< Psalmów 116 >

1 Miłuję Pana, iż wysłuchał głos mój, i prośby moje.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Albowiem nakłonił ucha swego ku mnie, gdym go wzywał za dni moich.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Ogarnęły mię były boleści śmierci, a utrapienia grobu zjęły mię; ucisk i boleść przyszła na mię. (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 I wzywałem imienia Pańskiego, mówiąc: Proszę, o Panie! wybaw duszę moję.
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 Miłościwy Pan i sprawiedliwy, Bóg nasz litościwy.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 Pan prostaczków strzeże; byłem uciśniony, a wspomógł mię.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Nawróć się, duszo moja! do odpocznienia swego; albowiem ci Pan dobrze uczynił.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 Bo wyrwał duszę moję od śmierci, oczy moje od płaczu, nogę moję od upadku.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 Będę chodził ustawicznie przed oblicznością Pańską w ziemi żyjących.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 Uwierzyłem, dlategom mówił, chociażem bardzo był utrapiony.
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 Jam był rzekł w zatrwożeniu mojem: Wszelki człowiek kłamca.
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 Cóż oddam Panu za wszystkie dobrodziejstwa jego, które mi uczynił?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 Kielich obfitego zbawienia wezmę, a imienia Pańskiego wzywać będę,
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 Śluby moje oddam Panu, a to zaraz przed wszystkim ludem jego.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Droga jest przed oczyma Pańskiemi śmierć świętych jego.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 O mój Panie! żem ja sługą twoim, jam sługą twoim, synem służebnicy twojej, rozwiązałeś związki moje.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 Tobie ofiarować będę ofiarę chwały, i imienia Pańskiego wzywać będę.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 Śluby moje oddam Panu, a to zaraz przed wszystkim ludem jego,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 W przysionkach domu Pańskiego, w pośrodku ciebie, Jeruzalemie! Halleluja.
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Psalmów 116 >