< Psalmów 31 >
1 Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy. W tobie, Panie! nadzieję mam, niech nie będę zawstydzony na wieki; w sprawiedliwości twojej wybaw mię.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nínú rẹ̀, Olúwa ni mo ti rí ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí; gbà mí nínú òdodo rẹ.
2 Nakłoń ku mnie ucha twego, co rychlej wybaw mię; bądźże mi mocną skałą, domem obronnym, abyś mię zachował.
Tẹ́ etí rẹ sí mi, gbà mí kíákíá; jẹ́ àpáta ààbò mi, jẹ́ odi alágbára láti gbà mí.
3 Boś ty jest skałą moją, i obroną moją; przetoż dla imienia twego prowadź mię, i zaprowadź mię.
Ìwọ pàápàá ni àpáta àti ààbò mi, nítorí orúkọ rẹ, máa ṣe olùtọ́ mi, kí o sì ṣe amọ̀nà mi.
4 Wywiedź mię z sieci, którą zastawili na mię; boś ty jest mocą moją.
Yọ mí jáde kúrò nínú àwọ̀n tí wọ́n dẹ pamọ́ fún mi, nítorí ìwọ ni ìsádi mi.
5 W ręce twoje poruczam ducha mego; odkupiłeś mię, Panie, Boże prawdziwy!
Ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé; ìwọ ni o ti rà mí padà, Olúwa, Ọlọ́run òtítọ́.
6 Mam w nienawiści tych, którzy przestrzegają próżnych marności; bo ja w Panu nadzieję pokładam.
Èmi ti kórìíra àwọn ẹni tí ń fiyèsí òrìṣà tí kò níye lórí; ṣùgbọ́n èmi gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
7 Będę się radował i weselił w miłosierdziu twojem, żeś wejrzał na utrapienie moje, a poznałeś uciśnienie duszy mojej.
Èmi yóò yọ̀, inú mi yóò dùn nínú ìfẹ́ ńlá rẹ, nítorí ìwọ ti rí ìbìnújẹ́ mi ìwọ ti mọ̀ ọkàn mi nínú ìpọ́njú.
8 Aniś mię zawarł w ręce nieprzyjaciela; aleś postawił na przestrzeństwie nogi moje.
Pẹ̀lú, ìwọ kò sì fà mi lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́ ìwọ ti fi ẹsẹ̀ mi lé ibi ààyè ńlá.
9 Zmiłuj się nademną, Panie! bom jest uciśniony; wywiędła od żałości twarz moja; także i dusza moja i żywot mój.
Ṣàánú fún mi, ìwọ Olúwa, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú; ojú mi fi ìbìnújẹ́ sùn, ọkàn àti ara mi pẹ̀lú.
10 Albowiem zwątlało od boleści zdrowie moje, a lata moje od wzdychania; zemdlała dla utrapianie mego siła moja, a kości moje wyschły.
Èmi fi ìbànújẹ́ lo ọjọ́ mi àti àwọn ọdún mi pẹ̀lú ìmí ẹ̀dùn; agbára mi ti kùnà nítorí òsì mi, egungun mi sì ti rún dànù.
11 U wszystkich nieprzyjaciół moich jestem w pohańbieniu wielkiem, a najwięcej u sąsiadów moich; stałem się na postrach znajomym moim; którzy mię widzą na dworze, uciekają przedemną.
Èmi di ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ọ̀tá mi gbogbo, pẹ̀lúpẹ̀lú láàrín àwọn aládùúgbò mi, mo sì di ẹ̀rù fún àwọn ojúlùmọ̀ mi; àwọn tí ó rí mi ní òde ń yẹra fún mi.
12 Wypadłem z pamięci jako umarły; stałem się jako naczynie stłuczone.
Èmi ti di ẹni ìgbàgbé kúrò ní ọkàn gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ti kú; èmi sì dàbí ohun èlò tí ó ti fọ́.
13 Albowiem nasłucham się uszczypków od wielu; strachu dość zewsząd, gdy się naradzają wespół przeciwko mnie, chytrze przemyśliwając, aby odjęli duszę moję.
Nítorí mo gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpayà tí ó yí mi ká; tí wọn gbìmọ̀ pọ̀ sí mi, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi láti gba ẹ̀mí mi.
14 Ale ja w tobie mam nadzieję, Panie! Rzekłem: Tyś jest Bogiem moim.
Ṣùgbọ́n èmí gbẹ́kẹ̀lé ọ, ìwọ Olúwa; mo sọ wí pé, “Ìwọ ní Ọlọ́run mi.”
15 W rękach twoich są czasy moje; wyrwijże mię z ręki nieprzyjaciół moich, i od tych, którzy mię prześladują.
Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ; gbà mí kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá mi àti àwọn onínúnibíni.
16 Oświeć oblicze twoje nad sługą twoim; wybaw mię przez miłosierdzie twoje.
Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tan ìmọ́lẹ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ lára; gbà mí nínú ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.
17 Panie! niech nie będę pohańbiony, ponieważ cię wzywam; niech się zawstydzą niezbożni, i zamilkną w grobie. (Sheol )
Má ṣe jẹ́ kí ojú ki ó tì mí, Olúwa; nítorí pé mo ké pè ọ́; jẹ́ kí ojú kí ó ti ènìyàn búburú; jẹ́ kí wọ́n lọ pẹ̀lú ìdààmú sí isà òkú. (Sheol )
18 Niech zaniemieją wargi kłamliwe, które mówią przeciwko sprawiedliwemu rzeczy przykre z hardością i ze wzgardą.
Jẹ́ kí àwọn ètè irọ́ kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́, pẹ̀lú ìgbéraga àti ìkẹ́gàn, wọ́n sọ̀rọ̀ àfojúdi sí olódodo.
19 O jakoż jest wielka dobroć twoja, którąś zachował bojącym się ciebie, którąś pokazywał tym, którzy ufają w tobie przed synami ludzkimi.
Báwo ni títóbi oore rẹ̀ ti pọ̀ tó, èyí tí ìwọ ti ní ní ìpamọ́ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, èyí tí ìwọ rọ̀jò rẹ̀ níwájú àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọ́ ṣe ibi ìsádi wọn.
20 Ukrywasz ich w skrytości oblicza twego, przed hardością człowieczą ukrywasz ich, jako w namiocie, przed swarliwemi językami.
Ní abẹ́ ìbòòji iwájú rẹ ni ìwọ pa wọ́n mọ́ sí kúrò nínú ìdìmọ̀lù àwọn ènìyàn; ní ibùgbé rẹ, o mú wọn kúrò nínú ewu kúrò nínú ìjà ahọ́n.
21 Błogosławiony Pan! bo dziwnie okazał miłosierdzie swoje przeciwko mnie, jakoby w mieście obronnem.
Olùbùkún ni Olúwa, nítorí pé ó ti fi àgbà ìyanu ìfẹ́ tí ó ní sí mi hàn, nígbà tí mo wà ní ìlú tí wọ́n rọ̀gbà yíká.
22 Jam rzekł w uciekaniu mojem: Odrzuconym jest od oczów twych; aleś ty wysłuchał głos modlitw moich, gdym wołał do ciebie.
Èmí ti sọ nínú ìdágìrì mi, “A gé mi kúrò ní ojú rẹ!” Síbẹ̀ ìwọ ti gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú nígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.
23 Miłujcież Pana wszyscy święci jego; boć Pan wiernych strzeże, oddaje sowicie hardzie postępującemu.
Ẹ fẹ́ Olúwa, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́! Olúwa pa olódodo mọ́, ó sì san án padà fún agbéraga ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́.
24 Zmacniajcie się (a posili Bóg serca wasze) wszyscy, którzy nadzieję macie w Panu.
Jẹ́ alágbára, yóò sì mú yín ní àyà le gbogbo ẹ̀yin tí ó dúró de Olúwa.