< Psalmów 86 >

1 Modlitwa Dawidowa. Nakłoń, Panie! ucha twego, a wysłuchaj mię; bomci nędzny i ubogi.
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
2 Strzeżże duszy mojej, bom jest ten, którego ty miłujesz; zachowaj sługę twego, Boże mój! który ma nadzieję w tobie.
Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
3 Zmiłuj się nademną, Panie, albowiem do ciebie na każdy dzień wołam.
Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
4 Rozwesel duszę sługi twego; bo do ciebie, o Panie! duszę swą podnoszę.
Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
5 Boś ty, Panie! dobry i litościwy, i wielce miłosierny wszystkim, którzy cię wzywają.
Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
6 Wysłuchajże, Panie! modlitwę moję, a posłuchaj pilnie głosu prośby mojej.
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
7 Wzywam cię w dzień ucisku mego; bo mię ty wysłuchasz.
Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
8 Nie masz żadnego podobnego tobie między bogami, o Panie! i nie masz takowych spraw, jako są twoje.
Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
9 Wszystkie narody, któreś ty stworzył, przychodząc kłaniać się będą przed obliczem twojem, Panie! i wielbić będą imię twoje.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
10 Boś ty jest wielki, a czynisz cuda; tyś sam jest Bogiem.
Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
11 Naucz mię, Panie, drogi twojej, abym chodził w prawdzie twojej, a ustanów serce moje w bojaźni imienia twego;
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
12 A będę cię chwalił, Panie, Boże mój! ze wszystkiego serca mego, i będę wielbił imię twoje na wieki,
Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
13 Ponieważ miłosierdzie twoje wielkie jest nademną, a tyś wyrwał duszę moję z dołu głębokiego. (Sheol h7585)
Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol h7585)
14 O Boże! powstali hardzi przeciwko mnie, a rota okrutników szukała duszy mojej, ci, którzy cię przed oczyma nie mają.
Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
15 Ale ty, Panie, Boże miłosierny i litościwy, i nierychły ku gniewu, i wielce miłosierny, i prawdziwy!
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
16 Wejrzyj na mię, a zmiłuj się nademną, dajże moc twoję słudze twemu, a zachowaj syna służebnicy twojej.
Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
17 Okaż mi znak dobroci twojej, aby to widząc ci, którzy mię mają w nienawiści, zawstydzeni byli, żeś mię ty, Panie! poratował, i pocieszyłeś mię.
Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.

< Psalmów 86 >