< Psalmów 82 >
1 Psalm Asafowy. Bóg stoi w zgromadzeniu Bożem, a w pośród bogów sądzi i mówi:
Saamu ti Asafu. Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá, ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn “ọlọ́run òrìṣà”.
2 Dokądże będziecie niesprawiedliwie sądzić, a osoby niezbożników przyjmować? (Sela)
“Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìṣòdodo kí ó sì ṣe ojú ìṣáájú sí àwọn ènìyàn búburú?
3 Czyńcie sprawiedliwość ubogiemu i sierotce; utrapionego i niedostatecznego usprawiedliwiajcie.
Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba; ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.
4 Wyrwijcie chudzinę i nędznego, a z ręki niepobożnej wyrwijcie go.
Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní; gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.
5 Lecz oni nic nie wiedzą, ani rozumieją; w ciemnościach ustawicznie chodzą; zaczem się zachwiały wszystkie grunty ziemi.
“Wọn kò mọ̀ ohun kankan, wọn kò lóye ohun kankan. Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn; à si mí gbogbo ìpìlẹ̀ ayé.
6 Jam rzekł: Bogowieście, a synami Najwyższego wy wszyscy jesteście.
“Mo wí pé, ‘Ẹyin ní “Ọlọ́run òrìṣà”; ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ.’
7 A wszakże jako i inni ludzie pomrzecie, a jako jeden z książąt upadniecie.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ó kú bí ènìyàn lásán; ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ-aládé.”
8 Powstańże, o Boże! a sądź ziemię; albowiem ty dziedzicznie trzymasz wszystkie narody.
Dìde, Ọlọ́run, ṣe ìdájọ́ ayé, nítorí gbogbo orílẹ̀-èdè ni ìní rẹ.