< Psalmów 145 >

1 Chwalebna pieśń Dawidowa. Wywyższać cię będę, Boże mój, królu mój! i błogosławić będę imieniowi twemu na wieki wieków.
Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
2 Na każdy dzień błogosławić cię będę, a chwalić imię twoje na wieki wieków.
Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
3 Pan wielki jest i bardzo chwalebny, a wielkość jego nie może być dościgniona.
Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
4 Naród narodowi wychwalać będzie sprawy twoje, a mocy twoje opowiadać będą.
Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
5 Ozdobę chwały wielmożności twojej, i dziwne twe sprawy wysławiać będę.
Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
6 I moc strasznych uczynków twoich ogłaszać będą, i ja zacność twoję opowiadać będę,
Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
7 Pamięć obfitej dobroci twojej wysławiać, o sprawiedliwości twojej śpiewać będą, mówiąc:
Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
8 Dobrotliwy i miłosierny jest Pan, nierychły do gniewu, i wielkiego miłosierdzia.
Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
9 Dobryć jest Pan wszystkim, a miłosierdzie jego nad wszystkiem sprawami jego.
Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
10 Niech cię wysławiają, Panie! wszystkie sprawy twoje, a święci twoi niech ci błogosławią.
Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
11 Sławę królestwa twego niech opowiadają, a o możności twojej niech rozmawiają;
Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
12 Aby oznajmili synom ludzkim mocy jego, a chwałę i ozdobę królestwa jego.
kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
13 Królestwo twoje jest królestwo wszystkich wieków, a panowanie twoje nie ustaje nad wszystkimi narodami.
Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
14 Trzyma Pan wszystkich upadających, a podnosi wszystkich obalonych.
Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
15 Oczy wszystkich w tobie nadzieję mają, a ty im dajesz pokarm ich czasu swojego.
Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
16 Otwierasz rękę twoję, a nasycasz wszystko, co żyje, według upodobania twego.
Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
17 Sprawiedliwy jest Pan we wszystkich drogach swoich, i miłosierny we wszystkich sprawach swoich.
Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
18 Bliski jest Pan wszystkim, którzy go wzywają, wszystkim, którzy go wzywają w prawdzie.
Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
19 Wolę tych czyni, którzy się go boją, a wołanie ich wysłuchiwa, i ratuje ich.
Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
20 Strzeże Pan wszystkich, którzy go miłują; ale wszystkich niepobożnych wytraci.
Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
21 Chwałę Pańską wysławiać będą usta moje; a błogosławić będzie wszelkie ciało imię święte jego na wieki wieków.
Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.

< Psalmów 145 >