< Psalmów 55 >
1 Przedniejszemu śpiewakowi na Neginot pieśń Dawidowa nauczająca. W uszy swe przyjmij, o Boże! modlitwę moję, a nie kryj się przed prośbą moją:
Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run, má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:
2 Posłuchaj mię z pilnością, a wysłuchaj mię; boć się uskarżam w modlitwie swej, i trwożę sobą:
gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn. Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.
3 Dla głosu nieprzyjaciela, i dla uciśnienia od bezbożnika; albowiem mię zarzucają kłamstwem, a w popędliwości swej sprzeciwiają mi się.
Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni, nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú; nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi, wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.
4 Serce moje boleje we mnie, a strachy śmierci przypadły na mię.
Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú; ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.
5 Bojaźń ze drżeniem przyszła na mię, a okryła mię trwoga.
Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi; ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.
6 I rzekłem: Obym miał skrzydła jako gołębica, zaleciałbym, a odpocząłbym.
Èmi sọ pé, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà! Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.
7 Otobym daleko zaleciał, a mieszkałbym na puszczy. (Sela)
Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré, kí ń sì dúró sí aginjù;
8 Pospieszyłbym, abym uszedł przed wiatrem gwałtownym, i przed wichrem.
èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò, jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle.”
9 Zatrać ich, Panie! rozdziel język ich; bom widział bezprawie i rozruch w mieście.
Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú, nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.
10 We dnie i w nocy otaczają ich po murach jego, a złość i przewrotność jest w pośrodku jego.
Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri; ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.
11 Ciężkości są w pośrodku jego, a nie ustępuje z ulic jego chytrość i zdrada.
Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀; ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.
12 Albowiem nie nieprzyjaciel jaki zelżył mię, inaczej zniósłbym to był; ani ten, który mię miał w nienawiści, powstał przeciwko mnie; bobym się wżdy był skrył przed nim;
Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi, èmi yóò fi ara mọ́ ọn; tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi, èmi ìbá sá pamọ́ fún un.
13 Ale ty, człowiecze mnie równy, wodzu mój, i znajomy mój.
Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi, ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,
14 Którzyśmy się z sobą mile w tajności naradzali, i do domu Bożego społecznie chadzali.
pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀, bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.
15 Oby ich śmierć z prędka załapiła, tak aby żywo zstąpili do piekła! albowiem złość jest w mieszkaniu ich, i w pośrodku ich. (Sheol )
Kí ikú kí ó dé bá wọn, kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú, jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà, nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn. (Sheol )
16 Ale ja do Boga zawołam, a Pan mię wybawi.
Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run; Olúwa yóò sì gbà mí.
17 W wieczór i rano, i w południe modlić się, i z trzaskiem wołać będę, aż wysłucha głos mój.
Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú, o sì gbọ́ ohùn mi.
18 Odkupi duszę moję, abym był w pokoju od wojny przeciwko mnie; bo ich wiele było przy mnie.
Ó rà mí padà láìléwu kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.
19 Wysłucha Bóg i utrapi ich, (jako ten, który siedzi od wieku. (Sela) przeto, że nie masz w nich poprawy, ani się Boga boją.
Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú àní, ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì (Sela) nítorí tí wọn kò ní àyípadà, tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.
20 Wyciągnął ręce swoje na tych, którzy z nim mieli pokój, wzruszył przymierze swoje.
Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀; ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.
21 Gładsze niż masło były słowa ust jego, ale walka w sercu jego: a mię kciejsze słowa jego niż olej, wszakże były jako miecze dobyte:
Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́, ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀; ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ, ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.
22 Wrzuć na Pana brzemię twoje, a on cię opatrzy, i nie dopuści, aby się na wieki zachwiać miał sprawiedliwy.
Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwa yóò sì mú ọ dúró; òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.
23 Ale ich ty, o Boże! wepchniesz w dół zginienia; mężowie krwawi i zdradliwi nie dojdą do połowy dni swoich; ale ja w tobie nadzieję mieć będę.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi wá sí ihò ìparun; àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn, kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn. Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.