< Psalmów 84 >
1 Przedniejszemu śpiewakowi na Gittyt, synom Korego psalm. O jako są miłe przybytki twoje, Panie zastępów!
Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ibùgbé rẹ̀ ti lẹ́wà tó, Olúwa àwọn ọmọ-ogun!
2 Żąda i bardzo tęskni dusza moja do sieni Pańskich; serce moje i ciało moje pochutniwa sobie do Boga żywego.
Ọkàn mi ń ṣàfẹ́rí nítòótọ́ ó tilẹ̀ pòǹgbẹ fún àgbàlá Olúwa àyà mi àti ara mi ń kọrin ayọ̀ sí Ọlọ́run alààyè.
3 Oto i wróbel znalazł sobie domek, i jaskółka gniazdo swoje, gdzie pokłada ptaszęta swe, u ołtarzów twoich, Panie zastępów, królu mój i Boże mój!
Nítòótọ́ ológoṣẹ́ ri ilé, ẹyẹ alápáǹdẹ̀dẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ fún ara rẹ̀, níbi tí yóò máa pa ọmọ rẹ̀ mọ́ sí: ibùgbé ní tòsí pẹpẹ rẹ̀, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọba mí àti Ọlọ́run mi.
4 Błogosławieni, którzy mieszkają w domu twoim; będą cię na wieki chwalić. (Sela)
Ìbùkún ní fún àwọn tí ó ń gbé inú ilé rẹ; wọn ó máa yìn ọ́ títí láé.
5 Błogosławiony człowiek, który ma siłę swoję w tobie, i w których sercu są drogi twoje.
Ìbùkún ni fún àwọn tí agbára wọn wà nínú rẹ àwọn tí wọ́n gbé ọkàn lé bíbẹ ibi mímọ́ wò.
6 Którzy idąc przez dolinę morwów, za źródło go sobie pokładają, i deszcz pożegnania przychodzi na nich.
Àwọn tí ń la àfonífojì omijé lọ wọn sọ ọ́ di kànga àkọ́rọ̀ òjò sì fi ìbùkún bò ó.
7 I idą huf za hufem, a ukazują się przed Bogiem na Syonie.
Wọ́n ń lọ láti ipa dé ipá títí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan fi farahàn níwájú Ọlọ́run ní Sioni.
8 O Panie, Boże zastępów! wysłuchaj modlitwę moję; przyjmij w uszy twe, o Boże Jakóbowy. (Sela)
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa Ọlọ́run Alágbára; tẹ́tí sí mi, Ọlọ́run Jakọbu.
9 O Boże, tarczo nasza! obacz, a wejrzyj na oblicze pomazańca twego.
Wo asà wa, Ọlọ́run; fi ojú àánú wò àwọn ẹni àmì òróró rẹ.
10 Albowiem lepszy jest dzień w sieniach twoich, niż gdzie indziej tysiąc; obrałem sobie raczej w progu siedzieć w domu Boga swego, niżeli mieszkać w przybytkach niezbożników.
Dídára ní ọjọ́ kan ní ààfin rẹ ju ẹgbẹ̀rún ọjọ́ lọ; èmi o kúkú máa ṣe aṣọ́nà nínú ilé Ọlọ́run mi jù láti gbé ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú.
11 Albowiem Pan Bóg jest słońcem i tarczą: tuć łaski i chwały Pan udziela, i nie odmawia, co jest dobrego, tym, którzy chodzą w niewinności.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run jẹ́ òòrùn àti asà; Olúwa fún ni ní ojúrere àti ọlá; kò sí ohun rere kan tí yóò fàsẹ́yìn fún àwọn tí ó rìn ní àìlábùkù.
12 Panie zastępów! błogosławiony człowiek, który ma nadzieję w tobie.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.