< Tytusa 1 >

1 Paweł, sługa Boży i Apostoł Jezusa Chrystusa według wiary wybranych Bożych i znajomości prawdy, która jest według pobożności,
Paulu, ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti aposteli Jesu Kristi, gẹ́gẹ́ bí ìgbàgbọ́ àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run àti ìmọ̀ òtítọ́ irú èyí tí í máa darí ènìyàn sí ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run—
2 Ku nadziei żywota wiecznego, który obiecał przed czasy wiekuistemi ten, który nie kłamie, Bóg, a objawił czasów swoich, (aiōnios g166)
ìgbàgbọ́ àti ìmọ̀ tí ó dúró lórí ìrètí iyè àìnípẹ̀kun, èyí tí Ọlọ́run tí kì í purọ́ ti ṣe ìlérí rẹ̀ ṣáájú kí ayé tó bẹ̀rẹ̀, (aiōnios g166)
3 To słowo swoje przez kazanie, które mi jest zwierzone według rozrządzenia zbawiciela naszego Boga:
àti pé ní àkókò tirẹ̀, òun ti fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ hàn nínú ìwàásù tí a fi lé mi lọ́wọ́ nípa àṣẹ Ọlọ́run Olùgbàlà wa,
4 Tytusowi, własnemu synowi według spólnej wiary, łaska, miłosierdzie i pokój niech będzie od Boga Ojca, i Pana Jezusa Chrystusa, zbawiciela naszego.
Sí Titu, ọmọ mi tòótọ́ nínú ìgbàgbọ́ wa kan náà: Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba àti Kristi Jesu Olùgbàlà wa.
5 Dlategom cię zostawił w Krecie, abyś to, co tam jeszcze zostaje, w rząd dobry wprawił i postanowił po miastach starszych, jakom ci ja był rozkazał;
Ìdí tí mo fi fi ọ́ sílẹ̀ ní Krete ni pé kí o lè ṣe àṣepé àwọn iṣẹ́ tó ṣẹ́kù. Mo sì ń rọ̀ ọ́ kí o yan àwọn alàgbà ní ìlú kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí mo ṣe darí rẹ̀.
6 Jeźli kto jest bez nagany, mąż jednej żony, dzieci wierne mający, które by nie mogły być obwinione w zbytku, albo niepoddane rządowi.
Ẹni tí yóò jẹ́ alàgbà gbọdọ̀ jẹ́ aláìlábùkù, wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ onìyàwó kan, ọmọ wọn náà gbọdọ̀ jẹ́ onígbàgbọ́ tí kò ní ẹ̀sùn ìwà ipá tàbí ẹ̀sùn àìgbọ́ràn kankan.
7 Albowiem biskup ma być bez nagany, jako szafarz Boży, nie sam sobie się podobający, nie gniewliwy, nie pijanica wina, nie bitny, nie szukający zysku sprośnego;
Alábojútó jẹ́ ẹni tí a gbé iṣẹ́ Ọlọ́run lé lọ́wọ́, nítorí náà, kò gbọdọ̀ ní àbùkù kankan tàbí agbéraga, oníjà, kò gbọdọ̀ jẹ́ ọ̀mùtí tàbí alágídí tàbí olójúkòkòrò.
8 Ale gościnny, dobre miłujący, roztropny, sprawiedliwy, świętobliwy, powściągliwy,
Wọ́n ní láti jẹ́ olùfẹ́ àlejò ṣíṣe, olùfẹ́ ohun tí ó dára. Wọ́n ní láti jẹ́ ẹni tí ó kò ara rẹ̀ ní ìjánu, ẹni dúró ṣinṣin, ọlọ́kàn mímọ́, àti ẹni oníwàtítọ́.
9 Trzymający się onej wiernej mowy, która jest według nauki, iżby też mógł napominać nauką zdrową i tych, którzy się sprzeciwiają, przekonywać;
Ó gbọdọ̀ di ẹ̀kọ́ nípa ìdúró ṣinṣin mú dáradára gẹ́gẹ́ bí ó ti kọ́ ọ, kí ó lè fi ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro kọ́ àwọn ẹlòmíràn. Nípa èyí, yóò lè fi ìdí òtítọ́ múlẹ̀ fún àwọn alátakò.
10 Albowiem jest wiele rządowi niepoddanych, próżnomównych i zwodzicieli myśli, a najwięcej tych, którzy są z obrzezki,
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni ọlọ̀tẹ̀, asọ̀rọ̀ asán àti ẹlẹ́tàn pàápàá jùlọ láàrín àwọn onílà.
11 Którym trzeba usta zatkać; którzy całe domy podwracają, ucząc rzeczy niesłusznych dla zysku sprośnego.
Ó gbọdọ̀ pa wọ́n lẹ́nu mọ́, nítorí wí pé wọ́n ń pa agbo Ọlọ́run run, nípasẹ̀ àwọn ẹ̀kọ́ tí kò jẹ́ èyí tí wọ́n ń kọ́ni. Èyí ni wọ́n ń ṣe fún ère àìṣòdodo.
12 Powiedział niektóry z nich własny ich prorok: Kreteńczycy zawsze są kłamcami, złemi bestyjami, brzuchami leniwemi.
Ọ̀kan nínú àwọn wòlíì wọn pàápàá sọ wí pé. “Òpùrọ́ ní àwọn ará Krete, wọ́n jẹ́ ẹranko búburú tí kò sé tù lójú, ọ̀lẹ, àti oníwọra”.
13 To świadectwo jest prawdziwe; dla której przyczyny ostro ich karz, aby zdrowi byli w wierze.
Òtítọ́ ni ẹ̀rí yìí. Nítorí náà, bá wọn wí gidigidi, kí wọn ba à lè yè koro nínú ìgbàgbọ́
14 Nie pilnując żydowskich baśni i przykazań ludzi tych, którzy się odwracają od prawdy.
kí àwọn má ṣe fiyèsí ìtàn lásán ti àwọn Júù, àti òfin àwọn ènìyàn tí wọ́n yípadà kúrò nínú òtítọ́.
15 Wszystkoć czyste czystym, lecz pokalanym i niewiernym nie masz nic czystego, ale pokalany jest i umysł, i sumienie ich.
Sí ọlọ́kàn mímọ́, ohun gbogbo ló jẹ́ mímọ́, ṣùgbọ́n àwọn tó ti díbàjẹ́ tí wọ́n kò sí ka ohunkóhun sí mímọ́. Nítòótọ́, àti ọkàn àti ẹ̀rí ọkàn wọn ló ti díbàjẹ́.
16 Udawają, że Boga znają; ale uczynkami swemi tego się zapierają, będąc obrzydłymi i nieposłusznymi, a do wszelkiego dobrego uczynku niesposobnymi.
Wọ́n ń fẹnu sọ wí pé àwọn mọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n wọ́n sẹ́ ẹ nípa ìṣe wọn. Wọ́n díbàjẹ́, wọn si jẹ aláìgbọ́ràn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò wúlò lọ́nàkọnà ní ti iṣẹ́ rere gbogbo.

< Tytusa 1 >