< Psalmów 79 >

1 Psalm podany Asafowi. O Boże! wtargnęli poganie w dziedzictwo twoje, splugawili kościół twój święty, obrócili Jeruzalem w kupy gruzu.
Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
2 Dali trupy sług twoich na pokarm ptastwu powietrznemu, ciała świętych twoich bestyjom ziemskim.
Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
3 Wylali krew ich jako wodę około Jeruzalemu, a nie był, ktoby ich pochował.
Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
4 Staliśmy się pohańbieniem u sąsiadów naszych; śmiechowiskiem i igrzyskiem u tych, którzy są około nas.
Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
5 Dokądże, o Panie? azaż na wieki gniewać się będziesz? a jako ogień pałać będzie zapalczywość twoja?
Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
6 Wylij gniew twój na pogan, którzy cię nie znają, i na królestwa, które imienia twego nie wzywają.
Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
7 Albowiemci pożarli Jakóba, a mieszkanie jego spustoszyli.
nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
8 Nie wspominajże nam przeszłych nieprawości naszych; niech nas rychło uprzedzi miłosierdzie twoje, bośmy bardzo znędzeni.
Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
9 Wspomóżże nas, o Boże zbawienia naszego! dla chwały imienia twego, a wyrwij nas, i bądź miłościw grzechom naszym dla imienia twego.
Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
10 Przeczżeby mieli mówić poganie: Gdzież jest Bóg ich? Bądź znacznym między poganami, przed oczyma naszemi, dla pomsty krwi sług twoich, która jest wylana.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
11 Niech przyjdzie przed oblicze twoje narzekanie więźniów, a według wielkości ramienia twego zachowaj ostatki tych, co są na śmierć skazani.
Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
12 A oddaj sąsiadom naszym siedmiorako na łono ich za pohańbienie ich, któreć uczynili, o Panie!
San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
13 Ale my lud twój i owce pastwiska twego, będziemy cię wysławiali na wieki; od narodu do narodu będziemy opowiadać chwałę twoję.
Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.

< Psalmów 79 >