< Sofoniasza 3 >

1 Biada temu miastu zmazanemu i splugawionemu, gwałty czyniącemu!
Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
2 Nie słucha głosu, ani przyjmuje karności, w Panu nie ufa, do Boga swego nie przybliża się.
Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
3 Książęta jego w pośrodku jego są lwy ryczące, sędziowie jego są wilki wieczorne, które nie gryzą kości aż do poranku.
Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
4 Prorocy jego skwapliwi, mężowie przewrotni; kapłani jego splugawili rzeczy święte, zakon gwałcą.
Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
5 Pan sprawiedliwy jest w pośród niego, nie czyni nieprawości, każdego dnia sąd swój wydaje na światłość bez przestania; wszakże złośnik wstydzić się nie umie.
Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
6 Wykorzeniłem narody, spustoszone są zamki ich, obróciłem w pustynię ulice ich, tak, że niemasz, ktoby przez nie chodził; spustoszone są miasta ich, tak, że niemasz ani człowieka ani obywatela.
“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
7 Rzekłem: Wżdyć się mnie bać będziesz, przyjmiesz karność, aby nie był wytracony przybytek twój, przez to, czemem cię nawiedzić chciał; ale rano wstawszy psują wszystkie przedsięwzięcia swoje.
Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
8 Przetoż oczekiwajcie na mię, mówi Pan, do dnia, którego powstanę do łupu; bo sąd mój jest, abym zebrał narody, i zgromadził królestwa, abym na nie wylał rozgniewanie moje i wszystkę popędliwość gniewu mego; ogniem zaiste gorliwości mojej będzie po żarta ta wszystka ziemia.
Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
9 Bo na ten czas przywrócę narodom wargi czyste, któremiby wzywali wszyscy imienia Pańskiego, a służyli mu jednomyślnie.
“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
10 Ci, którzy są za rzekami ziemi Murzyńskiej, pokłon mi oddają z córką rozproszonych moich, przyniosą mi dary.
Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11 Dnia onego nie zawstydzisz się za żadne uczynki twoje, któremiś wystąpiło przeciwko mnie; bo na ten czas odejmę z pośrodku ciebie tych, którzy się weselą z sławy twojej, a nie będziesz się więcej wywyższało na górze świętobliwości mojej.
Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
12 I zostawię w pośrodku ciebie lud ubogi a nędzny, i ufać będą w imieniu Pańskiem.
Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13 Ostatki Izraela nie będą czyniły nieprawości, ani będą mówiły kłamstwa, ani się znajdzie w ustach ich język zdradliwy; ale się paść będą i odpoczywać, a nie będzie, ktoby je przestraszył.
Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
14 Zaśpiewaj, córko Syońska! wykrzykajcie, Izraelczycy! wesel się a raduj się ze wszystkiego serca, córko Jeruzalemska!
Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15 Że odjął Pan sądy twoje, uprzątnął nieprzyjaciela twego; król Izraelski jest Panem w pośrodku ciebie, nie oglądasz więcej złego.
Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16 Dnia onego rzeką do Jeruzalemu: Nie bój się! a do Syonu: Niech nie mdleją ręce twoje!
Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17 Pan, Bóg twój, w pośrodku ciebie mocny zachowa cię, rozweseli się wielce nad tobą, przestanie na miłości swej przeciwko tobie, i rozweseli się nad tobą z śpiewaniem, mówiąc:
Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
18 Tęskniących po Jeruzalemie zasię zgromadzę, bo z ciebie są i smutni dla brzemienia zelżywości włożonej na cię.
“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19 Oto Ja koniec uczynię wszystkim, którzy cię trapić będą na on czas, a zachowam chromą, i wygnaną zgromadzę; owszem sposobię im chwałę i imię po wszystkiej ziemi, w której zelżywość ponosili.
Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20 Wtenczas przywiodę was, wtenczas, mówię, zgromadzę was; albowiem dam wam imię i chwałę między wszystkimi narodami ziemi, gdy zaś przywiodę więźnie wasze przed oczyma waszemi, mówi Pan.
Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.

< Sofoniasza 3 >