< Psalmów 9 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi, na Halmutlabben pieśń Dawidowa. Będę wysławiał Pana ze wszystkiego serca mego; opowiadać będę wszysteki cuda twoje.
Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
2 Rozweselę się, i rozraduję się w tobie; będę śpiewał imieniowi twemu, o Najwyższy!
Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
3 Że się obrócili nieprzyjaciele moi na wstecz: upadli i poginęli od obliczności twojej.
Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
4 Boś ty odprawił sąd mój, i sprawę moję; zasiadłeś na stolicy, Sędzia sprawiedliwy.
Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
5 Rozgromiłeś pogan, zatraciłeś złośnika, imię ich wygładziłeś na wieki wieczne.
Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
6 O nieprzyjacielu! azaż wykonane są spustoszenia twoie na wieczność? Poburzyłżeś miasta? i owszem ich samych pamiątka zginęła z niemi.
Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
7 Ale Pan na wieki trwa; zgotował stolicę swoję na sąd.
Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
8 On będzie sądził okrąg ziemi w sprawiedliwości, i osądzi narody w prawości.
Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
9 I będzie Pan ucieczką ubogiemu, ucieczką czasu ucisku.
Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
10 I będą ufać w tobie, którzy znają imię twoje; albowiem nie opuszczasz tych, Panie! którzy cię szukają.
Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
11 Śpiewajcież Panu, który mieszka na Syonie; opowiadajcie między narodami sprawy jego.
Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
12 Boć on szuka krwi, i mają w pamięci, a nie zapomina wołania utrapionych.
Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
13 Zmiłuj się nademną, Panie! obacz utrapienie moje od tych, którzy mię mają w nienawiści, ty, co mię wyrywasz z bram śmierci.
Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
14 Abym opowiadał wszystkie chwały twoje w bramach córki Syońskiej, weseląc się w zbawieniu twojem.
kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
15 Zanurzeni są poganie w dole, który uczynili; w sieci, którą skrycie zastawili, uwięzła noga ich.
Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
16 Oznajmił się Pan, gdy uczynił sąd; w sprawie rąk swoich się złośnik usidlił. Rzecz godna rozmyślania! (Sela)
A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
17 Niepobożni się obrócą do piekła, wszystkie narody, które zapominają Boga. (Sheol h7585)
Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol h7585)
18 Bo nie będzie na wieki zapamiętany ubogi; oczekiwanie nędznych nie zginie na wieki.
Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
19 Powstańże, Panie! niech się nie zmacnia śmiertelny człowiek; a niech narody osądzone będą przed tobą.
Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
20 Panie! puść na nie strach, aby poznały narody, iż są ludźmi śmiertelnymi. (Sela)
Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)

< Psalmów 9 >