< Psalmów 119 >

1 Błogosławieni, którzy żyją bez nagany, którzy chodzą w zakonie Pańskim,
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
2 Błogosławieni, którzy strzegą świadectw jego, i którzy go ze wszystkiego serca szukają;
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
3 I którzy nie czynią nieprawości, ale chodzą drogami jego.
Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
4 Tyś przykazał, aby pilnie strzeżono rozkazań twoich.
Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
5 Oby wyprostowane były drogi moje ku przestrzeganiu praw twoich!
Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
6 Tedy nie będę zawstydzony, gdy się będę oglądał na wszystkie rozkazania twoje.
Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
7 Będę cię wysławiał w szczerości serca, gdy się nauczę praw sprawiedliwości twojej.
Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
8 Ustaw twoich z pilnością strzedz będę; tylko mię nie opuszczaj.
Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
9 Jakim sposobem oczyści młodzieniec ścieszkę swoję? Gdy się zachowa według słowa twego.
Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
10 Ze wszystkiego serca mego szukam cię; nie dopuszczajże mi błądzić od rozkazań twoich.
Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
11 W sercu mojem składam wyroki twoje, abym nie zgrzeszył przeciwko tobie.
Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
12 Błogosławionyś ty, Panie! nauczże mię ustaw twoich.
Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
13 Wargami mojemi opowiadam wszystkie sądy ust twoich.
Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
14 W drodze świadectw twoich kocham się więcej, niż we wszystkich bogactwach.
Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
15 O przykazaniach twoich rozmyślam, i przypatruję się drogom twoim.
Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
16 W ustawach twoich kocham się, i nie zapominam słów twoich.
Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
17 Daruj to słudze twemu, abym żył, a przestrzegał słów twoich.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
18 Odsłoń oczy moje, abym się przypatrzył dziwom z zakonu twego.
La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
19 Jestem gościem na ziemi; nie ukrywaj przedemną rozkazań twoich.
Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
20 Omdlewa dusza moja, pragnąc sądów twoich na każdy czas.
Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
21 Wytraciłeś pysznych; przeklęci są ci, którzy błądzą od rozkazań twoich.
Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
22 Oddal odemnie pohańbienie i wzgardę, gdyż strzegę świadecwt twoich.
Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
23 I książęta zasiadają, a mówią przeciwko mnie; wszakże sługa twój rozmyśla w ustawach twoich.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
24 Świadectwa twoje zaiste są mojem kochaniem, i radcami mymi.
Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
25 Przylgnęła do prochu dusza moja; ożywże mię według słowa twego.
Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 Drogi moje rozpowiedziałem, a wysłuchałeś mię; naucz mię ustaw twoich.
Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
27 Daj, abym zrozumiał drogę rozkazań twoich, ażebym rozmyślał o dziwnych sprawach twoich.
Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
28 Rozpływa się od smutku dusza moja; utwierdźże mię według słowa twego.
Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
29 Drogę kłamliwą oddal odemnie, a zakonem twoim udaruj mię.
Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
30 Obrałem drogę prawdy, a sądy twoje przekładam sobie.
Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
31 Przystałem do świadectw twoich; Panie! nie zawstydzajże mię.
Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
32 Drogą przykazań twoich pobieżę, gdy rozszerzysz serce moje.
Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
33 Naucz mię, Panie! drogi ustaw twoich, a będę jej strzegł aż do końca.
Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Daj mi rozum, abym strzegł zakonu twego, ażebym go przestrzegał ze wszystkiego serca.
Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
35 Daj, abym chodził ścieżką przykazań twoich, gdyż w tem jest upodobanie moje.
Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Nakłoń serce moje do świadectw twoich, a nie do łakomstwa.
Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
37 Odwróć oczy moje, aby nie patrzały na marność; na drodze twojej ożyw mię.
Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
38 Utwierdź wyrok twój słudze twemu, który się oddał bojaźni twojej.
Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
39 Oddal odemnie pohańbienie moje, którego się boję; bo sądy twoje dobre.
Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
40 Oto pragnę rozkazań twoich; w sprawiedliwości twojej ożyw mię.
Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
41 Niech na mię przyjdą litości twoje, Panie! i zbawienie twoje według wyroku twego.
Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
42 Tak abym odpowiedź mógł dać samą rzeczą temu, który mi urąga, gdyż ufam w słowie twojem.
Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
43 A nie wyjmuj z ust moich słowa najprawdziwszego; albowiem sądów twoich oczekuję.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
44 I będę strzegł zakonu twego zawsze, aż na wieki wieczne.
Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
45 A ustawicznie będę chodził na przestrzeństwie, bom się dopytał rozkazań twoich.
Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
46 Owszem, będę mówił o świadectwach twoich przed królmi, a nie będę zawstydzony.
Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
47 Bom się rozkochał w przykazaniach twoich, którem umiłował.
nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
48 Przyłożę i ręce moje do rozkazań twoich, które miłuję, a będę rozmyślał o ustawach twoich.
Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
49 Wspomnij na słowo wyrzeczone do sługi twego, któremeś mię ubezpieczył.
Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
50 Toć pociecha moja w utrapieniu mojem, że mię wyrok twój ożywia.
Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
51 Pyszni bardzo się ze mnie naśmiewają; wszakże się od zakonu twego nie uchylam.
Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
52 Bo pamiętam na sądy twoje wieczne, Panie! któremi się cieszę.
Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
53 Strach mię ogarnął nad niezbożnymi, którzy opuszczają zakon twój.
Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
54 Są mi ustawy twoje pieśniami w domu pielgrzymstwa mego.
Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
55 Wspominam sobie i w nocy na imię twoje, Panie! i strzegę zakonu twego.
Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
56 Toć mam z tego, że przestrzegam przykazań twoich.
nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
57 Rzekłem: Panie! to jest cząstka moja, przestrzegać słów twoich.
Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
58 Modlę się przed obliczem twojem ze wszystkiego serca; zmiłujże się nademną według słowa twego.
Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
59 Uważyłem w myślach drogi moje, a obróciłem nogi moje ku świadectwom twoim.
Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
60 Śpieszę się, a nie omieszkuję przestrzegać rozkazań twoich.
Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
61 Hufy niepobożnych złupiły mię; ale na zakon twój nie zapominam.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
62 O północy wstaję, abym cię wysławiał w sądach sprawiedliwości twojej.
Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
63 Jestem towarzyszem wszystkich, którzy się ciebie boją, i tych, którzy przestrzegają przykazań twoich.
Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
64 Panie! pełna jest ziemia miłosierdzia twego; nauczże mię ustaw twoich.
Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
65 Łaskawieś postąpił ze sługą twoim, Panie! według słowa twego.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
66 Dobrego rozumu i umiejętności naucz mię; bom przykazaniom twoim uwierzył.
Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
67 Pierwej niżem się był uniżył, błądziłem; ale teraz wyroku twego przestrzegam.
Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
68 Dobryś ty i dobrotliwy; nauczże mię ustaw twoich.
Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
69 Uknowali hardzi kłamstwo przeciwko mnie; ale ja ze wszystkiego serca strzegę przykazań twoich.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
70 Serce ich zatyło jako sadło; ale się ja zakonem twoim cieszę.
Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
71 Jest mi to ku dobremu, żem był utrapiony, abym się nauczył ustaw twoich.
Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
72 Lepszy mi jest zakon ust twoich, niżeli tysiące złota i srebra.
Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
73 Ręce twoje uczyniły mię, i wykształtowały mię; dajże mi rozum, abym się nauczył przykazań twoich;
Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
74 Aby się radowali bojący się ciebie, ujrzawszy mię, że na słowo twoje oczekuję.
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
75 Znam, Panie! iż są sprawiedliwe sądy twoje, a iżeś mię słusznie utrapił.
Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
76 Niechajże mię, proszę, ucieszy miłosierdzie twoje według wyroku twego, któryś uczynił słudze twemu.
Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
77 Niechże na mię przyjdą litości twoje, abym żył; bo zakon twój jest kochaniem mojem.
Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
78 Niech będą zawstydzeni pyszni, przeto, że mię chytrze podwrócić chcieli; ale ja rozmyślać będę w przykazaniach twoich.
Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
79 Niech się obrócą do mnie, którzy się ciebie boją, i którzy znają świadectwa twoje.
Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
80 Niech będzie serce moje uprzejme przy ustawach twoich, abym nie był zawstydzony.
Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
81 Tęskni dusza moja po zbawieniu twojem, oczekuję na słowo twoje.
Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
82 Ustały oczy moje, czekając wyroku twego, gdy mówię: Kiedyż mię pocieszysz?
Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
83 Chociażem jest jako naczynie skórzane w dymie, wszakżem ustaw twoich nie zapomniał.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
84 Wieleż będzie dni sługi twego? kiedyż sąd wykonasz nad tymi, którzy mię prześladują?
Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
85 Pyszni pokopali mi doły, co nie jest według zakonu twojego.
Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
86 Wszystkie przykazania twoje są prawdą; bez przyczyny mię prześladują; ratujże mię.
Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
87 Bez mała mię już wniwecz nie obrócili na ziemi; a wszakżem ja nie opuścił przykazań twoich.
Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
88 Według miłosierdzia twego ożyw mię, abym strzegł świadectwa ust twoich.
Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
89 O Panie! słowo twoje trwa na wieki na niebie.
Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
90 Od narodu do narodu prawda twoja; ugruntowałeś ziemię, i stoi.
Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
91 Według rozrządzenia twego trwa to wszystko aż do dnia tego; wszystko to zaiste jest ku służbie twojej.
Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
92 By był zakon twój nie był kochaniem mojem, dawnobym był zginął w utrapieniu mojem.
Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
93 Na wieki nie zapomnę na przykazania twoje, gdyżeś mię w nich ożywił.
Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
94 Twójcim ja, zachowajże mię; bo przykazań twoich szukam.
Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
95 Czekają na mię niezbożnicy, aby mię zatracili; ale ja świadectwa twoje uważam.
Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
96 Wszelkiej rzeczy koniec widzę; ale przykazanie twoje bardzo szerokie.
Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
97 O jakom się rozmiłował zakonu twego! tak, iż każdego dnia jest rozmyślaniem mojem.
Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
98 Nad nieprzyjaciół moich mędrszym mię czynisz przykazaniem twojem; bo je mam ustawicznie przed sobą.
Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
99 Nad wszystkich nauczycieli moich stałem się rozumniejszym; bo świadectwa twoje są rozmyślaniem mojem.
Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
100 Nad starców jestem roztropniejszy; bo przykazań twoich przestrzegam.
Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
101 Od wszelkiej złej drogi zawściągam nogi swoje, abym strzegł słowa twego.
Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
102 Od sądów twoich nie odstępuję, przeto, że ich ty mnie uczysz.
Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
103 O jako są słodkie słowa twoje podniebieniu memu! nad miód są słodsze ustom moim.
Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
104 Z przykazań twoich nabyłem rozumu: przetoż mam w nienawiści wszelką ścieszkę obłędliwą.
Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
105 Słowo twe jest pochodnią nogą moim, a światłością ścieszce mojej.
Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
106 Przysięgłem i uczynię temu dosyć, że będę strzegł sądów sprawiedliwości twojej.
Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
107 Jestem bardzo utrapiony; o Panie! ożyw mię według słowa twego.
A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
108 Panie! dobrowolne śluby ust moich przyjmij proszę za wdzięczne, a sądów twoich naucz mię.
Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
109 Dusza moja jest w ustawicznem niebezpieczeństwie; wszakże na zakon twój nie zapominam.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
110 Sidło na mię niezbożnicy zastawili; lecz ja się od przykazań twoich nie obłądzę.
Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
111 Za dziedzictwo wieczne wziąłem świadectwa twoje; bo są radością serca mego.
Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
112 Nakłoniłem serca mego ku wykonywaniu ustaw twoich ustawicznie, i aż do końca (żywota).
Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
113 Wymysły mam w nienawiści, a zakon twój miłuję.
Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
114 Tyś jest ucieczką moją, i tarczą moją; na słowo twoje oczekuję.
Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
115 Odstąpcież odemnie złośnicy, abym strzegł rozkazania Boga mojego.
Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
116 Utwierdźże mię według słowa twego, abym żył, a nie zawstydzaj mię w oczekiwaniu mojem.
Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
117 Podpieraj mię, abym był zachowany, i rozmyślał w ustawach twoich ustawicznie.
Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
118 Podeptałeś wszystkich, którzy się obłądzili od ustaw twoich; albowiem jest kłamliwa zdrada ich.
Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
119 Odrzucasz jako zużelicę wszystkich niezbożników ziemi; dla tego miłuję świadectwa twoje.
Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
120 Drży od strachu przed tobą ciało moje; bo się sądów twoich lękam.
Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
121 Czynię sądy i sprawiedliwość: nie podawajże mię tym, którzy mi gwałt czynią.
Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
122 Zastąp sam sługę twego ku dobremu, aby mię hardzi nie potłoczyli.
Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
123 Oczy moje ustały, czekając na zbawienie twoje, i na wyrok sprawiedliwości twojej.
Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
124 Obchodź się z sługą twoim według miłosierdzia twego, a ustaw twoich naucz mię.
Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
125 Sługamci ja twój, dajże mi zrozumienie; abym umiał świadectwa twoje.
Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
126 Czasci już, abyś czynił Panie! albowiem wzruszono zakon twój.
Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
127 Dlatego umiłowałem rozkazania twoje nad złoto, a nad złoto najwyborniejsze.
Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
128 Przeto, że wszystkie przykazania twoje, wszystkie prawdziwe być uznaję, a wszelkie ścieżki obłędliwe mam w nienawiści.
nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
129 Dziwne są świadectwa twoje; przetoż ich strzeże dusza moja.
Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
130 Początek słów twoich oświeca i daje rozum prostakom.
Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
131 Usta moje otwieram i dyszę; albowiemem przykazań twoich pragnął.
Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
132 Wejżyjże na mię, a zmiłuj się nademną weaług prawa tych, którzy miłują imię twoje.
Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
133 Drogi moje utwierdź w słowie twojem, a niech nademną nie panuje żadna nieprawość.
Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
134 Wybaw mię od uciśnienia ludzkiego, abym strzegł rozkazań twoich.
Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
135 Rozświeć nad sługą twoim oblicze twoje, a naucz mię ustaw twoich.
Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
136 Strumienie wód płyną z oczów moich dla tych, którzy nie strzegli zakonu twego.
Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
137 Sprawiedliwyś ty, Panie! i prawdziwy w sądach twoich.
Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
138 Przykazałeś sprawiedliwe świadectwa twoje, i wielce prawdziwe.
Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
139 Zniszczyła mię gorliwość moja, iż zapominają na słowo twoje nieprzyjaciele moi.
Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
140 Doskonale są doświadczone słowa twoje; dlatego się sługa twój w nich rozkochał.
Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
141 Jam maluczki i wzgardzony; wszakże przykazań twoich nie zapominam.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
142 Sprawiedliwość twoja sprawiedliwość wieczna, a zakon twój prawda.
Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
143 Ucisk i utrapienie przyszło na mię; przykazania twoje są kochaniem mojem.
Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
144 Sprawiedliwość świadectw twoich trwa na wieki; daj mi rozum, a żyć będę.
Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
145 Wołam ze wszystkiego serca, wysłuchajże mię, o Panie! a będę strzegł ustaw twoich.
Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
146 Wołam do ciebie, zachowajże mię, a będę pilen świadectw twoich.
Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
147 Uprzedzam cię na świtaniu i wołam, na słowo twoje oczekując.
Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
148 Uprzedzają straż nocną oczy moje, przeto, abym rozmyślał o wyrokach twoich.
Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
149 Panie! głos mój usłysz według miłosierdzia twego; według sądu twego ożyw mię.
Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
150 Przybliżają się, którzy naśladują złości, ci, którzy się od zakonu twego oddalili.
Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
151 Bliskoś ty jest, Panie! a wszystkie przykazania twoje są prawdą.
Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
152 Dawno to wiem o świadectwach twoich, żeś je na wieki ugruntował.
Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
153 Obacz utrapienie moje, a wyrwij mię; bom na zakon twój nie zapomniał.
Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
154 Stań przy sprawie mojej, a obroń mię; dla słowa twego ożyw mię.
Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
155 Dalekoć jest od niezbożników zbawienie; bo się nie badają o ustawach twoich.
Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
156 Wielkie są litości twoje, Panie! według sądów twoich ożyw mię.
Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
157 Wieleć jest prześladowców moich i nieprzyjaciół moich; wszakże od świadectw twoich nie uchylam się.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
158 Widziałem przestępców, i mierziało mię to, że wyroku twego nie przestrzegali.
Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
159 Obaczże Panie! iż rozkazania twoje miłuję; według miłosierdzia twego ożyw mię.
Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
160 Najprzedniejsza rzecz słowa twego jest prawda, a na wieki trwa wszelki sąd sprawiedliwości twojej.
Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
161 Książęta mię prześladują bez przyczyny; wszakże słów twoich boi się serce moje.
Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
162 Ja się weselę z wyroku twego, tak jako ten, który znajduje wielkie korzyści.
Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
163 Ale nienawidzę kłamstwa, i brzydzą się niem; ale zakon twój miłuję.
Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
164 Chwalę cię siedm kroć przez dzień, dla sądów twoich sprawiedliwych.
Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
165 Pokój wielki dajesz tym, którzy miłują zakon twój, a nie doznawają żadnego obrażenia.
Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
166 Panie! oczekuję zbawienia twego; a przykazania twoje wykonywam.
Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
167 Przestrzega dusza moja świadectw twoich; albowiem je bardzo miłuję.
Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
168 Przestrzegam przykazań twoich i świadectw twoich; albowiem wszystkie drogi moje są przed tobą.
Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
169 Panie! niech się przybliży wołanie moje przed oblicze twoje; według słowa twego daj mi zrozumienie.
Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
170 Niech przyjdzie prośba moja przed twarz twoję, a według obietnicy twojej wyrwij mię.
Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
171 Chwałę wydadzą wargi moje, gdy mię nauczysz ustaw twoich.
Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
172 Opowiadać będzie język mój wyroki twoje; bo wszystkie przykazania twoje są sprawiedliwość.
Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
173 Niech mi będzie na pomocy ręka twoja, gdyżem sobie obrał przykazania twoje.
Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
174 Panie! zbawienia twego pragnę, a zakon twój jest kochaniem mojem.
Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
175 Żyć będzie dusza moja, i będzie cię chwaliła, a sądy twoje będą mi na pomocy.
Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
176 Błądzę jako owca zgubiona, szukajże sługi twego; boć przykazań twoich nie zapominam.
Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.

< Psalmów 119 >