< Psalmów 68 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy ku śpiewaniu. Powstanie Bóg, a będą rozproszeni nieprzyjaciele jego, i pouciekają przed twarzą jego ci, którzy go mają w nienawiści.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
2 Jako bywa dym rozpędzony, tak ich rozpędzasz: jako się wosk rozpływa od ognia, tak niezbożnicy poginą przed obliczem Bożem.
Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
3 Ale sprawiedliwi weselić się i radować będą przed obliczem Bożem, i pląsać będą od radości.
Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
4 Śpiewajcie Bogu, śpiewajcie psalmy imieniowi jego; gotujcie drogę temu, który jeździ na obłokach. Pan jest imię jego, radujcież się przed obliczem jego.
Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
5 Ojcem jest sierót, i sędzią wdów, Bogiem w przybytku swym świętym.
Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
6 Bóg, który samotne w rodowite domy rozmnaża, wywodzi więźniów z oków; ale odporni mieszkać muszą w ziemi suchej.
Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
7 Boże! gdyś wychodził przed obliczem ludu twego, gdyś chodził po puszczy; (Sela)
Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
8 Ziemia się trzęsła, także i niebiosa rozpływały się przed obliczem Bożem, i ta góra Synaj drżała przed twarzą Boga, Boga Izraelskiego.
Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
9 Deszcz obfity spuszczałeś hojnie, o Boże! na dziedzictwo twoje, a gdy omdlewało, tyś je zaś otrzeźwiał.
Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
10 Zastępy twoje mieszkają w niem, któreś ty dla ubogiego nagotował dobrocią twoją, o Boże!
Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
11 Pan dał słowo swe, i tych, którzy pociechy zwiastowali, zastęp wielki mówiących.
Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
12 Królowie z wojskami uciekali, uciekali: ale ta, która przyglądała domu, dzieliła łupy.
“Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
13 Chociażeście leżeć musieli między kotłami, przecież będziecie jako gołębica, mająca pióra posrebrzone, a której skrzydła jako żółte złoto.
Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
14 Gdy Wszechmogący rozproszy królów w tej ziemi, wybielejesz jako śnieg na górze Salmon.
Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
15 Na górze Bożej, na górze Basańskiej, na górze pogórczystej, na górze Basańskiej.
Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
16 Przeczże wyskakujecie góry pogórczyste? na tejci górze ulubił sobie Bóg mieszkanie, tamci Pan będzie mieszkał na wieki.
Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
17 Wozów Bożych jest dwadzieścia tysięcy, wiele tysięcy Aniołów; ale Pan między nimi jako na Synaj w świątnicy przebywa.
Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
18 Wstąpiłeś na wysokość, wiodłeś pojmanych więźniów, nabrałeś darów dla ludzi, i najodporniejszych, Panie Boże! przywiodłeś, aby mieszkali z nami.
Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
19 Błogosławiony Pan; na każdy dzień hojnie nas opatruje dobrami swemi Bóg zbawienia naszego. (Sela)
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
20 On jest Bóg nasz, Bóg obfitego zbawienia; panujący Pan z śmierci wywodzi.
Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
21 Zaiste Bóg zrani głowę nieprzyjaciół swoich, i wierzch głowy włosami nakryty chodzącego w grzechach swoich.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
22 Rzekł Pan: Wyprowadzę zaś swoich jako z Basan, wywiodę ich zaś z głębokości morskiej.
Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
23 Przetoż będzie noga twoja zbroczona we krwi, i język psów twoich we krwi nieprzyjacielskiej.
kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
24 Widzieli ciągnienia twoje, Boże! ciągnienia Boga mego i króla mego w świątnicy.
Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
25 Wprzód szli śpiewacy, a za nimi grający na instrumentach, a w pośrodku panienki bijąc w bębny.
Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
26 W zgromadzeniach błogosławcie Bogu, błogosławcie Panu, którzyście z narodu Izraelskiego. Tu niech będzie Benjamin maluczki, który ich opanował;
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
27 Tu książęta Judzcy, i hufy ich, książęta Zabulońscy, i książęta Neftalimscy.
Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
28 Obdarzył cię Bóg twój siłą; utwierdź, o Boże! to, coś w nas sprawił.
Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
29 Dla kościoła twego, który jest w Jeruzalemie, będąć królowie dary przynosić.
Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
30 Poraź poczet kopijników, zgromadzenie mocnych wodzów, i ludu bujnego, hardych, chlubiących się kęsem srebra; rozprosz narody pragnące wojny.
Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
31 Przyjdąć zacni książęta z Egiptu: Murzyńska ziemia pospieszy się wyciągnąć ręce swe do Boga.
Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
32 Królestwa ziemi! śpiewajcież Bogu, śpiewajcie Panu. (Sela)
Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
33 Temu, który jeździ na najwyższych niebiosach od wieczności; oto wydaje głos swój, głos mocy swojej.
Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
34 Przyznajcie moc Bogu, nad Izraelem dostojność jego, a wielmożność jego na obłokach.
Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
35 Strasznyś jest, o Boże! z świętych przybytków twoich; Bóg Izraelski sam daje moc i siły ludowi swemu. Niechajże będzie Bóg błogosławiony.
Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!

< Psalmów 68 >