< Psalmów 89 >
1 Nauczający (złożony) od Etana Ezrahytczyka. O miłosierdziach Pańskich na wieki śpiewać będę; od narodu do narodu opowiadać będę usty swemi prawdę twoję.
Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
2 Rzekłem bowiem: Miłosierdzie na wieki budowane będzie; na niebiosach utwierdziłeś prawdę twoję, o którejś rzekł:
Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
3 Postanowiłem przymierze z wybranym moim: przysiągłem Dawidowi, słudze swemu,
Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
4 Że aż na wieki utwierdzę nasienie twoje, a zbuduję od narodu do narodu stolicę twoję. (Sela)
‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
5 Przetoż, Panie! wysławiają niebiosa cud twój, i prawdę twoję w zgromadzeniu świętych.
Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
6 Albowiem któż na niebie przyrównany może być Panu? kto podobien jest Panu między synami mocarzów?
Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
7 I w zgromadzeniu świętych bardzo jest Bóg straszliwy, a straszny nade wszystkich, którzy są około niego.
Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
8 Panie, Boże zastępów! któż jest jakoś ty, Pan mocny? bo prawda twoja jest około ciebie.
Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
9 Ty panujesz nad nadętością morską; gdy się podnoszą nawałności jego, ty je skracasz.
Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
10 Tyś potawrł Egipt jako zranionego; mocą ramienia twego rozproszyłeś nieprzyjaciół twoich.
Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
11 Twojeć są niebiosa, twoja też i ziemia; okrąg świata i pełność jego tyś ugruntował.
Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
12 Tyś stworzył północy i południe; Tabor i Hermon śpiewają o imieniu twojem.
Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
13 Ramię twoje mocne jest; można jest ręka twoja, a wywyższona jest prawica twoja.
Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
14 Sprawiedliwość i sąd są gruntem stolicy twojej; miłosierdzie i prawda uprzedzają oblicze twoje.
Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
15 Błogosławiony lud, który zna dźwięk twój; Panie! w światłości oblicza twego chodzić będą.
Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
16 W imieniu twojem weselić się będą każdego dnia, a w sprwiedliwości twojej wywyższać się będą.
Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
17 Boś ty jest chwałą mocy ich, a za wolą twoją wywyższy się róg nasz.
Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
18 Bo od Pana jest tarcza nasza, a od świętego Izraelskiego król nasz.
Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
19 W on czas mówiąc w widzeniu do świętego twego rzekłeś: Położyłem ratunek w ręku mocarza, wywyższyłem wybranego z ludu.
Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
20 Znalazłem Dawida, sługę mego; olejkiem świętym moim pomazałem go.
Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
21 Przetoż ręka moja będzie stała przy nim, a ramię moje posili go.
Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
22 Nie uciśnie go nieprzyjaciel, a syn nieprawości nie utrapi go.
Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
23 Bo potrę przed twarzą jego przeciwników jego, a tych, którzy go mają w nienawiści, porażę.
Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
24 Nadto prawda moja i miłosierdzie moje z nim będzie, a w imieniu mojem wywyższony będzie róg jego.
Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
25 I położę na morzu rękę jego i na rzekach prawicę jego.
Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
26 On wołając rzecze: Tyś ojciec mój, Bóg mój, i skała zbawienia mego,
Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
27 Ja go też za pierworodnego wystawię, i za wyższego nad królami ziemi.
Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
28 Na wieki mu zachowam miłosierdzie moje, a przymierze moje stałe będzie przy nim.
Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
29 I uczynię, że na wieki będzie trwało nasienie jego, a stolica jego jako dni niebios.
Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
30 Ale jeźliby synowie jego opuścili zakon mój, a w sądach moich nie chodzili;
“Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
31 Jeźliby ustawy moje splugawili, a przykazań moich nie przestrzegali:
Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
32 Tedy nawiedzę rózgą przestępstwo ich, a karaniem nieprawość ich.
nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
33 Ale miłosierdzia swego nie odejmę od niego, ani skłamię przeciw prawdzie mojej.
ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
34 Nie splugawię przymierza mego, a tego, co wyszło z ust moich, nie odmienię.
Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
35 Razem przysiągł przez świętobliwość moję, że nie skłamię Dawidowi,
Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
36 A że nasienie jego zostanie na wieki, a stolica jego jako słońce przedemną;
Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
37 Jako miesiąc będzie utwierdzone na wieki, i jako świadkowie na niebie godnowierni. (Sela)
A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
38 Aleś go ty odrzucił i wzgardził; rozgniewałeś się na pomazańca twego.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
39 Zrzuciłeś przymierze z sługą twoim; strąciłeś na ziemię koronę jego.
Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
40 Roztargałeś wszystkie płoty jego, i basztyś jego rozwalił.
Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
41 Szarpają go wszyscy, którzy drogą mimo idą; pośmiewiskiem jest i sąsiadom swoim.
Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
42 Wywyższyłeś prawicę przeciwników jego; uweseliłeś wszysstkich nieprzyjaciół jego.
Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
43 I ostrze miecza jego stępiłeś, a nie ratowałeś go w bitwie.
Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
44 Zniosłeś ochędóstwo jego, a stolicę jego uderzyłeś o ziemię.
Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
45 Ukróciłeś dni młodości jego, a przyodziałeś go hańbą. (Sela)
Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
46 Dokądże, Panie! na wiekiż się kryć będziesz? także będzie jako ogień pałać zapalczywość twoja?
Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
47 Wspomnijże na mię, jako krótki jest wiek mój; azaś próżno stworzył wszystkich synów ludzkich?
Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
48 Któż z ludzi tak żyć może, aby nie oglądał śmierci? któż wyrwie duszę swą z mocy grobu? (Sela) (Sheol )
Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol )
49 Gdzież są litości twoje dawne, o Panie! któreś przysiągł Dawidowi w prawdzie swej?
Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
50 Wspomnij, Panie! na zelżywość sług twoich, a jakom ponosił wzgardę w zanadrzu swem od wszystkich narodów możnych.
Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
51 Panie! jako urągali nieprzyjaciele twoi, jako urągali ścieżkom pomazańca twego.
ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
52 Niech będzie błogosławiony Pan aż na wieki. Amen, Amen.
Olùbùkún ní Olúwa títí láé.