< Objawienie 17 >
1 I przyszedł jeden z siedmiu Aniołów, którzy mieli siedm czasz, i rzekł do mnie, mówiąc mi: Chodź, okażę ci osądzenie onej wielkiej wszetecznicy, która siedzi nad wodami wielkiemi,
Ọ̀kan nínú àwọn angẹli méje náà tí ó ní ìgò méje wọ̀n-ọn-nì sì wá, ó sì ba mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wá níhìn-ín; èmi ó sì fi ìdájọ́ àgbèrè ńlá ní tí ó jókòó lórí omi púpọ̀ han ọ,
2 Z którą wszeteczeństwo płodzili królowie ziemi i upili się winem wszeteczeństwa jej obywatele ziemi.
ẹni tí àwọn ọba ayé bá ṣe àgbèrè, tí a sì fi ọtí wáìnì àgbèrè rẹ̀ pa àwọn tí ń gbé inú ayé.”
3 I odniósł mię na puszczę w duchu. I widziałem niewiastę siedzącą na szarłatnoczerwonej bestyi, pełnej imion bluźnierstwa, która miała siedm głów i dziesięć rogów.
Ó sì gbé mi nínú ẹ̀mí lọ sí aginjù: mo sì rí obìnrin kan ó jókòó lórí ẹranko aláwọ̀ òdòdó kan tí ó kún fún orúkọ ọ̀rọ̀-òdì, ó ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá.
4 A ona niewiasta przyobleczona była w purpurę i w szarłat, i uzłocona złotem i drogim kamieniem, i perłami, mając kubek złoty w ręce swej, pełen obrzydliwości i nieczystości wszeteczeństwa swego.
A sì fi aṣọ elése àlùkò àti aṣọ òdòdó wọ obìnrin náà, a sì fi wúrà àti òkúta iyebíye àti perli ṣe é ní ọ̀ṣọ́, ó ní ago wúrà kan ní ọwọ́ rẹ̀, tí ó kún fún ìríra àti fún ẹ̀gbin àgbèrè rẹ̀;
5 A na czole jej było imię napisane: Tajemnica, Babilon wielki, matka wszeteczeństw i obrzydliwości ziemi.
àti níwájú rẹ̀ ni orúkọ kan tí a kọ: Ohun ìjìnlẹ̀ Babeli ńlá ìyá àwọn panṣágà àti àwọn ohun ìríra ayé.
6 I widziałem niewiastę onę pijaną krwią świętych i krwią męczenników Jezusowych; a widząc ją, dziwowałem się wielkim podziwieniem.
Mo sì rí obìnrin náà mu ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́, àti ẹ̀jẹ̀ àwọn ajẹ́rìí ikú Jesu ní àmuyó. Nígbà tí mo sì rí i, ẹnu yà mi gidigidi.
7 I rzekł mi Anioł: Czemuż się dziwujesz? Ja tobie powiem tajemnicę tej niewiasty i bestyi, która ją nosi, która ma siedm głów i dziesięć rogów.
Angẹli sì wí fún mi pé, “Nítorí kí ni ẹnu ṣe yà ọ́? Èmi ó sọ ti ìjìnlẹ̀ obìnrin náà fún ọ, àti ti ẹranko tí ó gùn, ti ó ní orí méje àti ìwo mẹ́wàá.
8 Bestyja, którąś widział, była, a nie jest, a ma wystąpić z przepaści, a iść na zginienie; i zadziwią się mieszkający na ziemi, (których imiona nie są napisane w księgach żywota od założenia świata), widząc bestyję, która była, a nie jest, a przecię jest. (Abyssos )
Ẹranko tí ìwọ ri nì, o ti wà, kò sì ṣí mọ́, yóò sì ti inú ọ̀gbun gòkè wá, yóò sì lọ sínú ìparun rẹ. Àwọn olùgbé ayé ti a kọ orúkọ wọn sínú ìwé iye láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé, nígbà tí wọn ń wò ẹranko tí o ti wà, tí kò sì ṣí mọ́, tí ó sì ń bọ̀ wá, ẹnu si ya wọn. (Abyssos )
9 Tuć jest rozum mający mądrość: Te siedm głów są siedm gór, na których ta niewiasta siedzi.
“Níhìn-ín ni ìtumọ̀ tí o ní ọgbọ́n wà. Orí méje ni òkè ńlá méje ni, lórí èyí tí obìnrin náà jókòó.
10 A królów jest siedm, pięć ich upadło, a jeden jest, inszy jeszcze nie przyszedł, a gdy przyjdzie, na mały czas musi trwać.
Ọba méje sì ní wọn: àwọn márùn-ún ṣubú, ọ̀kan ń bẹ, ọ̀kan ìyókù kò sì tí ì dé; nígbà tí ó bá sì dé, yóò dúró fún ìgbà kúkúrú.
11 A bestyja, która była a nie jest, toć jest ten ósmy, a jest z onych siedmiu, a idzie na zginienie.
Ẹranko tí ó sì ti wà, tí kò sì ṣí, òun náà sì ni ẹ̀kẹjọ, ó sì ti inú àwọn méje náà wá, ó sì lọ sí ìparun.
12 A dziesięć rogów, któreś widział, jest dziesięć królów, którzy królestwa jeszcze nie wzięli; ale wezmą moc jako królowie, na jednę godzinę z bestyją.
“Ìwo mẹ́wàá tí ìwọ sì rí ni ọba mẹ́wàá ni wọn, tí wọn kò ì ti gba ìjọba; ṣùgbọ́n wọn gba àṣẹ bí ọba pẹ̀lú ẹranko náà fún wákàtí kan.
13 Ci jedną radę mają i moc, i zwierzchność swoję bestyi podadzą.
Àwọn wọ̀nyí ní inú kan, wọ́n yóò sì fi agbára àti ọlá wọn fún ẹranko náà.
14 Ci z Barankiem walczyć będą, i Baranek ich zwycięży, bo jest Panem panów i królem królów, i którzy są z nim powołani i wybrani, i wierni.
Àwọn wọ̀nyí ni yóò si máa bá Ọ̀dọ́-Àgùntàn jagun, Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà yóò sì ṣẹ́gun wọn: nítorí òun ni Olúwa àwọn Olúwa, àti ọba àwọn ọba: àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú rẹ̀, tí a pè, tí a yàn, tí wọ́n sì jẹ́ olóòtítọ́ yóò sì ṣẹ́gun pẹ̀lú.”
15 I rzekł mi: Wody, któreś widział, gdzie wszetecznica siedzi, są ludzie i zastępy, i narody, i języki.
Ó sì wí fún mi pé, “Àwọn omi tí ìwọ ti rí ni, níbi tí àgbèrè náà jókòó, àwọn ènìyàn àti ẹ̀yà àti orílẹ̀ àti onírúurú èdè ni wọ́n.
16 A dziesięć rogów, któreś widział na bestyi, cić w nienawiści mieć będą wszetecznicę i uczynią ją spustoszoną i nagą, i ciało jej będą jeść, a samą ogniem spalą.
Àti ìwo mẹ́wàá tí ìwọ rí, àti ẹranko náà, àwọn wọ̀nyí ni yóò kórìíra àgbèrè náà, wọn ó sì sọ ọ́ di ahoro àti ẹni ìhòhò, wọn ó sì jẹ ẹran-ara rẹ̀, wọn ó sì fi iná sun ún pátápátá.
17 Albowiem Bóg podał do serc ich, aby czynili wolę jego, a czynili jednomyślnie, i dali królestwo swoje bestyi, ażby się wypełniły słowa Boże.
Nítorí Ọlọ́run ti fi sínú ọkàn wọn láti mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ, láti ní inú kan, àti láti fi ìjọba wọn fún ẹranko náà, títí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yóò fi ṣẹ.
18 A niewiasta, którąś widział, jest miasto ono wielkie, które ma królestwo nad królami ziemi.
Obìnrin tí ìwọ rí ní ìlú ńlá ni, tí ń jẹ ọba lórí àwọn ọba ilẹ̀ ayé.”