< Psalmów 73 >

1 Psalm Asafowy. Zaisteć dobry jest Bóg Izraelowi, tym, którzy są czystego serca.
Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
2 Ale nogi moje mało się były nie potknęły, a blisko tego było, że mało nie szwankowały kroki moje,
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
3 Gdym był zawiścią poruszon przeciwko szalonym, widząc szczęście niepobożnych.
Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
4 Bo nie mają związków aż do śmierci, ale w całości zostaje siła ich.
Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
5 W pracy ludzkiej nie są, a kaźni, jako inni ludzie, nie doznawają.
Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
6 Przetoż otoczeni są pychą, jako łańcuchem złotym, a przyodziani okrutnością, jako szatą ozdobną.
Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
7 Wystąpiły od tłustości oczy ich, a więcej mają nad pomyślenie serca.
Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
8 Rozpuścili się, i mówią złośliwie, o uciśnieniu bardzo hardzie mówią.
Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
9 Wystawiają przeciwko niebu usta swe, a język ich krąży po ziemi.
Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
10 A przetoż na to przychodzi lud jego, gdy się im wody już wierzchem leją,
Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
11 Że mówią: Jakoż ma Bóg o tem wiedzieć? albo mali o tem wiadomość Najwyższy?
Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
12 Albowiem, oto ci niezbożnymi będąc, mają pokój na świecie, i nabywają bogactw.
Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
13 Próżno tedy w czystości chowam ręce moje, a w niewinności serce moje omywam.
Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
14 Ponieważ mię cały dzień biją, a karanie cierpię na każdy poranek.
Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
15 Rzekęli: Będę też tak o tem mówił, tedy rodzaj synów twoich rzecze, żem im niepraw.
Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
16 Chciałemci tego rozumem doścignąć, ale mi się tu trudno zdało;
Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
17 Ażem wszedł do świątnicy Bożej, a tum porozumiał dokończenie ich.
títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
18 Zprawdęś ich na miejscach śliskich postawił, a podajesz ich na spustoszenie.
Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
19 Oto jakoć przychodzą na spustoszenie! niemal w okamgnieniu niszczeją i giną od strachu.
Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
20 Są jako sen temu, co ocucił; Panie! gdy ich obudzisz obraz ich lekce poważysz.
Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
21 Gdy zgorzkło serce moje, a nerki moje cierpiały kłucie:
Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
22 Zgłupiałem był, a nicem nie rozumiał, byłem przed tobą jako bydlę.
mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
23 A wszakże zawżdy byłem z tobą; boś mię trzymał za prawą rękę moję.
Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
24 Według rady swej prowadź mię, a potem do chwały przyjmiesz mię.
Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
25 Kogożbym innego miał na niebie? I na ziemi oprócz ciebie w nikim innym upodobania nie mam.
Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
26 Choć ciało moje, i serce moje ustanie, jednak Bóg jest skałą serca mego, i działem moim na wieki.
Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
27 Gdyż oto ci, którzy się oddalają od ciebie, zginą; wytracasz tych, którzy cudzołożą odstępowaniem od ciebie.
Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
28 Aleć mnie najlepsza jest trzymać się Boga; przetoż pokładam w Panu panującym nadzieję moję, abym opowiadał wszystkie sprawy jego.
Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.

< Psalmów 73 >