< Psalmów 14 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy. Głupi rzekł w sercu swojem: Niemasz Boga. Popsowali się, obrzydliwymi się stali w zabawach swoich: niemasz, ktoby czynił dobrze.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Aṣiwèrè wí nínú ọkàn rẹ̀ pé, “Ko sí Ọlọ́run.” Wọ́n díbàjẹ́, iṣẹ́ wọn sì burú; kò sí ẹnìkan tí yóò ṣe rere.
2 Pan z niebios spojrzał na synów ludzkich, aby obaczył, byłliby kto rozumny i szukający Boga.
Olúwa sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run wá lórí àwọn ọmọ ènìyàn bóyá ó le rí ẹni tí òye yé, ẹnikẹ́ni tó ń wá Ọlọ́run.
3 Aleć wszyscy odstąpili, jednako się nieużytecznymi stali; niemasz, ktoby czynił dobrze, niemasz i jednego.
Gbogbo wọn sì ti yípadà, gbogbo wọn sì ti díbàjẹ́; kò sì ṣí ẹni tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.
4 Azaż nie wiedzą wszyscy czyniciele nieprawości, że pożerają lud mój, jako więc chleb jedzą? ale Pana nie wzywają.
Ǹjẹ́ olùṣe búburú kò ha ní ìmọ̀? Àwọn tí ó ń pa ènìyàn mi jẹ bí ẹní jẹun; wọn kò sì ké pe Olúwa?
5 Tam się bardzo ulękną, gdyż Bóg jest przy narodzie sprawiedliwego.
Wọ́n wà níbẹ̀, tí a bò mọ́lẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù, nítorí Ọlọ́run wà ní àwùjọ àwọn olódodo.
6 Hańbicie radę ubogiego; ale Pan jest nadzieją jego.
Ẹ̀yin olùṣe búburú da èrò àwọn tálákà rú, ṣùgbọ́n Olúwa ni ààbò wọn.
7 Któż da z Syonu wybawienie Izraelowi? Gdyż zasię wyprowadzi Pan z więzienia lud swój; rozraduje się Jakób, a Izrael się rozweseli.
Ìgbàlà àwọn Israẹli yóò ti Sioni wá! Nígbà tí Olúwa bá mú ìkólọ àwọn ènìyàn rẹ̀ padà, jẹ́ kí Jakọbu kí ó yọ̀, kí inú Israẹli kí ó dùn!

< Psalmów 14 >