< Psalmów 95 >
1 Pójdźcież, śpiewajmy Panu; wykrzykujmy skale zbawienia naszego.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa, ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.
2 Uprzedźmy oblicze jego z chwałą; psalmy mu śpiewajmy.
Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò orin àti ìyìn.
3 Albowiem Pan jest Bóg wielki, i król wielki nade wszystkich bogów.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni, ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
4 W jegoż rękach są głębokości ziemi, i wierzchy gór jego są.
Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà, ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
5 Jegoż jest morze, bo je on uczynił; i ziemia, którą ręce jego ukształtowały.
Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.
6 Pójdźcie, kłaniajmy się, a upadajmy przed nim; klękajmy przed Panem, stworzycielem naszym.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín, ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú Olúwa ẹni tí ó dá wa,
7 Onci jest zaiste Bóg nasz, a myśmy lud pastwiska jego, i owce rąk jego. Dziś, jeźli głos jego usłyszycie,
nítorí òun ni Ọlọ́run wa, àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀, àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀. Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
8 Nie zatwardzajcież serca swego, jako w Meryba, a jako czasu kuszenia na puszczy.
“Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba, àti bí ẹ ti ṣe ní ọjọ́ náà ní Massa ní aginjù,
9 Kiedy mię kusili ojcowie wasi, doświadczylić mię, i widzieli sprawy moje.
nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò tí wọn wádìí mi, tí wọn sì rí iṣẹ́ mi.
10 Przez czterdzieści lat miałem spór z tym narodem, i rzekłem: Lud ten błądzi sercem, a nie poznali dróg moich;
Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà; mo wí pé, ‘Wọ́n jẹ́ ènìyàn tí ọkàn wọn ṣáko lọ wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
11 Którymem przysiągł w popędliwości mojej, że nie wnijdą do odpocznienia mego.
Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kì yóò wọ ibi ìsinmi mi.’”