< Objawienie 9 >
1 I zatrąbił piąty Anioł i widziałem, że gwiazda spadła z nieba na ziemię, a dano jej klucz studni przepaści. (Abyssos )
Angẹli karùn-ún sì fún ìpè tirẹ̀, mo sì rí, ìràwọ̀ kan bọ́ sílẹ̀ láti ọ̀run wá, a sì fi kọ́kọ́rọ́ ihò ọ̀gbun fún un. (Abyssos )
2 I otworzyła studnię przepaści; i wystąpił dym z onej studni, jakoby dym pieca wielkiego, i zaćmiło się słońce i powietrze od dymu onej studni. (Abyssos )
Ó sì ṣí ihò ọ̀gbun náà, èéfín sì rú jáde láti inú ihò náà wá, bí èéfín ìléru ńlá, oòrùn àti ojú sánmọ̀ sì ṣókùnkùn nítorí èéfín ihò náà. (Abyssos )
3 A z onego dymu wyszły szarańcze na ziemię i dano im moc, jako mają moc niedźwiadki ziemskie;
Àwọn eṣú sì jáde ti inú èéfín náà wá sórí ilẹ̀, a sì fi agbára fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbára àkéekèe ilẹ̀.
4 A rzeczono im, żeby nie szkodziły trawie ziemi, ani żadnej rzeczy zielonej, ani żadnemu drzewu, ale tylko samym ludziom, którzy nie mają pieczęci Bożej na czołach swoich.
A sì fún wọn pé ki wọn má ṣe pa koríko ilẹ̀ lára tàbí ohun tútù kan, tàbí igikígi kan; bí kò ṣe àwọn ènìyàn tí kò ni èdìdì Ọlọ́run ní iwájú wọn.
5 A dano im, nie żeby ich zabijały, ale aby ich dręczyły przez pięć miesięcy, a udręczenie ich, aby było jako udręczenie od niedźwiadka, gdy człowieka ukąsi.
A sì pàṣẹ fún wọn pé, kí wọn má ṣe pa wọ́n, ṣùgbọ́n kí a dá wọn ni oró ni oṣù márùn-ún, oró wọn sì dàbí oró àkéekèe, nígbà tí o bá ta ènìyàn.
6 Przetoż w one dni szukać będą ludzie śmierci, ale jej nie znajdą; i będą chcieli umrzeć, ale śmierć od nich uciecze.
Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn yóò sì máa wá ikú, wọn kì yóò sì rí i; wọn yóò sì fẹ́ láti kú, ikú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
7 A kształt onych szarańczy podobny był koniom zgotowanym do bitwy, a na głowach ich były jakoby korony podobne złotu, a twarze ich jako twarze ludzkie;
Ìrísí àwọn eṣú náà sì dàbí àwọn ẹṣin tí a múra sílẹ̀ fún ogun; àti ní orí wọn ni ohun tí o dàbí àwọn adé wúrà wà, ojú wọn sì dàbí ojú ènìyàn;
8 I miały włosy jako włosy niewieście, a zęby ich były jako lwie;
wọ́n sì ní irun bí obìnrin, eyín wọn sì dàbí ti kìnnìún.
9 A miały pancerze jako pancerze żelazne, a szum skrzydeł ich, jako grzmot wozów, gdy wiele koni bieży do bitwy.
Wọ́n sì ní ìgbàyà tí ó dàbí ìgbàyà irin; ìró ìyẹ́ wọn sì dàbí ìró kẹ̀kẹ́-ẹṣin púpọ̀ tí ń súré lọ sí ogun.
10 A ogony miały podobne niedźwiadkom, a żądła były w ogonach ich, a moc ich była szkodzić ludziom przez pięć miesięcy;
Wọ́n sì ni ìrù àti oró bí tí àkéekèe, àti ní ìrù wọn ni agbára wọn wà láti pa ènìyàn lára fún oṣù márùn-ún.
11 A miały nad sobą króla, anioła przepaści, któremu imię po żydowsku Abaddon, a po grecku ma imię Apolijon. (Abyssos )
Wọ́n ní angẹli ọ̀gbun náà bí ọba lórí wọn, orúkọ rẹ̀ ní èdè Heberu ní Abaddoni, àti ni èdè Giriki orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Apollioni (èyí ni Apanirun). (Abyssos )
12 Biada jedno przeszło, a oto jeszcze idą dwa biada potem.
Ègbé kan tí kọjá, kíyèsi i, ègbé méjì ń bọ̀ síbẹ̀ lẹ́yìn èyí.
13 Tedy zatrąbił Anioł szósty, a słyszałem głos jeden ze czterech rogów ołtarza złotego, który jest przed oblicznością Bożą,
Angẹli kẹfà si fọn ìpè rẹ̀, mo sì gbọ́ ohùn kan láti ibi ìwo mẹ́rin pẹpẹ wúrà wá, tí ń bẹ níwájú Ọlọ́run.
14 Mówiący szóstemu Aniołowi, który miał trąbę: Rozwiąż onych czterech Aniołów związanych u wielkiej rzeki Eufrates.
Òun wí fún angẹli kẹfà náà tí o ni ìpè náà pé, “Tú àwọn angẹli mẹ́rin náà sílẹ̀ tí a dè lẹ́bàá odò ńlá Eufurate!”
15 I rozwiązani są oni czterej Aniołowie, zgotowani na godzinę i na dzień, i na miesiąc, i na rok, aby pobili trzecią część ludzi.
A sì tú àwọn angẹli mẹ́rin náà sílẹ̀, tí a ti pèsè tẹ́lẹ̀ fún wákàtí náà, àti ọjọ́ náà, àti oṣù náà, àti ọdún náà, láti pa ìdámẹ́ta ènìyàn.
16 A liczba wojska jezdnego była dwieściekroć tysiąc tysięcy; bom słyszał liczbę ich.
Iye ogún àwọn ẹlẹ́ṣin sì jẹ́ àádọ́ta ọ̀kẹ́ lọ́nà igba, mo sì gbọ́ iye wọn.
17 Widziałem także konie w widzeniu, a ci, którzy siedzieli na nich, mieli pancerze ogniste hijacyntowe i siarczane; a głowy onych koni były jako głowy lwie, a z gęby ich wychodził ogień i dym i siarka.
Báyìí ni mo sì rí àwọn ẹṣin náà ní ojúran, àti àwọn tí o gùn wọ́n, wọ́n ni ìgbàyà aláwọ̀ iná, àti ti jakinti, àti ti sulfuru, orí àwọn ẹṣin náà sì dàbí orí àwọn kìnnìún; àti láti ẹnu wọn ni iná, àti èéfín, àti sulfuru tí ń jáde.
18 A od tego trojga pobita jest trzecia część ludzi od ognia i od dymu, i od siarki, które wychodziły z gąb ich.
Nípa ìyọnu mẹ́ta wọ̀nyí ni a tí pa ìdámẹ́ta ènìyàn, nípa iná, àti nípa èéfín, àti nípa sulfuru tí o ń tí ẹnu wọn jáde.
19 Albowiem moc ich jest w gębach ich i w ogonach ich; bo ogony ich wężom są podobne, mając głowy, któremi szkodzą.
Nítorí pé agbára àwọn ẹṣin náà ń bẹ ní ẹnu wọn àti ní ìrù wọn: nítorí pé ìrù wọn dàbí ejò, wọn sì ní orí, àwọn wọ̀nyí ni wọn sì fi ń pa ni lára.
20 A inni ludzie, którzy nie są pobici temi plagami, ani pokutowali od uczynków rąk swoich, aby się nie kłaniali dyjabłom i bałwanom złotym i srebrnym, i miedzianym, i kamiennym i drewnianym, którzy ani widzieć nie mogą, ani słyszeć, ani chodzić;
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ìyókù tí a kò sì ti ipa ìyọnu wọ̀nyí pa, kò sì ronúpìwàdà iṣẹ́ ọwọ́ wọn, kí wọn má ṣe sin àwọn ẹ̀mí èṣù àti ère wúrà, àti ti fàdákà, àti ti idẹ, àti òkúta, àti ti igi mọ́: àwọn tí kò lè ríran, tàbí kí wọn gbọ́rọ̀, tàbí kí wọn rìn.
21 Ani pokutowali z mężobójstw swoich, ani z czarów swoich, ani z wszeteczeństw swoich, ani z złodziejstw swoich.
Bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ronúpìwàdà ìwà ìpànìyàn wọn, tàbí oṣó wọn tàbí àgbèrè wọn, tàbí olè wọn.