< Psalmów 141 >
1 Pieśń Dawidowa. Panie! wołam do ciebie, pośpiesz się do mnie: posłuchaj głosu mego, gdy wołam do ciebie.
Saamu ti Dafidi. Olúwa, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi. Gbọ́ ohùn mi, nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.
2 Niech będzie przyjemna modlitwa moja, jako kadzidło przed obliczem twoim, a podnoszenie rąk moich jako ofiara wieczorna.
Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí àti ìgbé ọwọ́ mi si òkè rí bí ẹbọ àṣálẹ́.
3 Panie! połóż straż ustom moim; strzeż drzwi warg moich.
Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, Olúwa: kí o sì máa pa ìlẹ̀kùn ètè mi mọ́.
4 Nie nachylaj serca mego do złej rzeczy, abym nie czynił spraw niepobożnych z mężami czyniącymi nieprawość, i żebym się nie karmił rozkoszami ich.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi, láti máa bá àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ búburú má sì ṣe jẹ́ kí èmi jẹ àdídùn wọn.
5 Niech mię bije sprawiedliwy, a przyjmę to za miłosierdzie; i niech mię gromi, a będzie mi to za najwyborniejszy olejek, który nie zarazi głowy mojej; albowiem jeszczeć modlitwa moja płatna będzie przeciwko złości ich.
Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́: jẹ́ kí ó bá mi wí, ó jẹ́ òróró ní orí mi. Tí kì yóò fọ́ mi ní orí. Síbẹ̀ àdúrà mi wá láìsí ìṣe àwọn olùṣe búburú.
6 Niech będą zrzuceni do miejsc opoczystych sędziowie ich, aby słyszeli słowa moje, że były wdzięczne.
A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta, àwọn ẹni búburú yóò kọ pé àwọn ọ̀rọ̀ mi dùn.
7 Jako gdyby kto rąbał i łupał drwa na ziemi, tak się rozlatują kości nasze aż do ust grobowych. (Sheol )
Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni egungun wa tànkálẹ̀ ní ẹnu isà òkú.” (Sheol )
8 Ale do ciebie, Panie, Panie! podnoszę oczy moje; w tobie ufam, nie odpychaj duszy mojej.
Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, Olúwa Olódùmarè; nínú rẹ̀ ni èmi ti rí ààbò, má ṣe fà mi fún ikú.
9 Strzeż mię od sidła, które na mię zastawili, i od sideł czyniących nieprawość.
Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi, kúrò nínú ìkẹ́kùn àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
10 Niech wpadną razem w sieci swoje niepobożni, a ja za tem przeminę.
Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn, nígbà tí èmi bá kọjá lọ láìléwu.