< Rut 2 >

1 A Noemi miała powinowatego po mężu swym, człowieka możnego z domu Elimelechowego, którego zwano Booz.
Naomi ní ìbátan kan láti ìdílé Elimeleki ọkọ rẹ̀, aláàánú ọlọ́rọ̀, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi.
2 I rzekła Ruta Moabitka do Noemi: Pójdę proszę na pole, a niech zbieram kłosy za tym, przed którego oczyma łaskę znajdę; a ona rzekła: Idź, córko moja.
Rutu ará Moabu sì wí fún Naomi pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó lọ sí inú oko láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni tí èmi yóò bá ojúrere rẹ̀ pàdé.” Naomi sì sọ fún un pé, “Máa lọ, ọmọbìnrin mi.”
3 Szła tedy, a przyszedłszy zbierała na polu za żeńcami; i trafiło się, że przyszła na dział pola Boozowego, który był z domu Elimelechowego.
Rutu sì jáde lọ láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ lẹ́yìn wọn. Ó wá jẹ́ wí pé inú oko Boasi tí ó ti ìdílé Elimeleki wá ni ó lọ láìmọ̀-ọ́n-mọ̀.
4 A wtem przyszedł Booz z Betlehem, i rzekł do żeńców: Pan z wami. A oni mu odpowiedzieli: Niechżeć Pan błogosławi.
Nígbà náà ni Boasi dé láti Bẹtilẹhẹmu tí ó sì kí àwọn olùkórè wí pé, “Kí Olúwa wà pẹ̀lú yín.” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa bùkún fún ọ.”
5 Rzekł tedy Booz do sługi swego, który był przystawem nad żeńcami: Czyjaż to dzieweczka?
Boasi sì béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùkórè wí pé, “Ti ta ni ọ̀dọ́mọbìnrin yẹn?”
6 I odpowiedział mu sługa on, który był przystawem nad żeńcami, i rzekł: Ta dzieweczka jest Moabitka, która przyszła z Noemi z ziemi Moabskiej.
Ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olórí àwọn olùkórè náà sì fèsì pé, “Ọ̀dọ́mọbìnrin ará Moabu tí ó tẹ̀lé Naomi wá láti ilẹ̀ Moabu ni.
7 I rzekła mi: Niech proszę zbieram i zgromadzam kłosy między snopami za żeńcami; a przyszedłszy bawi się tu od samego poranku aż dotąd, a bardzo mało w domu siedzi.
Ó sọ wí pé, ‘Kí ń jọ̀wọ́ jẹ́ kí òun máa ṣá ọkà lẹ́yìn àwọn olùkórè.’ Ó sì ti ń ṣe iṣẹ́ kárakára láti òwúrọ̀ títí di ìsinsin yìí nínú oko àyàfi ìgbà tí ó lọ láti sinmi fún ìgbà díẹ̀ lábẹ́ ibojì.”
8 Tedy rzekł Booz do Rut: Słuchaj mię córko moja; nie chodź zbierać kłosów na insze pole i nie odchodź stąd, ale się tu trzymaj dziewek moich.
Nígbà náà ni Boasi sọ fún Rutu pé, “Gbọ́ ọmọbìnrin mi, má ṣe lọ sí oko mìíràn láti ṣá ọkà, má sì ṣe kúrò ní ibi. Dúró níbí pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi.
9 Pilnuj tego pola, na którem żąć będą, a chodź za nimi; bom rozkazał sługom moim, żeby się ciebie żaden nie tykał; a jeźli upragniesz, idź do naczynia, a napij się z tego, co czerpią słudzy moi.
Wo ibi tí wọ́n ti ń kórè kí o sì máa tẹ̀lé àwọn obìnrin. Mo ti pàṣẹ fún àwọn ọkùnrin kí wọ́n má ṣe fi ọwọ́ kàn ọ́. Nígbàkígbà tí òǹgbẹ bá sì ń gbẹ ọ́, lọ kí ó sì mu omi nínú àmù èyí tí àwọn ọkùnrin ti pọn omi sí nínú.”
10 Tedy ona upadłszy na oblicze swoje, ukłoniwszy się aż do ziemi rzekła do niego: Skądżem znalazła łaskę w oczach twoich, iż mię znasz, gdyżem jest cudzoziemka?
Rutu wólẹ̀, ó sì wí fún Boasi pé, “Èéṣe tí èmi fi bá ojúrere rẹ pàdé tó báyìí, tí o sì kíyèsi mi, èmi àjèjì àti àlejò?”
11 I odpowiedział Booz, a rzekł jej: Powiedziano mi zapewne wszystko, coś uczyniła świekrze twojej po śmierci męża twego, a jakoś opuściwszy ojca twego i matkę twoję, i ziemię, w którejś się urodziła, przyszła do ludu, któregoś nie znała przedtem.
Boasi sì fèsì wí pé, “Èmi ti gbọ́ gbogbo bí o ti ń ṣe sí ìyá ọkọ ọ̀ rẹ láti ìgbà tí ọkọ rẹ ti kú àti bí o ti ṣe fi baba àti ìyá rẹ àti ilẹ̀ rẹ sílẹ̀, tí o sì wá láti gbé láàrín àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
12 Niechżeć odda Pan uczynek twój, i niech będzie zapłata twoja doskonała od Pana, Boga Izraelskiego, gdyżeś przyszła, abyś nadzieję miała pod skrzydłami jego.
Kí Olúwa kí ó san ẹ̀san ohun tí ìwọ ṣe fún ọ. Kí o sì gba èrè kíkún láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, abẹ́ ìyẹ́ ẹni tí ìwọ sá wá fún ààbò.”
13 A ona rzekła: Znalazłam łaskę w oczach twoich, panie mój, gdyżeś mię pocieszył, a mówiłeś do serca służebnicy twojej, chociam ja nie jest, jako jedna z służebnic twoich.
Rutu sì fèsì wí pé, “Kí èmi kí ó máa rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ rẹ síwájú sí i olúwa mi. Ìwọ ti tù mí nínú nípa sísọ ọ̀rọ̀ rere sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò tó ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.”
14 I rzekł jej Booz: Gdy będzie czas jedzenia, przychodź tu, a jedz chleb, omoczywszy sztuczkę twoję w occie. I usiadła przy żeńcach, i podał jej prażma, które jadła aż do sytości, i jeszcze jej zbyło.
Nígbà tí àkókò oúnjẹ sì tó, Boasi sọ fún Rutu pé, “Wá gba ìwọ̀n àkàrà yìí kí o sì fi run wáìnì kíkan.” Òun sì jókòó pẹ̀lú àwọn olùkórè, Boasi sì fún un ní ọkà yíyan. Òun sì jẹ́, ó yó, ó sì tún ṣẹ́kù.
15 Potem wstała, aby zbierała; a Booz rozkazał sługom swoim mówiąc: Niech i między snopami zbiera, a nie brońcie jej tego.
Nígbà tí ó sì dìde láti máa ṣá ọkà, Boasi pàṣẹ fún àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Bí ó tilẹ̀ ń ṣà láàrín oko ọkà pàápàá, ẹ má ṣe dí i lọ́wọ́.
16 Owszem umyślnie upuszczajcie jej z snopów, a zostawiajcie, aby zbierała, a nie fukajcie na nią.
Bí kò ṣe pé kí ẹ mú lára àwọn ìtí sílẹ̀ fún láti ṣá, kí ẹ má sì ṣe ba a wí.”
17 A tak zbierała na onem polu aż do wieczora; i wymłóciła to, co zebrała, i miała jakoby z efę jęczmienia.
Rutu sì ń ṣá ọkà títí ó fi di ìrọ̀lẹ́, nígbà tí ó sì pa ọkà barle tí ó rí ṣà, tí ó sì fẹ́ ẹ tán, èyí tí ó rí sì tó ìwọ̀n garawa kan (lita méjìlélógún).
18 A wziąwszy to, szła do miasta, i oglądała świekra jej to, co nazbierała; a wyjąwszy dała jej i to, co jej zostało, gdy się najadła.
Ó sì gbé e, ó sì lọ sí ìlú, ìyá ọkọ rẹ sì rí ọkà tí ó rí ṣà bi o tí pọ̀ tó, Rutu sì mú oúnjẹ tí ó jẹ kù lẹ́yìn tí ó ti yó tan fún ìyá ọkọ rẹ̀.
19 I rzekła do niej świekra jej: Kędyżeś dziś zbierała, a gdzieś robiła? niechajże ten, który na cię miał baczenie, błogosławionym będzie. I oznajmiła świekrze swej, u kogo robiła, mówiąc: Imię męża, u któregom dziś robiła, Booz.
Ìyá ọkọ rẹ̀ sì bi í léèrè wí pé, “Níbo ni ìwọ ti ṣá ọkà lónìí? Àti wí pé oko ta ni ìwọ gbé ṣiṣẹ́? Alábùkún fún ni ọkùnrin náà tí ó bojú wò ọ.” Rutu sì sọ ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ti ṣiṣẹ́ fún ìyá ọkọ rẹ̀ pé, “Ní oko ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi ni mo ti ṣiṣẹ́ lónìí.”
20 Potem rzekła Noemi do synowy swojej: Niech będzie błogosławionym od Pana, który nie zawściągnął miłosierdzia swego od żywych i od umarłych. Nadto jeszcze rzekła Noemi: Ten mąż jest powinowatym naszym, i z pokrewnych naszych.
Naomi sì wí fún un pé, “Kí Olúwa, kí ó bùkún fún ọkùnrin náà. Ọlọ́run kò dáwọ́ oore àti àánú ṣíṣe sí àwọn alààyè àti òkú dúró.” Naomi sì sọ síwájú sí i wí pé, “Ìbátan tí ó súnmọ́ wa pẹ́kípẹ́kí ni ọkùnrin náà ń ṣe, ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ra ohun ìní ìdílé padà.”
21 Rzekła jej też Rut Moabitka: Nadto mi jeszcze mówił on mąż: Trzymaj się czeladzi mojej, póki nie pożną wszystkiego zboża mego.
Rutu, ará Moabu sì wí pé, “Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ó sọ fún mi pé, ‘Kí ń máa ṣá ọkà pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ òun, títí wọn yóò fi parí ìkórè.’”
22 Tedy rzekła Noemi do Ruty, synowy swej: Dobrze, córko moja, iż będziesz chodziła z dziewkami jego, żebyć kto przeciwnym nie był na polu innem.
Naomi sì sọ fún Rutu, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Ìbá dára bí ó bá le bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ ṣiṣẹ́. Nítorí pé wọ́n le è dà ọ́ láàmú bí o bá lọ sí oko ẹlòmíràn.”
23 Przetoż się trzymała służebnic Boozowych, i zbierała kłosy, póki się nie skończyło żniwo jęczmienne, i żniwo pszeniczne. Potem mieszkała u świekry swojej.
Rutu sì bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin Boasi ṣiṣẹ́ títí tí wọ́n fi parí ìkórè ọkà barle àti ti jéró. Ó sì ń gbé pẹ̀lú ìyá ọkọ rẹ̀.

< Rut 2 >