< Psalmów 41 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi pieśń Dawidowa. Błogosławiony, który ma baczenie na potrzebnego; w dzień zły wybawi go Pan.
Fún adarí orin. Saamu Dafidi. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní: Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
2 Pan go będzie strzegł, i żywić go będzie; błogosławony będzie na ziemi, ani go poda na wolę nieprzyjaciół jego.
Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
3 Pan go posili na łożu niemocy jego; wszystko leżenie jego odmieni w chorobie jego.
Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀ yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
4 Jam rzekł: Panie! zmiłuj się nademną, uzdrów duszę moję, bom tobie zgrzeszył.
Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
5 Nieprzyjaciele moi mówili źle o mnie: Kiedyż wżdy umrze, a zginie imię jego?
Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé, “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
6 Jeźli też który z nich przychodzi, aby mię nawiedził, tedy na zdradzie mówi; serce jego zgromadza sobie nieprawość, a precz odszedłszy roznosi.
Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
7 Społem przeciwko mnie szepczą wszyscy, którzy mię mają w nienawiści, a myślą złe o mnie,
Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
8 Mówiąc: Pomsta się nań za niezbożność wylała, a iż się położył, więcej nie wstanie.
wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́.”
9 Także i ten, z którymem żył w pokoju, któremum ufał, który chleb mój jadał, podniósł piętę przeciwko mnie.
Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
10 Ale ty, Panie! zmiłuj się nademną, a podnieś mię, i oddam im.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
11 A przez to poznam, że się kochasz we mnie, gdy się nie będzie weselił nieprzyjaciel mój ze mnie.
Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
12 Ale ty w niewinności mojej wesprzesz mię i postawisz mię przed obliczem twojem na wieki.
Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
13 Błogosławiony Pan, Bóg Izraelski, od wieku aż na wieki. Amen, Amen.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé.

< Psalmów 41 >