< Psalmów 115 >
1 Nie nam, Panie! nie nam, ale imieniowi twemu daj chwałę dla miłosierdzia twego, i dla prawdy twojej.
Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
2 Czemuż mają mówić poganie: Gdzież teraz jest Bóg ich?
Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
3 Wszakże Bóg nasz jest na niebie, czyniąc wszystko, co mu się podoba.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
4 Ale bałwany ich są srebro i złoto, robota rąk ludzkich.
Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
5 Usta mają, a nie mówią; oczy mają, a nie widzą.
Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
6 Uszy mają, a nie słyszą; nozdrze mają, a nie wonieją.
Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
7 Ręce mają, a nie macają; nogi mają, a nie chodzą, ani wołają gardłem swojem.
Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
8 Niech im podobni będą, którzy je czynią, i wszyscy, którzy w nich ufają.
Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
9 Izraelu! ufaj w Panu; bo on jest pomocnikiem ich i tarczą ich.
Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
10 Domie Aaronowy! ufajcie w Panu; on jest pomocnikiem, i tarczą ich.
Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
11 Którzy się boicie Pana, ufajcie w Panu; on jest pomocnikiem i tarczą ich.
Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
12 Pan będzie pamiętał na nas, będzie błogosławił; będzie błogosławił domowi Izraelskiemu, będzie błogosławił domowi Aaronowemu.
Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
13 Będzie błogosławił tym, którzy się boją Pana, małym i wielkim.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
14 Rozmnoży was Pan, was i synów waszych.
Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
15 Błogosławieniście wy od Pana, który stworzył niebo i ziemię.
Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
16 Niebiosa są niebiosa Pańskie; ale ziemię dał synom ludzkim.
Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
17 Umarli nie będą chwalili Pana, ani kto z tych, co zstępują do miejsca milczenia.
Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
18 Ale my będziemy błogosławili Panu, odtąd aż na wieki. Halleluja.
Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.