< Zachariasza 9 >

1 Brzemię słowa Pańskiego przeciwko ziemi, która jest w około ciebie, a Damaszek będzie odpocznieniem jego; albowiem oko Pańskie przypatruje się ludziom i wszystkim pokoleniom Izraelskim;
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki, Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀; nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn, àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
2 Nawet i do Emat dosięże, i do Tyru i do Sydonu, choć jest mądry bardzo.
Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀ Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.
3 Bo sobie Tyr obronę zbudował, i nazbierał srebra jako prochu, a złota jako błota po ulicach.
Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀, ó sì kó fàdákà jọ bí eruku, àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.
4 Oto Pan go wypędzi, a wrazi w morze siłę jego, a sam od ognia pożarty będzie.
Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ, yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun, a ó sì fi iná jó o run.
5 Co widząc Aszkalon, ulęknie się, także Gaza wielce żałośne będzie, i Akaron, przeto, że je zawstydziła nadzieja ich; i zginie król z Gazy, a Aszkalon nie będzie osadzone;
Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù; Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi, àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í. Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀, Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
6 I będzie mieszkał bękart w Azocie, a tak wykorzenię pychę Filistyńczyków.
Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu, Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
7 I odejmę krew każdego od ust jego, i obrzydliwości jego od zębów jego; zostawiony też będzie i on Bogu naszemu, aby był jako książę w Judzie, a Akaron jako Jebuzejczycy.
Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀, àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀: ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa, wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda, àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.
8 I położę się obozem u domu swego dla wojska, i dla przechodzącego a wracającego się; i nie przejdzie więcej przez nich łupieżca, przeto, że się tak teraz podoba w oczach moich.
Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri, kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́: nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.
9 Wesel się bardzo, córko Syońska! wykrzykaj, córko Jeruzalemska! Oto król twój przyjdzie tobie sprawiedliwy i zbawiciel ubogi i siedzący na ośle, to jest, na oślęciu, źrebiątku oślicy.
Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu. Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ: òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà; ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
10 Bo wytracę wozy z Efraima, i konie z Jeruzalemu, i będzie połamany łuk wojenny; i ogłosi pokój narodom, a władza jego (będzie) od morza aż do morza, i od rzeki aż do kończyn ziemi.
Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu, àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu, a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun. Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí. Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun, àti láti odò títí de òpin ayé.
11 Owszem, ty wesel się dla krwi przymierza swego; albowiem wypuściłem więźniów twoich z dołu, w którym niemasz wody.
Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.
12 Wróćcież się tedy do twierdzy, o więźniowie, którzy nadzieję macie! albowiemci i dziś dwojako opowiadam i nagrodzę.
Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí: àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.
13 Gdyż sobie naciągnę Judę, a łuk napełnię Efraimem; i wzbudzę synów twoich, o Syonie! przeciwko synom twoim, o Jawanie! i zgotuję cię jako miecz mocarza.
Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le, mo sì fi Efraimu kún un, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni, sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki, mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.
14 Bo się Pan ukaże przeciwko nim, a jako blask wyniknie strzała jego; panujący, mówię, Pan zatrąbi w trąbę, a pójdzie w wichrach południowych.
Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn; ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná. Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè, Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.
15 Pan zastępów ochraniać będzie lud swój, aby podbiwszy sobie kamienie z procy, jedli i pili wykrzykając jako od wina; i napełnią, jako miednice, tak i rogi ołtarza.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n; wọn ó sì jẹ ni run, wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀; wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì, wọn ó sì kún bí ọpọ́n, wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.
16 A tak wybawi ich dnia onego Pan, Bóg ich, jako trzodę ludu swego; bo kamienie wieńcami ozdobione, wystawione będą miasto chorągwi w ziemi jego.
Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà bí agbo ènìyàn rẹ̀: nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé, tí a gbé sókè bí àmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Albowiem oto o jakie błogosławieństwo jego! i jako wielka ozdoba jego! Zboże młodzieńców, a moszcz panny mowne uczyni.
Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀! Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá, àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.

< Zachariasza 9 >