< Psalmów 110 >

1 Psalm Dawidowy. Rzekł Pan Panu memu: Siądź po prawicy mojej, dokąd nie położę nieprzyjaciół twoich podnóżkiem nóg twoich.
Ti Dafidi. Saamu. Olúwa sọ fún Olúwa mi pé, “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi, títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”
2 Laskę mocy twojej pośle Pan z Syonu, mówiąc: Panuj w pośród nieprzyjaciół twoich.
Olúwa yóò na ọ̀pá agbára rẹ̀ láti Sioni wá, ìwọ jẹ ọba láàrín àwọn ọ̀tá rẹ.
3 Lud twój będzie dobrowolny w dzień zwycięstwa twego, w ozdobie świętobliwości, a rozrodzi się płód twój z żywota jako rosa na świtaniu.
Àwọn ènìyàn rẹ jẹ́ ọ̀rẹ́ àtinúwá ní ọjọ́ ìjáde ogun rẹ, nínú ẹwà mímọ́, láti inú òwúrọ̀ wá ìwọ ni ìrì ẹwà rẹ.
4 Przysiągł Pan, a nie będzie tego żałował, mówiąc: Tyś jest kapłanem na wieki według porządku Melchisedechowego.
Olúwa ti búra, kò sì í yí ọkàn padà pé, “Ìwọ ni àlùfáà, ní ipasẹ̀ Melkisedeki.”
5 Pan po prawicy twojej potrze królów w dzień gniewu swego.
Olúwa, ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni yóò lu àwọn ọba bolẹ̀ ni ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
6 Będzie sądził narody, i wszystko napełni trupami; potłucze głowę nad wielą ziem panującą.
Yóò ṣe ìdájọ́ láàrín kèfèrí, yóò kún ibùgbé wọn pẹ̀lú òkú ara; yóò fọ́n àwọn olórí ká sí orí ilẹ̀ ayé tí ó gbòòrò.
7 Z strumienia na drodze pić będzie; przetoż wywyższy głowę.
Yóò mu nínú odò ṣíṣàn ní ọ̀nà: nítorí náà ni yóò ṣe gbé orí sókè.

< Psalmów 110 >