< Psalmów 17 >

1 Modlitwa Dawidowa. Wysłuchaj, Panie! sprawiedliwość moję; miej wzgląd na wołanie moje; przyjmij w uszy modlitwę moję, którą czynię usty nieobłudnemi.
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi; fi etí sí igbe mi. Tẹ́tí sí àdúrà mi tí kò ti ètè ẹ̀tàn jáde.
2 Od obliczności twojej sąd mój niech wynijdzie; oczy twoje niech patrzą na uprzejmość.
Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ; kí ojú rẹ kí ó rí ohun tí ó tọ́.
3 Doświadczyłeś serca mego, nawiedziłeś je w nocy; doświadczyłeś mię ogniem, aleś nic nie znalazł; myśli moje nie uprzedzają ust moich.
Ìwọ ti dán àyà mi wò, ìwọ sì bẹ̀ mí wò ní òru, o sì ti wádìí mi, ìwọ kì yóò rí ohunkóhun èmi ti pinnu pé, ẹnu mi kì yóò ṣẹ̀.
4 Co się tknie spraw ludzkich według słowa ust twoich, chroniłem się drogi okrutnika.
Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ, èmi ti pa ara mi mọ́ kúrò ní ọ̀nà àwọn ìkà.
5 Zatrzymuj kroki moje na drogach twych, aby się nie chwiały nogi moje.
Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ; ẹsẹ̀ mi kì yóò yọ̀.
6 Ja cię wzywam, bo mię wysłuchiwasz, Boże! Nakłoń ucha twego ku mnie, wysłuchaj słowa moje.
Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn dẹ etí rẹ sí mi kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
7 Okaż miłosierdzie twoje, ty, który ochraniasz ufających w tobie od tych, którzy powstawają przeciwko prawicy twojej.
Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn ìwọ tí ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
8 Strzeż mię jako źrenicy oka; pod cieniem skrzydeł twoich ukryj mię.
Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ; fi mí pamọ́ sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ,
9 Przed twarzą niepobożnych, którzy mię niszczą, przed nieprzyjaciółmi duszy mojej, którzy mię ogarnęli.
lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi, kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.
10 Tukiem swoim okryli się; hardzie mówią usty swemi.
Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́, wọ́n sì fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
11 Gdziekolwiek idziemy, obtoczyli nas; oczy swe nasadzili, aby nas potrącili ku ziemi.
Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká, pẹ̀lú ojú ìṣọ́ra láti ṣọ́ mi sílẹ̀.
12 Każdy z nich podobien jest lwowi pragnącemu łupu, i lwięciu siedzącemu w jamie.
Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ, àní bí kìnnìún ńlá tí ó ń ba níbi ìkọ̀kọ̀.
13 Powstańże, Panie! uprzedź twarz jego, potrąć go, wyrwij duszę moję od niezbożnego mieczem twoim.
Dìde, Olúwa, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹni búburú nípa idà rẹ.
14 Wyrwij mię od ludzi ręką twoją, o Panie! od ludzi tego świata, których dział jest w tym żywocie, a których brzuch z szpiżarni twojej napełniasz, skąd nasyceni bywają, i synowie ich, a zostawiają ostatki swoje dzieciom swoim.
Olúwa, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀, kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn ayé yìí, tí èrè wọn wà nínú ayé yìí. Ìwọ ń pa ebi àwọn tí ìwọ fẹ́ràn lẹ́nu mọ́; àwọn ọmọ wọn sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, wọ́n sì kó ọrọ̀ jọ fún àwọn ọmọ wọn.
15 Ale ja w sprawiedliwości oglądam oblicze twoje; gdy się ocucę, nasycony będę obrazem obliczności twojej.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo; nígbà tí èmi bá jí, èmi yóò ní ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí èmi bá rí àwòrán rẹ.

< Psalmów 17 >