I dotarli aż do wejścia do Gedor, aż na wschodnią stronę doliny, szukając pastwiska dla swych trzód.
wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gedori. Lọ títí dé ìlà-oòrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn.
40 I znaleźli obfite i dobre pastwiska oraz ziemię obszerną, spokojną i bezpieczną. Tam bowiem mieszkali przedtem Chamici.
Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ọmọ Hamu ni ó ti ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
41 Zapisani [tu] imiennie przyszli za czasów Ezechiasza, króla Judy, zniszczyli ich namioty i przybytki, które się tam znajdowały, doszczętnie wygubili ich i osiedlili się na ich miejscu. Tam bowiem były pastwiska dla ich trzód.
Àwọn ọkùnrin tí a kọ orúkọ rẹ̀ sókè, dé ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Wọ́n sì kọlu àwọn ará Hamu ní àgọ́ wọn àti pẹ̀lú àwọn ará Mehuni tí a rí níbẹ̀ tí ó sì pa wọ́n run pátápátá títí di òní yìí. Wọ́n sì ń gbé ní ipò wọn, nítorí pé koríko ń bẹ níbẹ̀ fún agbo ẹran wọn.
42 [Niektórzy] z nich, pięciuset mężczyzn spośród synów Symeona, udali się na górę Seir, a ich przywódcami byli: Pelatiasz, Neariasz, Refajasz i Uzziel, synowie Jisziego.
Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ará Simeoni, lábẹ́ ìdarí pẹ̀lú Pelatiah, Neariah, Refaiah àti Usieli, àwọn ọmọ Iṣi, gbógun sí àwọn òkè ìlú ti Seiri.
43 I pobili resztę ocalałych Amalekitów, i zamieszkali tam do dziś.
Wọ́n sì pa àwọn ará Amaleki tí ó kù, àwọn tí ó ti sálà, wọ́n sì ti ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.