< Psalmów 7 >

1 Syggajon Dawidowe, które śpiewał Panu dla słów Chusy, syna Jemini. Panie, Boże mój! w tobie ufam; wybawże mię od wszystkich prześladowców moich, i wyzwól mię;
Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ; gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
2 By snać duszy mojej nie porwał jako lew, a nie rozszarpał, gdyby nie było, ktoby ją wybawił.
kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún, wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
3 Panie, Boże mój! jeźlim to uczynił, a jeźli jest nieprawość w rękach moich;
Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
4 Jeźlim złe oddał temu, który ze mną w pokoju mieszkał; jeźliżem nie wyrwał tego, który mię dręczył bez przyczyny:
bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
5 Niechajże prześladuje nieprzyjaciel duszę moję, a niechaj pochwyci, i podepcze na ziemi żywot mój, a sławę moję niech zagrzebie w proch. (Sela)
nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi; jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀ kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. (Sela)
6 Powstańże, Panie! w popędliwości twojej, podnieś się przeciwko wściekłości nieprzyjaciół moich, ocuć się, a obróć się ku mnie; boś ty sąd postanowił;
Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ; dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi. Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
7 Tedy się do ciebie zbieży zgromadzenie narodów; dla nich tedy usiądź na wysokości.
Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká. Jọba lórí wọn láti òkè wá.
8 Pan będzie sądził narody. Osądźże mię, Panie! według sprawiedliwości mojej, i według niewinności mojej, która jest przy mnie.
Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
9 Niechże, proszę, ustanie złość niepobożnych, a umocnij sprawiedliwego, który doświadczasz serc i wnętrzności, o Boże sprawiedliwy!
Ọlọ́run Olódodo, Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn, tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
10 Bóg jest tarczą moją, który wybawia ludzi serca szczerego.
Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
11 Bóg jest sędzią sprawiedliwym; Bóg obrusza się co dzień na niezbożnego.
Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́, Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
12 Jeźli się nie nawróci, naostrzy miecz swój; łuk swój wyciągnął, i nagotował go.
Bí kò bá yípadà, Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú; ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
13 Zgotował nań broń śmiertelną, a strzały swoje na prześladowników przyprawił.
Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀; ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
14 Oto rodzi nieprawość, bo począł boleść; ale porodzi kłamstwo.
Ẹni tí ó lóyún ohun búburú, tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
15 Kopał dół, i wykopał go; ale wpadnie w dół, który sam uczynił.
Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
16 Obróci się boleść jego na głowę jego, a na wierzch głowy jego nieprawość jego spadnie.
Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀; ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
17 Będę wysławiał Pana według sprawiedliwości jego, a będę śpiewał imieniowi Pana najwyższego.
Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀, èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.

< Psalmów 7 >