< Psalmów 78 >

1 Pieśń wyuczająca podana Asafowi. Słuchaj, ludu mój! zakonu mego; nakłońcież uszów swych do słów ust moich.
Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
2 Otworzę w podobieństwie usta moje, a będę opowiadał przypowiastki starodawne.
Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
3 Cośmy słyszeli, i poznali, i co nam ojcowie nasi opowiadali.
ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
4 Nie zataimy tego przed synami ich, którzy przyszłym potomkom swoim opowiadać będą chwały Pańskie, i moc jego, i cuda jego, które uczynił.
Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
5 Bo wzbudził świadectwo w Jakóbie, a zakon wydał w Izraelu; przykazał ojcom naszym, aby to do wiadomości podawali synom swoim,
Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
6 Aby poznał wiek potomny, synowie, którzy się narodzić mieli, a oni zaś powstawszy, aby to opowiadali synom swoim;
nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
7 Aby pokładali w Bogu nadzieję swoję, a nie zapominali na sprawy Boże, ale strzegli przykazań jego;
Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
8 Aby się nie stali jako ojcowie ich narodem odpornym i nieposłusznym, narodem, który nie wygotował serca swego, aby był wierny Bogu duch jego.
Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
9 Albo jako synowie Efraimowi zbrojni, którzy, choć umieli z łuku strzelać, wszakże w dzień wojny tył podali.
Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
10 Bo nie przestrzegali przymierza Bożego, a według zakonu jego zbraniali się chodzić.
Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
11 Zapomnieli na sprawy jego, i na dziwne dzieła jego, które im pokazywał.
Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
12 Przed ojcami ich czynił cuda w ziemi Egipskiej, na polu Soan.
Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
13 Rozdzielił morze, i przeprowadził ich, i sprawił, że stanęły wody jako kupa.
Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
14 Prowadził ich w obłoku we dnie, a każdej nocy w jasnym ogniu.
Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
15 Rozszczepił skały na puszczy, a napoił ich, jako z przepaści wielkich.
Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
16 Wywiódł strumienie ze skały, a uczynił, że wody ciekły jako rzeki.
Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
17 A wszakże oni przyczynili grzechów przeciwko niemu, a wzruszyli Najwyższego na puszczy do gniewu;
Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
18 I kusili Boga w sercu swem, żądając pokarmu według lubości swojej.
Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
19 A mówili przeciwko Bogu temi słowy: Izali może Bóg zgotować stół na tej puszczy?
Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
20 Oto uderzył w skałę, a wypłynęły wody, i rzeki wezbrały; izali też będzie mógł dać chleb? Izali nagotuje mięsa ludowi swemu?
Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
21 Przetoż usłyszawszy to Pan, rozgniewał się, a ogień się zapalił przeciw Jakóbowi, także i popędliwość powstała przeciw Izraelowi;
Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
22 Przeto, iż nie wierzyli Bogu, a nie mieli nadziei w zbawieniu jego.
nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
23 Choć był rozkazał obłokom z góry, i forty niebieskie otworzył.
Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
24 I spuścił im jako deszcz mannę ku pokarmowi, a pszenicę niebieską dał im.
Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
25 Chleb mocarzów jadł człowiek, a zesłał im pokarmów do sytości.
Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
26 Obrócił wiatr ze wschodu na powietrzu, a przywiódł mocą swą wiatr z południa;
Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
27 I spuścił na nich mięso jako proch, i ptastwo skrzydlate jako piasek morski;
Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
28 Spuścił je w pośród obozu ich, wszędy około namiotów ich.
Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
29 I jedli, a nasyceni byli hojnie, i dał im, czego żądali.
Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
30 A gdy jeszcze nie wypełnili żądości swej, gdy jeszcze pokarm był w ustach ich:
Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
31 Tedy zapalczywość Boża przypadła na nich, i pobił tłustych ich, a przedniejszych z Izraela poraził.
ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
32 Ale w tem wszystkiem jeszcze grzeszyli, i nie wierzyli cudom jego;
Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
33 Przetoż sprawił, że marnie dokonali dni swoich, i lat swoich w strachu.
O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
34 Gdy ich tracił, jeźliże go szukali, i nawracali się, a szukali z rana Boga,
Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
35 Przypominając sobie, iż Bóg był skałą ich, a Bóg najwyższy odkupicielem ich:
Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
36 (Aczkolwiek pochlebiali mu usty swemi, i językiem swoim kłamali mu;
Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
37 A serce ich nie było szczere przed nim, ani wiernymi byli w przymierzu jego.)
ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
38 On jednak będąc miłosierny odpuszczał nieprawości ich, a nie zatracał ich, ale częstokroć odwracał gniew swój, a nie pobudzał wszystkiego gniewu swego;
Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
39 Bo pamiętał, że są ciałem, wiatrem, który odchodzi, a nie wraca się zaś.
Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
40 Jako go często draźnili na puszczy, i do boleści przywodzili na pustyniach?
Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
41 Bo coraz kusili Boga, a Świętemu Izraelskiemu granice zamierzali.
Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
42 Nie pamiętali na rękę jego, i na on dzień, w który ich wybawił z utrapienia;
Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
43 Gdy czynił w Egipcie znaki swoje, a cuda swe na polu Soan;
ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
44 Gdy obrócił w krew rzeki ich, i strumienie ich, tak, że z nich pić nie mogli.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
45 Przepuścił na nich rozmaite muchy, aby ich kąsały, i żaby, aby ich gubiły:
Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
46 I dał chrząszczom urodzaje ich, a prace ich szarańczy.
Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
47 Potłukł gradem szczepy ich, a drzewa leśnych fig ich gradem lodowym.
Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
48 I podał gradowi bydło ich, a majętność ich węglu ognistemu.
Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
49 Posłał na nich gniew zapalczywości swojej, popędliwość, i rozgniewanie, i uciśnienie, przypuściwszy na nich aniołów złych.
Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
50 Wyprostował ścieżkę gniewowi swemu, nie zachował od śmierci duszy ich, i na bydło ich powietrze dopuścił;
Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
51 I pobił wszystko pierworodztwo w Egipcie, pierwiastki mocy ich w przybytkach Chamowych;
Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
52 Ale jako owce wyprowadził lud swój, a wodził ich jako stada po puszczy.
Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
53 Wodził ich w bezpieczeństwie, tak, że się nie lękali, (a nieprzyjaciół ich okryło morze, )
Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
54 Aż ich przywiódł do świętej granicy swojej, na onę górę, której nabyła prawica jego.
Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
55 I wyrzucił przed twarzą ich narody, i sprawił, że im przyszły na sznur dziedzictwa ich, ażeby mieszkały w przybytkach ich pokolenia Izraelskie.
Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
56 A wszakże przecież kusili i draźnili Boga najwyższego, a świadectwa jego nie strzegli.
Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
57 Ale się odwrócili, i przewrotnie się obchodzili, jako i ojcowie ich; wywrócili się jako łuk omylny.
Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
58 Bo go wzruszyli do gniewu wyżynami swemi, a rytemi bałwanami swemi pobudzili go do zapalczywości.
Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
59 Co słysząc Bóg rozgniewał się, i zbrzydził sobie bardzo Izraela,
Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
60 Tak, że opuściwszy przybytek w Sylo, namiot, który postawił między ludźmi,
Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
61 Podał w niewolę moc swoję, i sławę swoję w ręce nieprzyjacielskie.
Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
62 Dał pod miecz lud swój, a na dziedzictwo swoje rozgniewał się.
Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
63 Młodzieńców jego ogień pożarł, a panienki jego nie były uczczone.
Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
64 Kapłani jego od miecza polegli, a wdowy jego nie płakały.
àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
65 Lecz potem ocucił się Pan jako ze snu, jako mocarz wykrzykający od wina.
Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
66 I zaraził nieprzyjaciół swoich na pośladkach, a na wieczną hańbę podał ich.
Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
67 Ale choć wzgardził namiotem Józefowym, a pokolenia Efraimowego nie obrał,
Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
68 Wszakże obrał pokolenie Judowe, i górę Syon, którą umiłował.
ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
69 I wystawił sobie jako pałac wysoki świątnicę swoję, jako ziemię, którą ugruntował na wieki.
Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
70 I obrał Dawida sługę swego, wziąwszy go z obór owczych;
Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
71 Gdy chodził za owcami kotnemi, przyprowadził go, aby pasł Jakóba, lud jego, i Izraela, dziedzictwo jego;
Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
72 Który ich pasł w szczerości serca swego, a w roztropności rąk swoich prowadził ich.
Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.

< Psalmów 78 >