< Objawienie 4 >

1 Potemem widział, a oto drzwi były otworzone w niebie, a głos pierwszy, którym słyszał, jako trąby mówiącej ze mną, i rzekł: Wstąp sam, a pokażę ci, co się ma dziać napotem.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí èmi wò, sì kíyèsi i, ìlẹ̀kùn kan ṣí sílẹ̀ ní ọ̀run, ohùn kìn-ín-ní tí mo gbọ́ bí ohùn ìpè tí ń bá mi sọ̀rọ̀, tí ó wí pé, “Gòkè wá níhìn-ín, èmi ó sì fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn èyí hàn ọ́.”
2 A zarazem byłem w zachwyceniu ducha, a oto stolica postawiona była na niebie, a na stolicy siedziała osoba.
Lójúkan náà, mo sì wà nínú Ẹ̀mí, sì kíyèsi i, a tẹ́ ìtẹ́ kan ní ọ̀run, ẹnìkan sì jókòó lórí ìtẹ́ náà.
3 A ten, który siedział, podobny był na wejrzeniu kamieniowi jaspisowi i sardynowi; a około onej stolicy była tęcza, na wejrzeniu podobna szmaragdowi.
Ẹni tí ó sì jókòó náà dàbí òkúta jasperi àti kaneliani lójú. Ni àyíká ìtẹ́ náà ni òṣùmàrè kan wà tí ó dàbí òkúta emeradi lójú.
4 A około onej stolicy było stolic dwadzieścia i cztery; a na onych stolicach widziałem dwudziestu i czterech starców siedzących, obleczonych w szaty białe, a na głowach swoich mieli korony złote.
Yí ìtẹ́ náà ká sì ni ìtẹ́ mẹ́rìnlélógún mìíràn; àti lórí àwọn ìtẹ́ náà mo rí àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún jókòó, tí a wọ̀ ni aṣọ àlà; adé wúrà sì wà ni orí wọn.
5 A z onej stolicy wychodziły błyskawice i gromy, i głosy, i siedm lamp ognistych gorejących przed stolicą, które są siedm duchów Bożych.
Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni ìró mọ̀nàmọ́ná àti ohùn àti àrá ti jáde wá: níwájú ìtẹ́ náà ni fìtílà iná méje sì ń tàn, èyí tí ń ṣe Ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run.
6 A przed oną stolicą było morze szklane, podobne kryształowi, a w pośrodku stolicy i około stolicy czworo zwierząt pełnych oczu z przodku i z tyłu.
Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni òkun bi dígí wà tí o dàbí kristali. Àti yí ìtẹ́ náà ká ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀dá alààyè mẹ́rin tí ó kún fún ojú níwájú àti lẹ́yìn wọn.
7 A pierwsze zwierzę podobne było lwowi, a wtóre zwierzę podobne cielcowi, a trzecie zwierzę miało twarz jako człowiek, a czwarte zwierzę podobne było orłowi latającemu.
Ẹ̀dá kìn-ín-ní sì dàbí kìnnìún, ẹ̀dá kejì si dàbí ọmọ màlúù, ẹ̀dá kẹta sì ni ojú bi ti ènìyàn, ẹ̀dá kẹrin sì dàbí idì tí ń fò.
8 A oto każde z osobna z onych czterech zwierząt miało sześć skrzydeł wokoło, a wewnątrz były pełne oczów, a odpoczynku nie mają we dnie i w nocy, mówiąc: Święty, święty, święty Pan, Bóg wszechmogący, który był i jest, i przyjść ma.
Àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà, tí olúkúlùkù wọn ni ìyẹ́ mẹ́fà, kún fún ojú yíká ara àti nínú; wọn kò sì sinmi lọ́sàn àti lóru, láti wí pé:
9 A gdy one zwierzęta dawały chwałę i cześć, i dziękowanie siedzącemu na stolicy, żyjącemu na wieki wieków; (aiōn g165)
Nígbà tí àwọn ẹ̀dá alààyè náà bá sì fi ògo àti ọlá, àti ọpẹ́ fún ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, tí o ń bẹ láààyè láé àti láéláé. (aiōn g165)
10 Upadli dwadzieścia cztery starcy przed obliczem siedzącego na stolicy i kłaniali się żyjącemu na wieki wieków, i rzucali korony swoje przed stolicą, mówiąc: (aiōn g165)
Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà yóò sì wólẹ̀ níwájú ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, wọn yóò sì tẹríba fún ẹni tí ń bẹ láààyè láé àti láéláé, wọn yóò sì fi adé wọn lélẹ̀ níwájú ìtẹ́ náà, wí pé: (aiōn g165)
11 Godzieneś jest, Panie! wziąć chwałę i cześć, i moc; boś ty stworzył wszystkie rzeczy i za wolą twoją trwają, i stworzone są.
“Olúwa àti Ọlọ́run, ìwọ ni o yẹ, láti gba ògo àti ọlá àti agbára, nítorí pé ìwọ ni o dá ohun gbogbo, àti nítorí ìfẹ́ inú rẹ̀ ni wọn fi wà tí a sì dá wọn.”

< Objawienie 4 >