< Psalmów 48 >

1 Pieśń psalmu synów Korego. Wielki jest Pan, i bardzo chwalebny w mieście Boga naszego, na górze świętej swojej.
Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Ẹni ńlá ní Olúwa, tí ó sì yẹ láti máa yìn ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ rẹ̀.
2 Ozdobą krainy, uciechą wszystkiej ziemi jest góra Syon w stronach północnych, miasto króla wielkiego.
Ó dára nínú ipò ìtẹ́ rẹ̀, ayọ̀ gbogbo ayé, òkè Sioni, ní ìhà àríwá ní ìlú ọba ńlá.
3 Bóg w pałacach jego uznany jest za twierdzę wysoką.
Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin rẹ̀; ó fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
4 Bo oto królowie, gdy się zgromadzili i ciągnęli wespół,
Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀, wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ.
5 Sami to ujrzawszy bardzo się zadziwili, a przestraszeni będąc prędko uciekali.
Wọn rí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n, a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ.
6 Strach ich tam ogarnął i boleść, jako niewiastę rodzącą.
Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀, ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí.
7 Wiatrem wschodnim pokruszysz okręty z Tarsys.
Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Tarṣiṣi, wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà-oòrùn.
8 Jakośmy słyszeli, takeśmy widzieli w mieście Pana zastępów, w mieście Boga naszego; Bóg je ugruntował aż na wieki. (Sela)
Gẹ́gẹ́ bí a ṣe gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwa rí, ní inú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ìlú Ọlọ́run wa, Ọlọ́run jẹ́ kí ó wà ní abẹ́ ààbò títí láéláé. (Sela)
9 Uważamy, o Boże! miłosierdzie twoje w pośród kościoła twego.
Láàrín tẹmpili rẹ, Ọlọ́run, àwa ti ń sọ ti ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
10 Jakie jest imię twoje, Boże! taka też jest chwała twoja aż do kończyn ziemi; sprawiedliwości pełna jest prawica twoja.
Gẹ́gẹ́ bí orúkọ rẹ Ọlọ́run, ìyìn rẹ̀ dé òpin ayé, ọwọ́ ọ̀tún rẹ kún fún òdodo.
11 NIech się rozweseli góra Syon: niech się rozradują córki Judzkie dla sądów twoich, Boże!
Jẹ́ kí òkè Sioni kí ó yọ̀ kí inú àwọn ọmọbìnrin Juda kí ó dùn nítorí ìdájọ́ rẹ.
12 Otoczcie Syon, i obstąpcie go; policzcie wieże jego.
Rìn Sioni kiri lọ yíká rẹ̀, ka ilé ìṣọ́ rẹ̀.
13 Przypatrujcie się pilnie basztom jego, a oglądajcie pałace jego, abyście umieli powiadać narodowi potomnemu.
Kíyèsi odi rẹ̀, kíyèsi àwọn ààfin rẹ̀ kí ẹ̀yin lè máa wí fún ìran tí ń bọ̀.
14 Że ten Bóg jest Bogiem naszym na wieki wieczne, a iż on naszym hetmanem będzie aż do śmierci.
Nítorí Ọlọ́run yìí Ọlọ́run wà ní títí ayé, Òun ni yóò ṣe amọ̀nà wa títí dè òpin ayé.

< Psalmów 48 >