< Psalmów 69 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi na Sosannim psalm Dawidowy. Wybaw mię, o Boże! boć przyszły wody aż do duszy mojej.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Pogrążony jestem w głębokiem błocie, gdzie dna niemasz; przyszedłem w głębokości wód, a nawałność ich porwała mię.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Spracowałem się wołając, wyschło gardło moje; ustały oczy moje, gdym oczekiwał Boga mojego.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 Więcej jest tych, którzy mię mają w nienawiści bez przyczyny, niż włosów na głowie mojej; zmocnili się ci, którzy mię wygubić usiłują, a są nieprzyjaciółmi mymi niesłusznie; czegom nie wydarł, musiałem nagradzać.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Boże! ty znasz głupstwo moje, a występki moje nie są tajne przed tobą.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Niechajże nie będą zawstydzeni dla mnie ci, którzy na cię oczekują, Panie, Panie zastępów! niech nie przychodzą dla mnie do hańby ci, którzy cię szukają, o Boże Izraelski!
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Bo dla ciebie ponoszę urąganie, a zelżywość okryła oblicze moje.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 Stałem się obcym braciom moim, a cudzoziemcem synom matki mojej,
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Przeto, że gorliwość domu twego zżarła mię, a urąganie urągających tobie przypadło na mię.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Gdym płakał i trapił postem duszę moję, stało mi się to pohańbienie.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Gdym wziął na się wór miasto szaty, byłem u nich przypowieścią.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 Mówili o mnie ci, którzy siedzieli w bramie, a byłem piosnką u tych, którzy pili mocny napój.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Ale ja obracam modlitwę moję do ciebie, Panie! czas jest upodobania twego; o Boże! według wielkości miłosierdzia twego wysłuchajże mię, dla prawdy zbawienia twego.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Wyrwij mię z błota, abym nie był pogrążony; niech będę wyrwany od tych, którzy mię nienawidzą, jako z głębokości wód;
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Aby mię nie zatopiły strumienie wód, i nie pożarła głębia i nie zawarła nademną studnia wierzchu swego.
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Wysłuchajże mię, Panie! boć dobre jest miłosierdzie twoje; według wielkiej litości twojej wejrzyj na mię.
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Nie zakrywajże oblicza twego od sługi swego, bom jest w utrapieniu; pośpieszże się, wysłuchaj mię.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Przybliż się do duszy mojej, a wybaw ją; dla nieprzyjaciół moich odkup mię.
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Ty znasz pohańbienie moje, i zelżywość moję, i wstyd mój: przed tobąć są wszyscy nieprzyjaciele moi.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Pohańbienie pokruszyło serce moje, z czegom był żałośny; oczekiwałem, azaliby się mię kto użalił, ale nikt nie był; azaliby mię kto pocieszył, alem nie znalazł.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Owszem, miasto pokarmu podali mi żółć, a w pragnieniu mojem napoili mię octem.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Niechajże im będzie stół ich przed nimi sidłem, a szczęście ich na upadek.
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Niech się zaćmią oczy ich, aby nie widzieli, a biodra ich niech się zawżdy chwieją.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Wylij na nich rozgniewanie swoje, a popędliwość gniewu twego niech ich ogarnie.
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Niech będzie mieszkanie ich puste, w namiotach ich niech nikt nie mieszka.
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Bo tego, któregoś ty ubił, prześladują, a o boleści poranionych twoich rozmawiają.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Przydajże nieprawość ku nieprawości ich, a niech nie przychodzą do sprawiedliwości twojej.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Niech będą wymazani z ksiąg żyjących, a z sprawiedliwymi niech nie będą zapisani.
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Jamci utrapiony, i zbolały; lecz zbawienie twoje, Boże! na miejscu bezpiecznem postawi mię.
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 Tedy będę chwalił imię Boże pieśnią, a będę je wielbił z dziękczynieniem.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 A będzie to przyjemniejsze Panu, niżeli wół albo cielec rogaty z rozdzielonemi kopytami.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 To widząc pokorni rozradują się, szukając Boga, a ożyje serce ich;
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 Iż wysłuchiwa Pan ubogich, a więźniami swymi nie gardzi.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Niech go chwalą niebiosa i ziemia, morze i wszystko, co się w nich rucha.
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Bógci zaiste zachowa Syon, i pobuduje miasta Judzkie; i będą tam mieszkać, a ziemię tę dziedzicznie otrzymają.
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 Także i nasienie sług jego dziedzicznie ją otrzyma, a którzy miłują imię jego, będą w niej mieszkać.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Psalmów 69 >